Jobu 17 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 17:1-16

Ìdáhùn Jobu

1“Ẹ̀mí mi bàjẹ́,

ọjọ́ mi ni a ti gé kúrú,

isà òkú dúró dè mí.

2Nítòótọ́ àwọn ẹlẹ́yà wà lọ́dọ̀ mi,

ojú mi sì tẹ̀mọ́ ìmúnibínú wọn.

3“Fi fún mi Olúwa, ìlérí tí ìwọ fẹ́;

ta ni yóò le ṣe ààbò fún mi?

4Nítorí pé ìwọ ti sé wọ́n láyà kúrò nínú òye;

nítorí náà ìwọ kì yóò gbé wọn lékè.

5Ẹni tí ó sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn dídún fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ fún èrè,

òun ni ojú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò mú òfo.

6“Ọlọ́run ti sọ mi di ẹni òwe fún àwọn ènìyàn;

níwájú wọn ni mo dàbí ẹni ìtutọ́ sí ní ojú.

7Ojú mí ṣú bàìbàì nítorí ìbìnújẹ́,

gbogbo ẹ̀yà ara mi sì dàbí òjìji.

8Àwọn olódodo yóò yanu sí èyí,

ẹni aláìṣẹ̀ sì bínú sí àwọn àgàbàgebè.

9Olódodo pẹ̀lú yóò di ọ̀nà rẹ̀ mú,

àti ọlọ́wọ́ mímọ́ yóò máa lera síwájú.

10“Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti gbogbo yín,

ẹ yípadà, kí ẹ si tún padà nísinsin yìí;

èmi kò le rí ọlọ́gbọ́n kan nínú yín.

11Ọjọ́ tí èmi ti kọjá, ìrò mi ti fà yá,

àní ìrò ọkàn mi.

12Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń ṣọ́ òru di ọ̀sán;

wọ́n ní, ìmọ́lẹ̀ súnmọ́ ibi tí òkùnkùn dé.

13Bí mo tilẹ̀ ní ìrètí, ipò òku ní ilé mi;

mo ti tẹ́ ibùsùn mi sínú òkùnkùn.

14Èmi ti wí fún ìdíbàjẹ́ pé, ìwọ ni baba mi,

àti fún kòkòrò pé, ìwọ ni ìyá mi àti arábìnrin mi,

15ìrètí mi ha dà nísinsin yìí?

Bí ó ṣe ti ìrètí mi ni, ta ni yóò rí i?

16Yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ipò òkú,

nígbà tí a jùmọ̀ sinmi pọ̀ nínú erùpẹ̀ ilẹ̀?”

New International Version

Job 17:1-16

1My spirit is broken,

my days are cut short,

the grave awaits me.

2Surely mockers surround me;

my eyes must dwell on their hostility.

3“Give me, O God, the pledge you demand.

Who else will put up security for me?

4You have closed their minds to understanding;

therefore you will not let them triumph.

5If anyone denounces their friends for reward,

the eyes of their children will fail.

6“God has made me a byword to everyone,

a man in whose face people spit.

7My eyes have grown dim with grief;

my whole frame is but a shadow.

8The upright are appalled at this;

the innocent are aroused against the ungodly.

9Nevertheless, the righteous will hold to their ways,

and those with clean hands will grow stronger.

10“But come on, all of you, try again!

I will not find a wise man among you.

11My days have passed, my plans are shattered.

Yet the desires of my heart

12turn night into day;

in the face of the darkness light is near.

13If the only home I hope for is the grave,

if I spread out my bed in the realm of darkness,

14if I say to corruption, ‘You are my father,’

and to the worm, ‘My mother’ or ‘My sister,’

15where then is my hope—

who can see any hope for me?

16Will it go down to the gates of death?

Will we descend together into the dust?”