Jeremiah 52 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 52:1-34

Ìṣubú Jerusalẹmu

1Sedekiah jẹ́ ọmọ ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó jẹ ọba. Ọdún mọ́kànlá ló fi jẹ ọba ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Hamutali ọmọ Jeremiah; láti Libina ló ti wá. 252.2: 2Ọb 24.18–25.30; 2Ki 36.11-13.Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa gẹ́gẹ́ bí Jehoiakimu ti ṣe 3Nítorí ìbínú Olúwa ni gbogbo èyí ṣe ṣẹlẹ̀ sí Jerusalẹmu àti Juda àti ní ìkẹyìn. Ó sì gbà wọ́n gbọ́ ní iwájú rẹ̀.

Sedekiah ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Babeli.

4Nígbà tí ó di ọdún kẹsànán ti Sedekiah tí ń ṣe ìjọba ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù kẹwàá Nebukadnessari ọba Babeli sì lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọ́n pàgọ́ sí ẹ̀yìn odi ìlú náà; wọ́n sì mọ odi yíká rẹ̀. 5Ìlú náà sì wá lábẹ́ ìhámọ́ títí di ọdún kọkànlá ọba Sedekiah.

6Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù mẹ́rin ìyàn ìlú náà sì ti burú dé ibi pé kò sí oúnjẹ kankan mọ́ fún àwọn ènìyàn láti jẹ. 7Bákan náà, odi ìlú náà ti ya àwọn ọmọ-ogun sì tí sálọ. Wọn fi ìlú náà sílẹ̀ ní òru nípa ojú ọ̀nà tó wà láàrín odi méjèèjì lẹ́bàá ọgbà ọba. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, Àwọn ará Babeli yìí yí ìlú náà ká. Wọ́n sá gba aginjù lọ. 8Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ogun Babeli lépa ọba Sedekiah wọ́n sì le bá ni pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko. Gbogbo àwọn ọmọ-ogun sì pínyà, kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ wọ́n sì túká. 9Wọ́n sì mu ní ìgbèkùn.

Wọn mú un lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babeli, ní Ribla ní ilẹ̀ Hamati níbẹ̀ ni ó ti ṣe ìdájọ́ lórí rẹ̀. 10Ní Ribla ni ọba Babeli ti pa ọmọkùnrin Sedekiah lójú rẹ̀; ó sì tún pa gbogbo àwọn aláṣẹ Juda. 11Lẹ́yìn náà, ọba Babeli yọ Sedekiah ní ojú, o sì fi ẹ̀wọ̀n dè é, ó sì gbe e lọ sí Babeli níbi tí ó ti fi sínú ọgbà ẹ̀wọ̀n títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.

12Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù karùn-ún, tí ó jẹ́ ọdún kọkàn-dínlógún Nebukadnessari ọba Babeli, ni Nebusaradani balógun ìṣọ́ wá sí Jerusalẹmu. 13Ó dáná sun pẹpẹ Olúwa, ààfin ọba àti gbogbo àwọn ilé Jerusalẹmu. Ó sì dáná sun gbogbo àwọn ilé ńláńlá. 14Gbogbo àwọn ogun Babeli, tí ó wà lọ́dọ̀ olórí ẹ̀ṣọ́, wó ògiri tí ó yí Jerusalẹmu ká lulẹ̀. 15Nebusaradani balógun ìṣọ́ kó gbogbo àwọn tálákà àti gbogbo àwọn tí ó kù ní ìlú, ní ìgbèkùn lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn tí ó ya lọ, tí ó sì ya tọ ọba Babeli lọ, àti ìyókù àwọn ènìyàn náà. 16Ṣùgbọ́n Nebusaradani, balógun ìṣọ́ fi àwọn tálákà tó kú ní ilẹ̀ náà sílẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ nínú ọgbà àjàrà àti ro oko.

17Àwọn ará Babeli fọ́ ọ̀wọ̀n idẹ wọ̀n-ọn-nì àti àwọn ìjókòó wọ̀n-ọn-nì, àti agbada idẹ títóbi wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ilé Olúwa, àwọn ará Babeli fọ́ túútúú, Wọ́n sì kó gbogbo idẹ náà lọ sí Babeli. 18Bákan náà, wọ́n tún kó àwọn ìkòkò wọ̀n-ọn-nì, ọkọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ọ̀pá fìtílà wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọpọ́n wọ̀n-ọn-nì, ṣíbí wọ̀n-ọn-nì àti gbogbo ohun èlò idẹ tí wọ́n ń lò níbi pẹpẹ lọ. 19Balógun ìṣọ́ náà kó àwokòtò wọ̀n-ọn-nì, ohun ìfọnná wọ̀n-ọn-nì, ọpọ́n wọ̀n-ọn-nì, ìkòkò wọ̀n-ọn-nì, ọ̀pá fìtílà wọ̀n-ọn-nì, ṣíbí wọ̀n-ọn-nì àti ago wáìnì wọ̀n-ọn-nì; èyí tí a fi wúrà àti fàdákà ṣe lọ.

