Isaiah 65 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 65:1-25

Ìdájọ́ àti ìgbàlà

165.1-2: Ro 10.20-21.“Èmi fi ara mi hàn fún àwọn tí kò béèrè fún mi;

Àwọn tí kò wá mi ni wọ́n rí mi.

Sí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò pe orúkọ mi,

Ni èmi wí pé, ‘Èmi nìyìí, Èmi nìyìí.’

2Gbogbo ọjọ́ ni mo ti nawọ́ mi síta

sí àwọn ènìyàn ọlọ́rùn líle,

tí wọn ń rìn lọ́nà tí kò dára,

tí wọ́n sì gbára lé èrò ara wọn

3àwọn ènìyàn tí wọ́n bí mi nínú nígbà gbogbo

lójú ara mi gan an,

wọ́n ń rú ẹbọ nínú ọgbà

wọ́n sì ń sun tùràrí lórí i pẹpẹ bíríkì;

4wọ́n ń jókòó láàrín ibojì

wọ́n sì ń lo òru wọn nínú ìṣọ́ ìkọ̀kọ̀;

tí wọ́n ń jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀,

tí ìkòkò ọbẹ̀ wọn kún fún ẹran àìmọ́;

5tí ó wí pé, ‘Ẹ sún mẹ́yìn; ẹ má wá sọ́dọ̀ mi,

nítorí mo ti jẹ́ mímọ́ jù fún un yín!’

Àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ jẹ́ èéfín nínú ihò imú mi

iná tí ń fi gbogbo ọjọ́ jó.

6“Kíyèsi i, a ti kọ ọ́ síwájú mi:

Èmi kì yóò dákẹ́,

ṣùgbọ́n èmi yóò san án padà lẹ́kùnrẹ́rẹ́;

Èmi yóò san án padà sí àyà wọn

7àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín àti tàwọn baba yín,”

ni Olúwa wí.

“Nítorí pé wọ́n sun ẹbọ ní orí òkè ńlá

wọ́n sì ṣe ẹ̀gbin sí mi ní òkè kékeré,

Èmi yóò wọ́n ọ́n sí itan wọn

ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ẹ̀san ohun gbogbo tí wọ́n ṣe tẹ́lẹ̀.”

8Báyìí ni Olúwa wí:

“Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí oje sì tún wà nínú àpólà àjàrà

tí àwọn ènìyàn sì wí pé, ‘má ṣe bà á jẹ́,

nítorí ìbùkún ń bẹ nínú rẹ̀,’

bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe nítorí ìránṣẹ́ mi;

Èmi kì yóò pa gbogbo wọn run.

9Èmi yóò mú ìrandíran wá láti ìdílé Jakọbu,

àti láti Juda àwọn tí yóò jogún òkè ńlá mi wọ̀n-ọn-nì;

àwọn àyànfẹ́ ènìyàn mi yóò jogún wọn,

ibẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ mi yóò sì gbé.

10Ṣaroni yóò di pápá oko fún ọ̀wọ́ ẹran,

àti Àfonífojì Akori yóò di ibi ìsinmi fún agbo ẹran,

fún àwọn ènìyàn mi tí ó wá mi.

11“Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó kọ Olúwa sílẹ̀

tí ó sì gbàgbé òkè ńlá mímọ́ mi,

tí ó tẹ́ tábìlì fún Gadi

tí ẹ sì kún abọ́ pẹ̀lú ọtí wáìnì fún àtubọ̀tán,

12Èmi yóò yà ọ́ sọ́tọ̀ fún idà,

àti pé ẹ̀yin yóò bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ fún àwọn tí a pa;

nítorí mo pè, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò dáhùn.

Mo sọ̀rọ̀ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò tẹ́tí sílẹ̀

Ẹ̀yin ṣe búburú ní ojú mi

ẹ sì yan ohun tí ó bà mí lọ́kàn jẹ́.”

13Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:

“Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò jẹun;

ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ẹ̀yin,

àwọn ìránṣẹ́ mi yóò mu,

ṣùgbọ́n òǹgbẹ yóò máa gbẹ ẹ̀yin;

àwọn ìránṣẹ́ mi yóò ṣe àjọyọ̀,

ṣùgbọ́n a ó dójútì yin.

14Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò kọrin

láti inú ayọ̀ ọkàn wọn wá,

ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò kígbe sókè

láti inú ìrora ọkàn yín

àti ìpohùnréré ní ìròbìnújẹ́ ọkàn.

