Joṣua 2 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Joṣua 2:1-24

Rahabu àti àwọn Ayọ́lẹ̀wò

12.1: Hb 11.31; Jk 2.25.Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.

2A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.” 3Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé: “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”

4Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá. 5Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.” 6(Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.) 7Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.

8Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà. 9Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín. 10Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá. 11Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé. 12Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní ààmì tó dájú: 13pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”

14“Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”

15Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú. 16Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”

17Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí. 18Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ. 19Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án. 20Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”

21Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.”

Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.

22Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn. 23Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn. 24Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”

Nouă Traducere În Limba Română

Iosua 2:1-24

Trimiterea cercetașilor la Ierihon, în casa lui Rahab

1După aceea, Iosua, fiul lui Nun, a trimis în secret, din Șitim, doi cercetași, zicând: „Duceți‑vă să cercetați țara și mai ales Ierihonul!“

Ei au plecat și au intrat în casa unei prostituate numită Rahab, culcându‑se acolo.

2Regelui Ierihonului i s‑a zis: „Iată că niște bărbați dintre fiii lui Israel au venit aici, în timpul nopții, ca să cerceteze țara.“

3Atunci regele Ierihonului a trimis să i se spună prostituatei Rahab:

– Scoate‑i afară pe bărbații care au venit la tine și au intrat în casa ta, fiindcă au venit să cerceteze întreaga țară!

4Femeia însă îi luase pe cei doi bărbați și‑i ascunsese.

Ea a răspuns:

– Este adevărat că acei bărbați au venit la mine, dar nu știam de unde sunt. 5Când s‑a făcut noapte și poarta urma să fie închisă, bărbații au ieșit și nu știu unde s‑au dus. Urmăriți‑i repede și îi veți ajunge!

6Ea îi urcase pe acoperiș și îi ascunsese printre snopii de in pe care‑i avea întinși pe acoperiș.

7Ei i‑au urmărit pe drumul care duce la vadurile Iordanului. După ce au ieșit urmăritorii, poarta s‑a închis în urma lor.

8Înainte să se culce cercetașii, Rahab s‑a urcat la ei pe acoperiș.

9Ea le‑a zis bărbaților:

– Știu că Domnul v‑a dat țara aceasta. Din cauza voastră a căzut groaza peste noi, iar locuitorii țării sunt topiți de frică. 10Am auzit cum, la ieșirea voastră din Egipt, Domnul a secat înaintea voastră apele Mării Roșii10 Ebr.: Yam Suf (lit.: Marea Trestiilor sau Marea Algelor– vezi Iona 2:5, unde același termen ebraic, suf, are sensul de alge). Denumirea de Marea Roșie a fost introdusă în traducerile moderne prin LXX și Vulgata. În VT însă, sintagma ebraică denumea actualul Golf Aqaba, la sud de Elat. Chiar și astăzi localnicii numesc Golful Aqaba Yam Suf. Vezi 1 Regi 9:26. și am aflat ce le‑ați făcut lui Sihon și lui Og, cei doi regi amoriți de la răsărit de Iordan, pe care i‑ați dat spre nimicire10 Ebr.: haram/herem, termen care se referă la un lucru, un animal sau o persoană care erau închinate irevocabil Domnului, fie cu scopul nimicirii, precum în cazul acesta, fie ca dar, precum în alte cazuri. Ceea ce era herem îi aparținea de acum Domnului, fiind interzis uzului profan.. 11Când am auzit lucrurile acestea, ni s‑au înmuiat inimile și fiecare om și‑a pierdut curajul din cauza voastră, fiindcă Domnul, Dumnezeul vostru, este Dumnezeu sus în ceruri și jos pe pământ!

12Acum deci, vă rog, jurați‑mi pe Domnul că veți arăta față de familia tatălui meu, aceeași bunătate pe care și eu am avut‑o față de voi. Dați‑mi un semn demn de încredere 13că‑i veți lăsa în viață pe tatăl meu, mama mea, frații mei și surorile mele împreună cu tot ce au și că ne veți scăpa sufletele de la moarte.

14Bărbații i‑au răspuns:

– Suntem gata să ne dăm viața pentru voi, dacă nu ne vei trăda. Iar atunci când Domnul ne va da țara, ne vom purta cu tine cu îndurare și credincioșie.

15Ea i‑a coborât atunci prin fereastră cu o frânghie, căci casa ei era parte din zid, ea locuind chiar în zid.

16Apoi le‑a zis:

– Mergeți spre munte, ca să nu vă întâlniți cu cei care vă urmăresc, și ascundeți‑vă acolo timp de trei zile, până se vor întoarce. După aceea veți putea să vă continuați drumul.

17Bărbații i‑au spus:

– Noi vom fi dezlegați de jurământul acesta, pe care ne‑ai pus să‑l facem, 18dacă atunci când vom intra în țară nu vei lega această frânghie din fir cărămiziu de fereastra prin care ne‑ai coborât și dacă nu vei aduce în casa ta pe tatăl tău, pe mama ta și pe frații tăi, toată familia ta. 19Dacă cineva va ieși afară, dincolo de porțile casei tale, sângele lui va cădea asupra capului său, iar noi vom fi nevinovați. Dar dacă va pune cineva mâna pe vreunul din cei ce vor fi în casă cu tine, sângele lui va cădea asupra capului nostru. 20Dacă ne vei trăda, atunci vom fi dezlegați de jurământul acesta, pe care ne‑ai pus să‑l facem.

21Ea le‑a răspuns:

– Să fie precum ați spus!

Apoi i‑a trimis, și ei au plecat, iar ea a legat frânghia cărămizie de fereastră. 22Ei s‑au dus și au ajuns la munte, unde au rămas trei zile, până când s‑au întors cei care îi urmăreau și care îi căutaseră de‑a lungul întregului drum fără să‑i găsească. 23Apoi cei doi bărbați s‑au întors, au coborât muntele și au traversat Iordanul. Au venit la Iosua, fiul lui Nun, și i‑au istorisit tot ce li s‑a întâmplat. 24Ei i‑au spus lui Iosua: „Într-adevăr, Domnul a dat în mâinile noastre întreaga țară și toți locuitorii țării tremură înaintea noastră!“