Ẹkun Jeremiah 1 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ẹkun Jeremiah 1:1-22

1Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan,

nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn!

Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,

tí ó wà ní ipò opó,

Ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú

ni ó padà di ẹrú.

2Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò

pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀.

Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀

kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún.

Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀

wọ́n ti di alátakò rẹ̀.

3Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú,

Juda lọ sí àjò

Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,

ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi.

Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́

ibi tí kò ti le sá àsálà.

4Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀,

nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn.

Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro,

àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn,

àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú,

òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.

5Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀,

nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀,

Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́

nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú,

ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.

6Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé

kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni.

Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín

tí kò rí ewé tútù jẹ;

nínú àárẹ̀ wọ́n sáré

níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.

7Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni

Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀

tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́.

Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá,

kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un.

Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó

wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.

8Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀

ó sì ti di aláìmọ́.

Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀,

nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀;

ó kérora fúnrarẹ̀,

ó sì lọ kúrò.

9Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀,

Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu;

olùtùnú kò sì ṣí fún un.

“Wo ìpọ́njú mi, Olúwa,

nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”

10Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé

gbogbo ìní rẹ;

o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè

tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ—

àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀

láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.

11Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora

bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ;

wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ

láti mú wọn wà láààyè.

“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó,

nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”

12“Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín?

Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá,

Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà

tí a fi fún mi, ti

Olúwa mú wá fún mi

ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.

13“Ó rán iná láti òkè

sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi.

Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi,

ó sì yí mi padà.

Ó ti pa mí lára

mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.

14“Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà;

ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀.

Wọ́n ti yí ọrùn mi ká

Olúwa sì ti dín agbára mi kù.

Ó sì ti fi mí lé

àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.

15“Olúwa kọ

àwọn akọni mi sílẹ̀,

ó rán àwọn ológun lòdì sí mi

kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run.

Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́

àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.

16“Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún

tí omijé sì ń dà lójú mi,

Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi,

kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà.

Àwọn ọmọ mi di aláìní

nítorí ọ̀tá ti borí.”

17Sioni na ọwọ́ jáde,

ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un.

Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu

pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un

Jerusalẹmu ti di

ohun aláìmọ́ láàrín wọn.

18“Olóòtítọ́ ni Olúwa,

ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀.

Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn;

ẹ wò mí wò ìyà mi.

Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi

ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.

19“Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi

ṣùgbọ́n wọ́n dà mí.

Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi

ṣègbé sínú ìlú

nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ

tí yóò mú wọn wà láààyè.

20Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira!

Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi,

ìdààmú dé bá ọkàn mi

nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi.

Ní gbangba ni idà ń parun;

ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.

21“Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi,

ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi.

Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi;

wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe.

Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde,

kí wọ́n le dàbí tèmi.

22“Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ;

jẹ wọ́n ní yà

bí o ṣe jẹ mí ní yà

nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi.

Ìrora mi pọ̀

ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”

Persian Contemporary Bible

مراثی 1:1-22

1اورشليم كه زمانی پرجمعيت بود اينک متروک شده است! شهری كه در بين قومها محبوب بود اينک بيوه گشته است! او كه ملكهٔ شهرها بود اينک برده شده است!

2اورشليم تمام شب می‌گريد و قطره‌های اشک روی گونه‌هايش می‌غلتد. از ميان يارانش يكی هم باقی نمانده كه او را تسلی دهد. دوستانش به او خيانت كرده و همگی با او دشمن شده‌اند.

3مردم مصيبت‌زده و رنجديدهٔ يهودا به اسارت رفته‌اند؛ به ديار غربت تبعيد شده‌اند و اينک هيچ آسايش ندارند. دشمنان، آنها را احاطه نموده عرصه را بر آنها تنگ كرده‌اند.

4ديگر كسی به خانهٔ خدا نمی‌آيد تا در روزهای عيد عبادت كند. دخترانی كه سرود می‌خواندند اينک عزادارند، و كاهنان تنها آه می‌كشند. دروازه‌های شهر، متروک شده و اورشليم در ماتم فرو رفته است.

5دشمنانش بر او غلبه يافته كامياب شده‌اند. خداوند اورشليم را برای گناهان بسيارش تنبيه كرده است. دشمنان، فرزندان او را اسير كرده، به ديار غربت به بردگی برده‌اند.

6تمام شكوه و زيبايی اورشليم از دست رفته است. بزرگانش مانند غزالهای گرسنه دنبال چراگاه می‌گردند و ناتوانتر از آنند كه بتوانند از چنگ دشمن فرار كنند.