20Àwọn ọ̀wọ́n méjì, agbada ńlá kan àti àwọn màlúù idẹ méjìlá tí ó wà lábẹ́ ìjókòó alágbéká tí Solomoni ọba ṣe fún ilé Olúwa, idẹ ni gbogbo ohun èlò wọ̀nyí, ó ju èyí tí a lè wọ́n lọ. 21Ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọ̀wọ́n yìí ni ga ní ìwọ̀n ìgbọ̀nwọ́ méjì-dínlógún; okùn ìgbọ̀nwọ́ méjìlá sì yí i ká. Ọ̀kọ̀ọ̀kan nípọn tó ìka mẹ́rin, wọ́n sì ní ihò nínú. 22Ọ̀nà orí idẹ kan tó ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún ní gíga, wọ́n sì fi èso pomegiranate ṣe ọ̀ṣọ́ sí i lára yíká. Ọ̀wọ́n kejì sì wà pẹ̀lú èso pomegiranate tí ó jọra. 23Pomegiranate mẹ́rìn-dínlọ́gọ́rùn-ún ni ó wà ní àwọn ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àpapọ̀ gbogbo pomegiranate sì jẹ́ ọgọ́rùn-ún kan.

24Balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ mu Seraiah olórí àwọn àlùfáà àti Sefaniah àlùfáà kejì àti àwọn olùṣọ́ ìloro mẹ́ta. 25Nínú àwọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà, ó mú ìwẹ̀fà kan, tí ó wà ní ìtọ́jú àwọn ológun, àti àwọn olùdámọ̀ràn ọba méje. Bákan náà, ó tún mu akọ̀wé olórí ogun tí ó wà ní ìtọ́jú títo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti ọgọ́ta nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀ tí wọ́n rí ní ìlú náà. 26Nebusaradani, balógun ìṣọ́ kó gbogbo wọn, ó sì mú wọn tọ ọba Babeli wá ní Ribla. 27Ọba Babeli sì kọlù wọ́n, ó sì pa wọ́n ní Ribla ni ilẹ̀ Hamati.

Báyìí ni a mú Juda kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀.

28Èyí ni iye àwọn ènìyàn tí Nebukadnessari kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì.

Ní ọdún keje ẹgbẹ̀ẹ́dógún ó-lé-mẹ́tàlélógún (3,023) ará Juda.

29Ní ọdún kejì-dínlógún Nebukadnessari

o kó ẹgbẹ̀rún ó-lé-méjì-dínlọ́gbọ̀n láti Jerusalẹmu.

30Ní ọdún kẹtàlélógún àwọn Júù

tí Nebusaradani kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì jẹ́ ọ̀tà-dínlẹ́gbẹ̀rin-ó-dín-márùn-ún (745).

Gbogbo ènìyàn tí ó kó lápapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀tàlélógún.

Ìtúsílẹ̀ Jehoiakimu

31Ní ọdún kẹtà-dínlógójì ti Jehoiakini ọba Juda ni Efili-Merodaki di ọba Babeli. Ó gbé orí Jehoiakini ọba Juda sókè, ó sì tú sílẹ̀ nínú túbú ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù kejìlá. 32Ó ń sọ̀rọ̀ rere fún un, ó sì gbé ìtẹ́ rẹ̀ ga ju ìtẹ́ àwọn ọba tókù lọ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Babeli. 33Nítorí náà, Jehoiakini pàrọ̀ aṣọ túbú rẹ̀, ó sì ń jẹun ní gbogbo ìgbà ní iwájú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀. 34Ní ojoojúmọ́ ni ọba Babeli ń fún Jehoiakini ní ìpín tirẹ̀ bí ó tí ń bẹ láààyè, títí di ọjọ́ kú rẹ̀.

Persian Contemporary Bible

ارميا 52:1-34

سقوط اورشليم

(وقايع اين باب مربوط به باب 39 می‌باشد)

1صدقيا بيست و یک ساله بود كه پادشاه شد و يازده سال در اورشليم سلطنت كرد. اسم مادرش حميطل (دختر ارميای لبنه‌ای) بود. 2صدقيا مثل يهوياقيم، آنچه در نظر خداوند نادرست بود، به عمل آورد. 3در آن زمان، خشم خداوند بر اورشليم و يهودا افروخته شد و ايشان را از خود طرد نمود و كاری كرد كه صدقيا عليه پادشاه بابل قيام كند تا بدين ترتيب بنی‌اسرائيل از سرزمينشان بيرون رانده شوند.

4لذا، در روز دهم ماه دهم از سال نهم سلطنت صدقيا، نبوكدنصر، پادشاه بابل، با تمام سپاهيان خود به اورشليم لشكركشی كرد و در اطراف آن سنگر ساخت. 5شهر، دو سال در محاصره بود. 6سرانجام در روز نهم ماه چهارم كه قحطی در شهر بيداد می‌كرد و آخرين ذخيرهٔ نان هم تمام شده بود، 7مردم اورشليم، شكافی در ديوار شهر ايجاد كردند. سربازان وقتی اين را ديدند، عليرغم محاصرهٔ شهر، شبانه از دروازه‌هايی كه بين دو ديوار نزديک باغهای پادشاه بود، بيرون رفتند و به طرف درهٔ اردن گريختند.

