Joẹli 1 – YCB & CST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Joẹli 1:1-20

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Joẹli ọmọ Petueli wá.

Ìṣígun Eṣú

2Ẹ gbọ́ èyí ẹ̀yin àgbàgbà;

ẹ fi etí sílẹ̀ gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ará ilẹ̀ náà.

Ǹjẹ́ irú èyí ha wà ní ọjọ́ yín,

tàbí ní ọjọ́ àwọn baba yín?

3Ẹ sọ ọ́ fún àwọn ọmọ yín,

ki àwọn ọmọ yín sọ fún àwọn ọmọ wọn,

ki àwọn ọmọ wọn sọ fún àwọn ìran mìíràn.

4Èyí tí eṣú tí agénijẹ jẹ kù

ní ọ̀wọ́ eṣú ńláńlá ti jẹ,

èyí tí ọ̀wọ́ eṣú ńláńlá jẹ kù

ní eṣú kéékèèkéé jẹ

Èyí tí eṣú kéékèèkéé jẹ kù

ni eṣú apanirun mìíràn jẹ.

5Ẹ jí gbogbo ẹ̀yin ọ̀mùtí kí ẹ sì sọkún

ẹ hu gbogbo ẹ̀yin ọ̀mu-wáìnì;

ẹ hu nítorí wáìnì tuntun

nítorí a gbà á kúrò lẹ́nu yín.

61.6: If 9.8.Nítorí orílẹ̀-èdè kan ti ṣígun sí ilẹ̀ mìíràn

ó ní agbára púpọ̀, kò sì ní òǹkà;

ó ní eyín kìnnìún

ó sì ní èrìgì abo kìnnìún.

7Ó ti pa àjàrà mi run,

ó sì ti ya ẹ̀ka igi ọ̀pọ̀tọ́ mi kúrò,

ó ti bò èèpo rẹ̀ jálẹ̀, ó sì sọ ọ́ nù;

àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ni a sì sọ di funfun.

8Ẹ pohùnréré ẹkún bí wúńdíá

tí a fi aṣọ ọ̀fọ̀ dí ni àmùrè, nítorí ọkọ ìgbà èwe rẹ̀.

9A ké ọrẹ jíjẹ́ àti ọrẹ mímu kúrò

ní ilé Olúwa;

àwọn àlùfáà ń ṣọ̀fọ̀, àwọn

ìránṣẹ́ Olúwa,

10Oko di ìgboro, ilẹ̀ ń ṣọ̀fọ̀,

nítorí a fi ọkà ṣòfò:

ọtí wáìnì tuntun gbẹ, òróró ń bùṣe.

11Kí ojú kí ó tì yín, ẹ̀yin àgbẹ̀;

ẹ pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùtọ́jú àjàrà,

nítorí alikama àti nítorí ọkà barle;

nítorí ìkórè oko ṣègbé.

12Àjàrà gbẹ, igi ọ̀pọ̀tọ́ sì rọ̀ dànù;

igi pomegiranate, igi ọ̀pẹ pẹ̀lú,

àti igi apiili, gbogbo igi igbó ni o rọ:

Nítorí náà ayọ̀ ọmọ ènìyàn gbẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn.

Ìpè fún ìrònúpìwàdà

13Ẹ di ara yín ni àmùrè,

sí pohùnréré ẹkún ẹ̀yin àlùfáà:

ẹ pohùnréré ẹkún, ẹ̀yin ìránṣẹ́ pẹpẹ:

ẹ wá, fi gbogbo òru dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀,

ẹ̀yin ìránṣẹ́ Ọlọ́run mi: nítorí tí a dá ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ

mímu dúró ní ilé Ọlọ́run yín.

14Ẹ yà àwẹ̀ kan sí mímọ́,

ẹ pe àjọ kan tí o ní ìrònú,

ẹ pe àwọn àgbàgbà,

àti gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà

jọ sí ilé Olúwa Ọlọ́run yín,

kí ẹ sí ké pe Olúwa.

15A! Fún ọjọ́ náà,

nítorí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀,

yóò de bí ìparun láti ọwọ́ Olódùmarè.

16A kò ha ké oúnjẹ kúrò níwájú

ojú wá yìí,

ayọ̀ àti inú dídùn kúrò nínú ilé

Ọlọ́run wá?