7اينک اورشليم در ميان مصیبتها، روزهای پرشكوه گذشته را به ياد می‌آورد. زمانی كه او به محاصرهٔ دشمن درآمد، هيچ مدد كننده‌ای نداشت؛ دشمن او را مغلوب كرد و به شكست او خنديد.

8اورشليم گناهان بسياری مرتكب شده و ناپاک گرديده است. تمام كسانی كه او را تكريم می‌كردند، اينک تحقيرش می‌كنند، زيرا برهنگی و خواری او را ديده‌اند. او می‌نالد و از شرم، چهرهٔ خود را می‌پوشاند.

9لكهٔ ننگی بر دامن اورشليم بود، اما او اعتنايی نكرد؛ او به عاقبت خود نيانديشيد و ناگهان سقوط كرد. اينک كسی نيست كه او را تسلی دهد. او از خداوند رحمت می‌طلبد، زيرا دشمن بر او غالب آمده است.

10دشمن، گنجينه‌های او را غارت كرد و قومهای بيگانه در برابر چشمانش به عبادتگاه مقدسش داخل شدند، قومهایی كه خدا ورود آنها را به عبادتگاهش قدغن كرده بود.

11اهالی اورشليم برای يک لقمه نان آه می‌كشند. هر چه داشتند برای خوراک دادند تا زنده بمانند. اورشليم می‌گويد: «خداوندا، ببين چگونه خوار شده‌ام!

12«ای كسانی كه از كنارم می‌گذريد، چرا به من نگاه نمی‌كنيد؟ نگاهی به من بيندازيد و ببينيد آيا غمی همچون غم من وجود دارد؟ ببينيد خداوند به هنگام خشم خود به من چه كرده است!

13«او از آسمان آتش نازل كرد و تا مغز استخوان مرا سوزاند. سر راهم دام گسترد و مرا به زمين كوبيد. او مرا ترک گفت و در غمی بی‌پايان رهايم كرد.

14«گناهانم را به هم بافت و همچون طنابی بر گردنم انداخت و مرا زير يوغ بردگی كشاند. تمام توانم را گرفت و مرا در چنگ دشمنانم كه قويتر از من بودند رها كرد.

15«خداوند تمام سربازان شجاع مرا از من گرفت. او لشكری بر ضد من فرا خواند تا جوانان مرا از بين ببرند. خداوند شهر محبوب خود را همچون انگور در چرخشت پايمال كرد.

16«برای اين مصيبتهاست كه می‌گريم و قطره‌های اشک بر گونه‌هايم می‌غلتد. آن كه به من دلداری می‌داد و جانم را تازه می‌ساخت از من دور شده است. دشمن بر من غالب آمده و فرزندانم بی‌كس شده‌اند.

17«دستهای خود را دراز می‌كنم و كمک می‌طلبم، اما كسی نيست كه به دادم برسد. خداوند قومهای همسايه را بر ضد من فرا خوانده و من مورد نفرت آنان قرار گرفته‌ام.

18«اما خداوند عادلانه حكم فرموده است، زيرا من از فرمان او سرپيچی كرده بودم. ای مردم جهان، اندوه مرا بنگريد و ببينيد چگونه پسران و دخترانم را به اسيری برده‌اند.

19«از ياران كمک خواستم، اما ايشان به من خيانت كردند. كاهنان و ريش‌سفيدان در حالی كه به دنبال لقمه نانی بودند تا خود را زنده نگه دارند، در كوچه‌های شهر از گرسنگی جان دادند.

20«ای خداوند، ببين چقدر پريشان و نگرانم! به خاطر گناهانی كه انجام داده‌ام جانم در عذاب است. در خانه، بلای كشنده در انتظارم است و در بيرون، شمشير مرگبار.

21«مردم ناله‌هايم را می‌شنوند، اما كسی به دادم نمی‌رسد. دشمنانم چون شنيدند چه بلايی بر سرم آوردی، شاد شدند. ای خداوند، به وعده‌ات وفا كن و بگذار دشمنانم نيز به بلای من دچار گردند.

22«به گناهان آنها نيز نظر كن و همانگونه كه مرا برای گناهانم تنبيه كرده‌ای، آنان را نيز به سزای كردارشان برسان. ناله‌های من بسيار و دلم بی‌تاب است.»