8ولی سربازان بابلی، ايشان را تعقيب كردند و در بيابانهای اطراف اريحا، صدقيای پادشاه را گرفتند، ولی محافظين او فرار كردند. 9سپس او را به حضور پادشاه بابل كه در شهر ربله در سرزمين حمات مستقر شده بود، آوردند و پادشاه بابل در آنجا حكم محكوميت او را صادر كرد، 10و در برابر او، تمام پسرانش و بزرگان يهودا را كشت. 11سپس چشمان او را از حدقه درآورد و او را با زنجيرها بسته، به بابل برد و تا آخر عمر در زندان نگه داشت.

تخريب اورشليم و تبعيد مردم

12در روز دهم ماه پنجم از سال نوزدهم سلطنت نبوكدنصر، پادشاه بابل، نبوزرادان فرمانده سپاه بابل و مشاور پادشاه، وارد اورشليم شد 13و خانه خداوند، كاخ سلطنتی و تمام خانه‌های بزرگ شهر را به آتش كشيد، 14و سربازانش ديوار شهر را خراب كردند. 15آنگاه عده‌ای از فقرای يهودا را با آنانی كه در اورشليم زنده مانده بودند و كسانی كه صدقيا را ترک كرده و به بابلی‌ها پيوسته بودند، و صنعتگران باقی مانده در شهر را به بابل تبعيد كرد. 16تنها عده‌ای فقير را برای كار كشاورزی و باغبانی در آنجا باقی گذاشت.

17بابلی‌ها، دو ستون مفرغی را كه در قسمت ورودی خانه خداوند قرار داشت و حوضچهٔ مفرغی و گاوهای مفرغی زير حوضچه را برداشتند و به بابل بردند. 18‏-19نبوزرادان تمام ديگهای بزرگ و كوچک مفرغی و خاک‌اندازها را كه برای قربانگاه به کار می‌رفت و انبرها، قاشقها، كاسه‌ها و تمام ظروف ديگر مفرغی خانهٔ خدا را با خود برد. او همچنين انبرها، چراغدانها، پياله‌ها و كاسه‌های طلا و نقره را به همراه برد.

20دو ستون و حوضچه و دوازده گاو مفرغی كه زير حوضچه قرار داشت به قدری سنگين بودند كه وزن كردن آنها امكان‌پذير نبود. تمام اينها در زمان سليمان پادشاه ساخته شده بود. 21بلندی هر ستون در حدود هشت متر و محيط آن در حدود پنج متر و نيم و ضخامت ديوارهاش چهار انگشت بود و میان‌تهی بود، 22و هر يک از آنها نيز سر ستونی مفرغی به بلندی دو متر و نيم داشت و گرداگرد هر سر ستون، انارهای مفرغی، كنده‌كاری شده بود؛ 23روی هر سر ستون، يكصد انار وجود داشت، ولی از پايين فقط نود و شش انار را می‌شد ديد.

24‏-25در ضمن نبوزرادان، فرماندهٔ سپاه بابل اين افراد را نيز در مخفیگاههايشان در شهر پيدا كرد:

سرايا، كاهن اعظم و معاون او صفنيا، سه نفر از نگهبانان خانهٔ خدا، يكی از فرماندهان لشكر با هفت نفر از مشاوران مخصوص پادشاه، کاتب فرماندهٔ سپاه يهودا (كه مسئول ثبت تعداد سربازان بود) و شصت نفر از اشخاص مهم ديگر. 26نبوزرادان ايشان را به ربله نزد پادشاه بابل برد، 27و پادشاه در آنجا همه را كشت.

به اين ترتيب اهالی يهودا به بابل تبعيد شدند. 28تعداد اسيرانی كه در سال هفتم سلطنت نبوكدنصر به بابل برده شدند، ۳,۰۲۳ نفر بود. 29يازده سال بعد، او ۸۳۲ نفر ديگر را هم اسير كرد و به بابل برد. 30پنج سال بعد از آن، نبوزرادان فرماندهٔ سپاه بابل، ۷۴۵ نفر ديگر را تبعيد كرد. بنابراين، در مجموع، ۴,۶۰۰ نفر تبعيد شدند.

31در روز بيست و پنجم ماه دوازدهم از سی و هفتمين سال اسيری يهوياكين، پادشاه يهودا، اويل مرودک به پادشاهی بابل رسيد و يهوياكين را مورد لطف خود قرار داد و او را از زندان بيرون آورد. 32او با يهوياكين رفتاری مهرآميز در پيش گرفت و او را بر تمام پادشاهان تبعيدی در بابل برتری داد، 33لباس نو به او پوشاند و از آن پس، او هميشه با پادشاه بابل سر سفره می‌نشست. 34اويل مرودک تا روزی كه يهوياكين زنده بود، برای رفع احتياجاتش به او مقرری می‌پرداخت.