Joṣua 1 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Joṣua 1:1-18

Olúwa pàṣẹ fún Joṣua

1Lẹ́yìn ikú u Mose ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Joṣua ọmọ Nuni, olùrànlọ́wọ́ ọ Mose: 2“Mose ìránṣẹ́ mi ti kú. Nísinsin yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹ múra láti kọjá odò Jordani lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Israẹli. 3Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Mose. 4Ilẹ̀ ẹ yín yóò fẹ̀ láti aginjù Lebanoni, àti láti odò ńlá, ti Eufurate—gbogbo orílẹ̀-èdè Hiti títí ó fi dé Òkun ńlá ní ìwọ̀-oòrùn. 51.5: Hb 13.5.Kì yóò sí ẹnikẹ́ni tí yóò le è dúró níwájú rẹ ní ọjọ́ ayé è rẹ gbogbo. Bí mo ti wà pẹ̀lú u Mose, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, Èmi kì yóò fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Èmi kì yóò kọ̀ ọ́.

6“Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le, nítorí ìwọ ni yóò ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, láti lè jogún ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fi fún wọn. 7Jẹ́ alágbára, kí o sì mú àyà le gidigidi. Kí o sì ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin tí Mose ìránṣẹ́ mi fún ọ mọ́, Má ṣe yà kúrò nínú u rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì, kí ìwọ kí ó lè ṣe rere níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ. 8Má ṣe jẹ́ kí Ìwé Ofin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ọ̀sán àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí. 9Èmi kò ha ti pàṣẹ fún ọ bí? Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le. Má ṣe bẹ̀rù, má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì, nítorí pé Olúwa à rẹ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”

10Báyìí ni Joṣua pàṣẹ fún olórí àwọn ènìyàn rẹ̀ 11“Ẹ la ibùdó já, kí ẹ sì sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Ẹ pèsè oúnjẹ yín sílẹ̀. Ní ìwòyí ọ̀túnla, ẹ̀yin yóò la Jordani yìí kọjá, láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín láti ní.’ ”

121.12-18: Jo 22.1-34; Nu 32.4-22.Ṣùgbọ́n Joṣua sọ fún àwọn ará a Reubeni, àwọn ará Gadi àti fún ìdajì ẹ̀yà Manase pé, 13“Rántí àṣẹ tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pa fún yín: ‘Olúwa Ọlọ́run yín á fún yin ní ìsinmi, òun yóò sì fún un yín ní ilẹ̀ yìí.’ 14Àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín lè dúró ní ilẹ̀ tí Mose fún un yin ní ìlà-oòrùn Jordani; ṣùgbọ́n gbogbo àwọn jagunjagun un yín, pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín. Ẹ̀yin yóò sì rán àwọn arákùnrin yín lọ́wọ́ 15títí Olúwa yóò fi fún wọn ní ìsinmi, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún un yín, àti títí tí àwọn pẹ̀lú yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún wọn. Lẹ́yìn náà, ẹ̀yin lè padà sí ilẹ̀ ìní in yín, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún un yin ní agbègbè ìlà-oòrùn ti Jordani.”

16Nígbà náà ni wọ́n dá Joṣua lóhùn pé, “Ohunkóhun tí ìwọ pàṣẹ fún wa ni àwa yóò ṣe, ibikíbi tí ìwọ bá rán wa ni àwa yóò lọ. 17Gẹ́gẹ́ bí àwa ti gbọ́rọ̀ sí Mose nínú ohun gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò máa gbọ́ tìrẹ. Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà pẹ̀lú u Mose. 18Ẹnikẹ́ni tí ó bá tàpá sí ọ̀rọ̀ rẹ, tí kò sì ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ nínú ohun gbogbo tí ìwọ yóò pàṣẹ fún wọn, pípa ni a ó pa á. Kí ìwọ sá à ṣe gírí, kí ó sì mú àyà le!”

Nouă Traducere În Limba Română

Iosua 1:1-18

Iosua – noul conducător al lui Israel

1După moartea lui Moise, robul Domnului, Domnul i‑a vorbit lui Iosua, fiul lui Nun, slujitorul lui Moise, zicând:

2„Moise, robul Meu, a murit. Acum deci ridică‑te, traversează Iordanul, tu împreună cu tot poporul acesta, spre țara pe care o dau fiilor lui Israel. 3Vă voi da orice teritoriu peste care va călca talpa piciorului vostru, întocmai cum i‑am promis lui Moise. 4Teritoriul vostru se va întinde de la pustie până la Liban și de la Râul cel Mare, râul Eufrat, cuprinzând toată țara hitiților, până la Marea cea Mare4 Marea Mediterană., în apus. 5Niciun om nu‑ți va putea sta împotrivă cât vei trăi. Cum am fost cu Moise, tot așa voi fi și cu tine! Nu te voi lăsa și nu te voi părăsi!

6Fii tare și curajos, pentru că tu vei da în stăpânire acestui popor țara pe care am jurat că le‑o voi da părinților lor. 7Fii deci tare și foarte curajos, veghind să împlinești toată Legea pe care ți‑a poruncit‑o robul Meu Moise. Nu te abate de la ea nici la dreapta, nici la stânga, ca să prosperi oriunde vei merge. 8Cartea aceasta a Legii să nu să se depărteze de gura ta! Meditează asupra ei zi și noapte, veghind, astfel încât să poți împlini tot ceea ce este scris în ea, căci atunci vei reuși oriunde vei merge și vei prospera! 9Oare nu Eu ți‑am poruncit: fii tare și curajos! Nu te îngrozi și nu te înspăimânta, fiindcă Domnul, Dumnezeul tău, este cu tine oriunde vei merge!“

10Iosua le‑a poruncit supraveghetorilor poporului, zicând: 11„Treceți prin tabără și porunciți poporului, zicând: «Pregătiți‑vă provizii, căci peste trei zile veți traversa Iordanul ca să intrați și să luați în stăpânire țara pe care Domnul, Dumnezeul vostru, v‑o dă ca moștenire.»“

12Iosua le‑a zis rubeniților, gadiților și unei jumătăți a seminției lui Manase:

13– Aduceți‑vă aminte ce v‑a poruncit Moise, robul Domnului, când a zis: „Domnul, Dumnezeul vostru, vă dă odihnă și vă dă țara aceasta.“ 14Prin urmare, soțiile voastre, copiii voștri și vitele voastre să rămână în țara pe care v‑a dat‑o Moise în partea aceasta a Iordanului. Însă toți războinicii viteji să traverseze înarmați înaintea fraților voștri ca să‑i ajute, 15până când Domnul, Dumnezeul vostru, va da odihnă fraților voștri asemenea vouă și până când vor lua și ei în stăpânire țara pe care Domnul, Dumnezeul vostru, le‑o dă. După aceea vă veți întoarce să stăpâniți țara care v‑a fost dată ca moștenire de către Moise, robul Domnului, dincoace de Iordan, spre răsăritul soarelui.

16Ei i‑au răspuns lui Iosua, zicând:

– Vom face tot ceea ce ne‑ai poruncit și vom merge oriunde ne vei trimite! 17Te vom asculta tot așa cum l‑am ascultat și pe Moise! Numai să fie acum Domnul, Dumnezeul tău, și cu tine la fel cum a fost cu Moise. 18Orice om care se va răzvrăti împotriva poruncii tale și care nu va asculta de toate cuvintele pe care ni le poruncești, va fi omorât. Tu însă fii tare și curajos!