Isaiah 66 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 66:1-24

Ìdájọ́ àti ìrètí

166.1-2: Mt 5.34; Ap 7.49-50.Báyìí ni Olúwa wí:

“Ọ̀run ni ìtẹ́ mi,

ayé sì ni àpótí ìtìsẹ̀ mi,

Níbo ni ilé tí ẹ ó kọ́ fún mi wà?

Níbo ní ibi ìsinmi mi yóò gbé wà?

2Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí,

bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?”

ni Olúwa wí.

“Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí:

ẹni náà tí ó rẹra rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀,

tí ó sì wárìrì sí ọ̀rọ̀ mi.

3Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rú ẹbọ

ó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kan

àti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́-àgùntàn kan tọrẹ,

dàbí ẹni tí ó bẹ́ ajá kan lọ́rùn;

ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbìn ìyẹ̀fun tọrẹ

dàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá,

ẹni tí ó bá sì sun tùràrí ìrántí,

dàbí ẹni tí ó súre fún òrìṣà.

Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tì wọ́n,

ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn;

4Fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọn

n ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn.

Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn,

nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tí sílẹ̀.

Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú mi

wọ́n sì yan ohun tí mo kórìíra rẹ̀.”

5Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,

Ẹ̀yin tí ẹ ń wárìrì nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀:

“Àwọn arákùnrin yín tí wọ́n kórìíra yín,

tí wọ́n ta yín nù nítorí orúkọ mi, wí pé,

‘Jẹ́ kí a yin Olúwa lógo,

kí a le rí ayọ̀ yín!’

Ṣùgbọ́n àwọn ni ojú yóò tì.

666.6: If 16.1,17.Gbọ́ rògbòdìyàn láti ìlú wá,

gbọ́ ariwo náà láti tẹmpili wá!

Ariwo tí Olúwa ní í ṣe

tí ó ń san án fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ ohun

tí ó tọ́ sí wọn.

766.7: If 12.5.“Kí ó tó lọ sí ìrọbí,

ó ti bímọ;

kí ó tó di pé ìrora dé bá a,

ó ti bí ọmọkùnrin.

8Ta ni ó ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí?

Ta ni ó ti rí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí?

Ǹjẹ́ a le bí orílẹ̀-èdè kan níjọ́ kan

tàbí kí orílẹ̀-èdè lalẹ̀hù ní ìṣẹ́jú kan?

Síbẹ̀síbẹ̀ Sioni bẹ̀rẹ̀ rírọbí

bẹ́ẹ̀ ni ó sì bí àwọn ọmọ rẹ̀.

9Ǹjẹ́ èmi a ha máa mú wá sí ìrọbí

kí èmi má sì mú ni bí?”

ni Olúwa wí.

“Ǹjẹ́ èmi a ha máa ṣé ilé ọmọ

nígbà tí mo ń mú ìbí wá?”

Ni Ọlọ́run yín wí.

10“Ẹ bá Jerusalẹmu yọ̀ kí inú yín kí ó sì dùn sí i,

gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀;

ẹ yọ̀ gidigidi pẹ̀lú rẹ̀,

gbogbo ẹ̀yin tí ó ti kẹ́dùn fún un.

11Nítorí pé ẹ̀yin yóò mu ẹ o sì ní ìtẹ́lọ́rùn

nínú ọmú rẹ̀ tí ó tu ni lára;

Ẹ̀yin yóò mu àmuyó

ẹ ó sì gbádùn nínú àkúnwọ́sílẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ rẹ̀.”

12Nítorí báyìí ni Olúwa wí:

“Èmi yóò fún un ní àlàáfíà gẹ́gẹ́ bí odò

àti ọrọ̀ orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí ìṣàn omi;

ẹ̀yin yóò mu ọmú, a ó sì gbé yín ní apá rẹ̀

a ó bá yín ṣeré ní orúkún rẹ̀.

13Gẹ́gẹ́ bí ìyá ti í tu ọmọ rẹ̀ nínú,

bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò tù yín nínú

a ó sì tù yín nínú lórí Jerusalẹmu.”

14Nígbà tí ẹ bá rí èyí, inú yín yóò dùn

ẹ̀yin yóò sì gbilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i koríko;

ọwọ́ Olúwa ni a ó sọ di mí mọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,

ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ ni a ó fihàn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.

15Kíyèsi i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú iná

àti kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ tí ó dàbí ìjì líle;

òun yóò mú ìbínú rẹ sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ìrunú,

àti ìbáwí rẹ̀ pẹ̀lú ahọ́n iná.

16Nítorí pẹ̀lú iná àti idà

ni Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ lórí i gbogbo ènìyàn,

àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí Olúwa yóò pa.