17Irúgbìn bàjẹ́ nínú ebè wọn,

a sọ àká di ahoro, a wó àká palẹ̀;

nítorí tí a mú ọkà rọ.

18Àwọn ẹranko tí ń kérora tó!

Àwọn agbo ẹran dààmú,

nítorí tí wọ́n kò ni pápá oko;

nítòótọ́, àwọn agbo àgùntàn jìyà.

19Olúwa, sí ọ ni èmi o ké pè,

nítorí iná tí run pápá oko tútù aginjù,

ọwọ́ iná sí ti jó gbogbo igi igbó.

20Àwọn ẹranko igbó gbé ojú sókè sí ọ pẹ̀lú:

nítorí tí àwọn ìṣàn omi gbẹ,

iná sí ti jó àwọn pápá oko aginjù run.

Nueva Versión Internacional (Castilian)

Joel 1:1-20

1Esta es la palabra del Señor, que vino a Joel hijo de Petuel.

La invasión de langostas

2¡Oíd esto, ancianos del pueblo!

¡Prestad atención, habitantes todos del país!

¿Alguna vez sucedió cosa semejante

en vuestros tiempos o en los de vuestros antepasados?

3Contádselo a vuestros hijos,

y que ellos se lo cuenten a los suyos,

y estos a la siguiente generación.

4Lo que dejaron las langostas grandes

lo devoraron las langostas pequeñas;

lo que dejaron las langostas pequeñas

se lo comieron las larvas;

y lo que dejaron las larvas

se lo comieron las orugas.1:4 El texto hebreo en este versículo usa cuatro términos que se refieren a langostas y que son de difícil traducción; también en 2:25.

5¡Despertad, borrachos, y llorad!

Gemid, todos los entregados al vino,

porque el vino dulce os fue arrebatado de los labios.

6Una nación poderosa e innumerable

ha invadido mi país:

tiene dientes de león,

colmillos de leona.

7Asoló mis vides,

desgajó mis higueras.

Las peló hasta dejar blancas sus ramas;

¡las derribó por completo!

8Mi pueblo gime como virgen vestida de luto

por la muerte de su prometido.

9Las ofrendas de cereales y las libaciones

no se ofrecen ya en la casa del Señor.

Hacen duelo los sacerdotes,

los ministros del Señor.

10Los campos yacen devastados,

reseca está la tierra;

han sido arrasados los cereales,

se ha secado el vino nuevo

y agotado el aceite.

11Secaos también vosotros, labradores;

gemid, viñadores,

por el trigo y la cebada,

porque se ha perdido la cosecha de los campos.

12La vid se marchitó;

languideció la higuera;

se marchitaron los granados,

las palmeras, los manzanos,

¡todos los árboles del campo!

¡Y hasta la alegría de la gente acabó por marchitarse!

Llamado al arrepentimiento

13Vestíos de duelo y gemid, sacerdotes;

lamentaos, ministros del altar.

Venid, ministros de mi Dios,

y pasad la noche vestidos de luto,

porque las ofrendas de cereales y las libaciones

han sido suspendidas en la casa de vuestro Dios.

14Proclamad ayuno,

convocad una asamblea solemne.

Reunid a los ancianos del pueblo

en la casa del Señor vuestro Dios;

reunid a todos los habitantes del país,

y clamad al Señor.

15¡Ay de aquel día, el día del Señor, que ya se aproxima!

Vendrá como devastación de parte del Todopoderoso.

16¿No se nos arrebató el alimento

ante nuestros propios ojos,

y la alegría y el regocijo

de la casa de nuestro Dios?

17La semilla se pudrió

a pesar de haber sido cultivada.1:17 La semilla … cultivada. Texto de difícil traducción.

Los silos están en ruinas

y los graneros, derribados

porque la cosecha se perdió.

18¡Cómo brama el ganado!

Vagan sin rumbo las vacas

porque no tienen donde pastar,

y sufren también las ovejas.

19A ti clamo, Señor,

porque el fuego ha devorado los pastizales de la estepa;

las llamas han consumido todos los árboles silvestres.

20Aun los animales del campo te buscan con ansiedad,

porque se han secado los arroyos

y el fuego ha devorado los pastizales de la estepa.