Joẹli 2 – YCB & CST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Joẹli 2:1-32

Àwọn jagunjagun eṣú

1Ẹ fun ìpè ní Sioni,

ẹ sì fún ìpè ìdágìrì ní òkè mímọ́ mi.

Jẹ́ kí àwọn ará ilẹ̀ náà wárìrì,

nítorí tí ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ wá,

nítorí ó kù sí dẹ̀dẹ̀.

2Ọjọ́ òkùnkùn àti ìrọ́kẹ̀kẹ̀,

ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri,

Bí ọyẹ́ òwúrọ̀ ti í la bo orí àwọn òkè ńlá:

àwọn ènìyàn ńlá àti alágbára; ya dé,

ti kó ti ì sí irú rẹ̀ rí,

bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kì yóò sí mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, títí dé ọdún ìran dé ìran.

3Iná ń jó níwájú wọ́n;

ọwọ́ iná sì ń jó lẹ́yìn wọn:

Ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Edeni níwájú wọn,

àti lẹ́yìn wọn bí ahoro ijù;

nítòótọ́, kò sì sí ohun tí yóò bọ́ lọ́wọ́ wọn.

42.4-5: If 9.7,9.Ìrí wọn dàbí ìrí àwọn ẹṣin;

wọ́n ń sáré lọ bí àwọn ẹlẹ́ṣin ogun

5Bí ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ni

wọn ń fo ní orí òkè

bí ariwo ọ̀wọ́-iná tí ń jó koríko gbígbẹ,

bí akọni ènìyàn tí a kójọ fún ogun.

6Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀:

gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.

7Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára;

wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun;

olúkúlùkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀,

wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.

8Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò kọlu ẹnìkejì rẹ̀;

olúkúlùkù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀:

nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù idà

wọn kì yóò gbọgbẹ́.

9Wọn yóò sáré síwá sẹ́yìn ní ìlú;

wọn yóò súré lórí odi,

wọn yóò gùn orí ilé;

wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.

102.10: If 9.2.Ayé yóò mì níwájú wọn;

àwọn ọ̀run yóò wárìrì;

oòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn,

àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn.

112.11: If 6.17.Olúwa yóò sì bú ramúramù

jáde níwájú ogun rẹ̀:

nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi;

nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ;

nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi;

ara ta ni ó lè gbà á?

Fa ọkàn rẹ ya

12“Ǹjẹ́ nítorí náà nísinsin yìí,” ni Olúwa wí,

“Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi,

àti pẹ̀lú àwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”

13Ẹ sì fa ọkàn yín ya,

kì í sì í ṣe aṣọ yín,

ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín,

nítorí tí o pọ̀ ní oore-ọ̀fẹ́,

ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú,

ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.

14Ta ni ó mọ̀ bí òun yóò yípadà, kí o sì ronúpìwàdà,

kí ó sì fi ìbùkún sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀—

àní ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ mímu

fún Olúwa Ọlọ́run yín?

15Ẹ fún ìpè ní Sioni,

ẹ ya àwẹ̀ kan sí mímọ́,

ẹ pe àjọ tí ó ni ìrònú.

16Ẹ kó àwọn ènìyàn jọ,

ẹ ya ìjọ sí mímọ́;

ẹ pe àwọn àgbàgbà jọ,

ẹ kó àwọn ọmọdé jọ,

àti àwọn tí ń mú ọmú:

jẹ kí ọkọ ìyàwó kúrò nínú ìyẹ̀wù rẹ̀.

Kí ìyàwó sì kúrò nínú iyàrá rẹ̀

17Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ Olúwa,

sọkún láàrín ìloro àti pẹpẹ.

Sí jẹ́ kí wọn wí pé, “Dá àwọn ènìyàn rẹ sí, Olúwa.

Má sì ṣe fi ìní rẹ fun ẹ̀gàn,

tí yóò sì di òwe ní àárín àwọn kèfèrí.

Èéṣe tí wọn yóò fi wí láàrín àwọn ènìyàn pé,

‘Ọlọ́run wọn ha da?’ ”

18Nígbà náà ní Olúwa yóò jowú fún ilẹ̀ rẹ̀,

yóò sì káàánú fún ènìyàn rẹ̀.