17“Gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́ tí wọ́n sì sọ ara wọn di mímọ́ láti lọ sínú ọgbà, tí wọ́n tẹ̀lé ẹni tí ó wà láàrín àwọn tí ó jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀ àti èkúté àti àwọn ohun ìríra mìíràn ni wọn yóò bá òpin wọn pàdé papọ̀,” ni Olúwa wí.

18“Àti Èmi, nítorí ìgbésẹ̀ wọn àti èrò wọn, èmi ti múra tán láti wá kó àwọn orílẹ̀-èdè àti ahọ́n jọ, wọn yóò sì wá wo ògo mi.

19“Èmi yóò sì gbé ààmì kan kalẹ̀ láàrín wọn, èmi yóò sì rán díẹ̀ nínú àwọn tí ó sálà lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè Tarṣiṣi, sí àwọn ará Libia àti Ludi, sí Tubali àti ará Giriki, àti sí àwọn erékùṣù tí ó jìnnà réré tí kò tí ìgbọ́ nípa òkìkí mi tàbí kí ó rí ògo mi. Wọn yóò kéde ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè. 20Wọn yóò sì mú àwọn arákùnrin yín wá, láti gbogbo orílẹ̀-èdè, sí òkè mímọ́ mi ní Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa lórí ẹṣin, lórí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti ọkọ-ẹṣin, àti lórí ìbáaka àti ìbákasẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn yóò kó wọn wá, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli ti mú ọrẹ oníhóró wọn wá, sínú Tẹmpili Olúwa nínú ohun èlò mímọ́. 21Àti pé èmi yóò sì yan àwọn kan nínú wọn pẹ̀lú láti jẹ́ àlùfáà àti Lefi,” ni Olúwa wí.

2266.22: Isa 65.17; 2Pt 3.13; If 21.1.“Gẹ́gẹ́ bí àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun tí mo dá yóò ṣe wà níwájú mi títí láé,” ni Olúwa wí, “Bẹ́ẹ̀ ni orúkọ yín àti ìrandíran yín yóò pegedé. 23Láti oṣù tuntun kan dé òmíràn àti láti ọjọ́ ìsinmi kan dé òmíràn, ni gbogbo ọmọ ènìyàn yóò wá, wọn yóò sì tẹríba níwájú mi,” ni Olúwa wí. 2466.24: Mk 9.48.“Wọn yóò sì jáde lọ wọn yóò sì lọ wo òkú àwọn tí wọ́n dìtẹ̀ sí mi; kòkòrò wọn kì yóò kú, bẹ́ẹ̀ ni iná wọn ni a kì yóò pa, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jẹ́ ohun ìríra fún gbogbo ọmọ ènìyàn.”

Akuapem Twi Contemporary Bible

Yesaia 66:1-24

Atemmu Ne Anidaso

1Sɛɛ na Awurade se:

“Ɔsoro yɛ mʼahengua,

na asase yɛ me nan ntiaso.

Ofi a wubesi ama me no wɔ he?

Ɛhe na ɛbɛyɛ me homebea?

2Ɛnyɛ me nsa na ɛyɛɛ eyinom nyinaa,

na ɛma ɛbae ana?”

Awurade na ose.

“Obi a mʼani sɔ no ni:

nea ɔwɔ ahobrɛase ne ahonu honhom,

na ne ho popo wɔ mʼasɛm ho.

3Nanso obi a ɔde nantwinini bɔ afɔre no

saa onipa no ara kum nnipa,

na nea ɔma oguamma no,

saa onipa no ara bu ɔkraman kɔn mu;

nea ɔbɔ aduan afɔre no

saa onipa no ara de prako mogya bɔ afɔre,

nea ɔhyew nnuhuam a ɛwɔ din no

saa onipa no ara som ɔbosom.

Wɔafa wɔn ankasa akwan

na wɔn akra ani gye wɔn akyiwade ho;

4enti me nso mɛpɛ ayayade ayɛ wɔn

na mede nea wosuro bɛba wɔn so.

Efisɛ mefrɛe no, obiara annye so,

mekasae no, obiara antie.

Wɔyɛɛ bɔne wɔ mʼani so

na wɔyɛɛ nea mempɛ.”

5Muntie Awurade asɛm,

mo a mote nʼasɛm a mo ho popo:

“Mo nuanom mmarima a wɔtan mo,

na me din nti wotwa mo gyaw no, aka se,

‘Momma wɔnhyɛ Awurade anuonyam,

na yɛahu mo anigye!’

Nanso wɔn anim begu ase.

6Muntie huuyɛ a efi kuropɔn no mu,

muntie gyegyeegye a efi asɔredan no mu!

Ɛyɛ Awurade nnyigyei

a ɔde retua nʼatamfo ka sɛnea ɛfata wɔn.

7“Ansa na ɔbea bɛkyem no,

ɔwo;

ansa na ɔbɛte awoyaw no

ɔwo ɔbabarima.

8Hena na wate biribi sɛɛ ho asɛm pɛn?

Hena na wahu biribi sɛɛ pɛn?

Wobetumi de da koro akyekyere ɔmansin,

anaa ɔman mu, bere sin bi mu ana?

Nanso awo ka Sion ara pɛ a

ɔwo ne mma.

9Mede obi bedu awoko ano a

memma no nwo ana?” Sɛnea Awurade se ni.

“Misiw awotwaa ano

bere a awo adu so ana?” Wo Nyankopɔn na ose.

10Mo ne Yerusalem ani nnye na munni ahurusi mma no,

mo a modɔ no nyinaa;

mo ne no nsɛpɛw mo ho yiye,

mo a mudi ne ho awerɛhow nyinaa.

11Mubenum nʼawerɛkyekye nufu

no amee;

mobɛnom aboro so

na mo ani begye nea abu so atra so no ho.

12Na sɛɛ na Awurade se:

“Mede asomdwoe bɛma no sɛ asubɔnten,

ne amanaman no ahonya nso sɛ asuten a ayiri.

Mubenum na waturu mo wɔ ne basa so

na obegyigye mo agoru wɔ nʼanankoroma so.

13Sɛnea ɛna kyekye ne ba werɛ no

saa ara na mɛkyekye mo werɛ;

na mubenya awerɛkyekye wɔ Yerusalem.”

14Sɛ muhu eyi a, mo koma ani begye

na mobɛyɛ frɔmfrɔm sɛ sare;

wobehu Awurade nsa wɔ ne nkoa so,

nanso wobehu nʼabufuwhyew wɔ nʼatamfo so.

15Hwɛ, Awurade de ogya reba,

na ne nteaseɛnam te sɛ mfɛtɛ;

ɔde nʼabufuw bɛba wɔ anibere so,

na ɔde gyaframa ayɛ nʼanimka.

16Ogya ne nʼafoa,

na Awurade de bebu nnipa nyinaa atɛn,

na wɔn a wɔbɛtotɔ wɔ Awurade nsa ano bɛyɛ bebree.

17“Wɔn a wɔtew wɔn ho na wodwira wɔn ho de kɔ nturo mu, na wodi ɔbaako a ɔfra wɔn a wɔwe mprakonam ne akisi ne nneɛma a ɛyɛ akyiwade akyi no, wɔbɛbɔ mu ahu wɔn awiei,” sɛnea Awurade se ni.

18“Esiane wɔn nneyɛe ne wɔn nsusuwii nti, Me, mereba abɛboaboa amanaman ne ɔkasa ahorow ano, na wɔbɛba abehu mʼanuonyam.

19“Na mɛyɛ nsɛnkyerɛnne bi wɔ wɔn mu, na mede nkae no mu bi bɛkɔ amanaman no mu: Tarsis, Libiafo ne Lidiafo (wɔn a wɔagye din wɔ agyantow mu), Tubal ne Helafo, ne asupɔw a ɛwɔ akyirikyiri a wɔntee me din a ahyeta na wonhuu mʼanuonyam no. Wɔbɛpae mu aka mʼanuonyam wɔ amanaman mu. 20Na wɔde mo nuabarimanom nyinaa befi amanaman nyinaa so bɛba me bepɔw kronkron a ɛwɔ Yerusalem no so sɛ, afɔrebɔde ama Awurade. Wɔtete apɔnkɔ so ne nteaseɛnam mu ne asako mu ne mfurumpɔnkɔ ne yoma so bɛba,” sɛɛ na Awurade se. “Wɔde wɔn bɛba sɛnea Israelfo de wɔn aduan afɔre kɔ Awurade asɔredan mu, wɔ afahyɛ nkuruwa a ho tew mu. 21Na meyi wɔn mu bi ayɛ asɔfo ne Lewifo,” Awurade, na ose!

22“Sɛnea ɔsorosoro foforo ne asase foforo bɛtena hɔ no, saa ara na mo din ne mo asefo bɛtena hɔ,” sɛnea Awurade se ni. 23“Efi Ɔsram Foforo baako kɔpem foforo, efi Homeda baako kosi foforo no, adesamma nyinaa bɛba abɛkotow me,” sɛnea Awurade se ni. 24“Na wobefi adi akohu wɔn a wɔtew atua tiaa me no afunu; wɔn asunson renwu, na wɔn gya nso rennum, na wɔn ho bɛyɛ adesamma nyinaa nwini.”