19Nítòótọ́, Olúwa yóò dá wọn lóhùn:

“Yóò sì wí fun àwọn ènìyàn rẹ̀ pé,

Wò ó èmi yóò rán ọkà, àti ọtí wáìnì tuntun,

àti òróró sí i yín, a ó sì fi wọn tẹ́ yín lọ́rùn:

èmi kì yóò sì fi yín ṣe ẹ̀gàn mọ́ láàrín àwọn aláìkọlà.

20“Ṣùgbọ́n èmi yóò lé ogun àríwá jìnnà réré kúrò lọ́dọ̀ yín,

èmi yóò sì lé e lọ sí ilẹ̀ tí ó ṣá, tí ó sì di ahoro,

pẹ̀lú ojú rẹ̀ sí Òkun ìlà-oòrùn,

àti ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìwọ̀-oòrùn Òkun.

Òórùn rẹ̀ yóò sì gòkè,

òórùn búburú rẹ̀ yóò sì gòkè.”

Nítòótọ́ ó ti ṣe ohun ńlá.

21Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀;

jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn kí o sì yọ̀,

nítorí Olúwa ti ṣe ohun ńlá,

22Ẹ má bẹ̀rù, ẹranko igbó,

nítorí pápá oko aginjù ń rú,

nítorí igi ń so èso rẹ̀, igi ọ̀pọ̀tọ́

àti àjàrà ń so èso ọ̀rọ̀ wọn.

23Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Sioni,

ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín,

nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́,

Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín,

àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.

24Àwọn ilẹ̀ ìpakà yóò kún fún ọkà;

àti ọpọ́n wọn nì yóò sàn jáde

pẹ̀lú ọtí wáìnì tuntun àti òróró.

25“Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín.

Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewé

ọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòrò ajẹnirun mìíràn ti fi jẹ

àwọn ogun ńlá mi tí mo rán sí àárín yín.

26Ẹ̀yin yóò ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti jẹ, títí ẹ̀yin yóò fi yó

ẹ ó sì yín orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín,

ẹni tí ó fi ìyanu bá yín lò;

ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mi láéláé.

27Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, èmi wà láàrín Israẹli,

àti pé; Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín,

àti pé kò sí ẹlòmíràn:

Ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mí láéláé.

Ọjọ́ Olúwa

282.28-32: Ap 2.17-21.“Yóò sì ṣe níkẹyìn ọjọ́,

èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí sí ara ènìyàn gbogbo;

àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀,

àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá,

àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò máa ríran.

29Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin,

àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin,

ní èmi yóò tú ẹ̀mí mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.

30Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrun

àti ní ayé,

ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.

312.31: If 6.12.A á sọ oòrùn di òkùnkùn,

àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀,

kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa tó dé.

322.32: Ro 10.13.Yóò sí ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pè

orúkọ Olúwa ní a ó gbàlà:

nítorí ní òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu

ní ìgbàlà yóò gbé wà,

Olúwa ti wí,

àti nínú àwọn

ìyókù tí Olúwa yóò pè.

Nueva Versión Internacional (Castilian)

Joel 2:1-32

Un ejército de langostas

1Tocad la trompeta en Sión;

dad la voz de alarma en mi santo monte.

Tiemblen todos los habitantes del país,

pues ya viene el día del Señor;

en realidad ya está cerca.

2Día de tinieblas y oscuridad,

día de nubes y densos nubarrones.

Como la aurora que se extiende sobre los montes,

así avanza un pueblo fuerte y numeroso,

pueblo como nunca lo hubo en la antigüedad

ni lo habrá en las generaciones futuras.

3El fuego devora delante de ellos;

detrás, las llamas lo queman todo.

Antes de su llegada, el país se parece al jardín del Edén;

después, queda un desolado desierto;

¡nada escapa a su poder!

4Tienen aspecto de caballos;

galopan como corceles.

5Y al saltar sobre las cumbres de los montes,

producen un estruendo como el de carros de guerra,

como el crepitar del fuego al consumir la hojarasca.

¡Son como un ejército poderoso en formación de batalla!

6Ante él se estremecen las naciones;

todo rostro palidece.

7Atacan como guerreros,

escalan muros como soldados.

Cada uno mantiene la marcha

sin romper la formación.

8No se atropellan entre sí;

cada uno marcha en línea.

Se lanzan entre las flechas

sin romper filas.

9Se abalanzan contra la ciudad,

arremeten contra los muros,

trepan por las casas,

se meten por las ventanas como ladrones.

10Ante este ejército tiembla la tierra

y se estremece el cielo,

el sol y la luna se oscurecen

y las estrellas dejan de brillar.

11Truena la voz del Señor

al frente de su ejército;

son innumerables sus tropas

y poderosos los que ejecutan su palabra.

El día del Señor es grande y terrible.

¿Quién lo podrá resistir?

Exhortación al arrepentimiento

12«Ahora bien —afirma el Señor—,

volveos a mí de todo corazón,

con ayuno, llantos y lamentos».

13Rasgaos el corazón

y no las vestiduras.

Volveos al Señor vuestro Dios,

porque él es bondadoso y compasivo,

lento para la ira y lleno de amor,

cambia de parecer y no castiga.

14Tal vez Dios reconsidere y cambie de parecer,

y deje tras de sí una bendición.

Las ofrendas de cereales y las libaciones

son del Señor vuestro Dios.

15Tocad la trompeta en Sión,

proclamad el ayuno,

convocad una asamblea solemne.

16Congregad al pueblo,

purificad la asamblea;

juntad a los ancianos del pueblo,

reunid a los pequeños

y a los niños de pecho.

Que salga de su alcoba el recién casado,

y la recién casada de su cámara nupcial.

17Lloren, sacerdotes, ministros del Señor,

entre el pórtico y el altar;

y digan: «Compadécete, Señor, de tu pueblo.

No entregues tu propiedad al oprobio,

para que las naciones no se burlen de ella.2:17 no se burlen de ella. Alt. no la sometan.

¿Por qué habrán de decir entre los pueblos:

“Dónde está su Dios?”»

La respuesta del Señor

18Entonces el Señor mostró amor por su tierra

y perdonó a su pueblo.

19Y les respondió el Señor:

«Mirad, os enviaré cereales, vino nuevo y aceite,

hasta dejaros plenamente satisfechos;

y no volveré a entregaros

al oprobio entre las naciones.

20»Alejaré de vosotros al que viene del norte,

arrojándolo hacia una tierra seca y desolada:

lanzaré su vanguardia hacia el mar oriental,

y su retaguardia hacia el mar occidental.2:20 el mar oriental … el mar occidental. Es decir, el Mar Muerto y el Mediterráneo.

Subirá su hedor

y se elevará su fetidez».

¡El Señor hará grandes cosas!

21No temas, tierra,

sino alégrate y regocíjate,

porque el Señor hará grandes cosas.

22No temáis, animales del campo,

porque los pastizales de la estepa reverdecerán;

los árboles producirán su fruto,

y la higuera y la vid darán su riqueza.

23Alegraos, hijos de Sión,

regocijaos en el Señor vuestro Dios,

que a su tiempo os dará las lluvias de otoño.

Os enviará la lluvia,

la de otoño y la de primavera,

como en tiempos pasados.

24Las eras se llenarán de grano;

los lagares rebosarán de vino nuevo y de aceite.

25«Yo os compensaré a vosotros

por los años en que todo lo devoró

ese gran ejército de langostas

que envié contra vosotros:

las grandes, las pequeñas,

las larvas y las orugas.2:25 Véase nota en 1:4.

26Comeréis en abundancia, hasta saciaros,

y alabaréis el nombre del Señor vuestro Dios,

que hará maravillas con vosotros.

¡Nunca más será avergonzado mi pueblo!

27Entonces sabréis que yo estoy en medio de Israel,

que yo soy el Señor vuestro Dios,

y no hay otro fuera de mí.

¡Nunca más será avergonzado mi pueblo!

El día del Señor

28»Después de esto,

derramaré mi Espíritu sobre todo ser humano.

Vuestros hijos y vuestras hijas profetizarán,

tendrán sueños los ancianos

y visiones los jóvenes.

29En esos días derramaré mi Espíritu

aun sobre los siervos y las siervas.

30En el cielo y en la tierra mostraré prodigios:

sangre, fuego y columnas de humo.

31El sol se convertirá en tinieblas

y la luna en sangre

antes que llegue el día del Señor,

día grande y terrible.

32Y todo el que invoque el nombre del Señor

escapará con vida,

porque en el monte Sión y en Jerusalén

habrá escapatoria,

como lo ha dicho el Señor.

Y entre los sobrevivientes

estarán los llamados del Señor.