15Ẹ̀yin yóò fi orúkọ yín sílẹ̀

fún àwọn àyànfẹ́ mi gẹ́gẹ́ bí ègún;

Olúwa Olódùmarè yóò sì pa yín,

ṣùgbọ́n fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ni òun

yóò fún ní orúkọ mìíràn

16Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbàdúrà ìbùkún ní ilẹ̀ náà

yóò ṣe é nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́;

Ẹni tí ó bá búra ní ilẹ̀ náà

yóò búra nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́.

Nítorí ìyọnu àtijọ́ yóò di ìgbàgbé

yóò sì fi ara sin kúrò lójú mi.

Àwọn ọrun tuntun àti ayé tuntun

17“Kíyèsi i, Èmi yóò dá

àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun

A kì yóò rántí ohun àtẹ̀yìnwá mọ́,

tàbí kí wọn wá sí ọkàn.

18Ṣùgbọ́n ẹ yọ̀ kí inú yín dùn títí láé

nínú ohun tí èmi yóò dá,

nítorí èmi yóò dá Jerusalẹmu láti jẹ́ ohun ìdùnnú

àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ohun ayọ̀.

19Èmi yóò ṣe àjọyọ̀ lórí Jerusalẹmu

n ó sì ní inú dídùn nínú àwọn ènìyàn mi;

ariwo ẹkún àti igbe

ni a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ mọ́.

20“Títí láé a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀

ọmọ ọwọ́ tí yóò gbé fún ọjọ́ díẹ̀,

tàbí àgbàlagbà tí kì yóò lo ọjọ́ ayé rẹ̀ tán;

ẹni tí ó bá kú ní ìwọ̀n ọgọ́rùn-ún

ni a ó pè ní ọ̀dọ́mọdé;

ẹni tí kò ba le pé ọgọ́rùn-ún kan

ni a ó pè ní ẹni ìfibú.

21Wọn yó ò kọ́ ilé, wọn yóò sì gbé nínú wọn

wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì jẹ èso wọn.

22Wọn kì yóò kọ́ ilé fún ẹlòmíràn láti gbé,

tàbí kí wọn gbìn fún ẹlòmíràn láti jẹ,

Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí igi kan,

bẹ́ẹ̀ ní ọjọ́ àwọn ènìyàn mi yóò rí;

àwọn àyànfẹ́ mi yóò jẹ iṣẹ́ ọwọ́

wọn fún ìgbà pípẹ́.

23Wọn kì yóò ṣe iṣẹ́ lásán,

wọn kí yóò bímọ fún wàhálà;

nítorí wọn yóò jẹ́ àwọn ènìyàn ti Olúwa bùkún fún,

àwọn àti àwọn ìrandíran wọn pẹ̀lú wọn.

24Kí wọn tó pè, èmi yóò dáhùn;

nígbà tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, èmi yóò gbọ́.

2565.25: Isa 11.6-9.Ìkookò àti ọ̀dọ́-àgùntàn yóò jẹun pọ̀,

kìnnìún yóò sì jẹ koríko gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù,

ṣùgbọ́n erùpẹ̀ ni yóò jẹ́ oúnjẹ ejò.

Wọn kì yóò pa ni lára tàbí pa ni run

ní gbogbo òkè mímọ́ mi,”

ni Olúwa wí.

Akuapem Twi Contemporary Bible

Yesaia 65:1-25

Atemmu Ne Nkwagye

1“Medaa me ho adi kyerɛɛ wɔn a wɔammisa mʼase;

wɔn a wɔnhwehwɛ me no huu me.

Ɔman a wonsu mfrɛ me no,

meka kyerɛɛ wɔn se, ‘Mini, Mini.’

2Da mu nyinaa, matrɛw me nsa mu ama

nnipa a wɔyɛ asoɔden ne nyiyiano,

a wɔnenam akwammɔne so,

na wodi wɔn ankasa nsusuwii akyi.

3Nnipa a daa no woyi me ahi

wɔ mʼanim pɛɛ,

wɔbɔ afɔre wɔ nturo mu

na wɔhyew nnuhuam wɔ ntayaa afɔremuka so;

4wɔn a wɔtenatena nna so

na anadwo wosii pɛ kokoa mu;

wɔwe mprakonam

na wɔn nkutu mu wɔ nkwan a wɔde nam a ɛho ntew ayɛ;

5wɔka se, ‘Mumfi ha; mommmɛn me,

efisɛ me ho tew dodo ma mo!’

Saa nnipa yi yɛ wusiw wɔ me hwenem,

ogya a ɛkɔ so hyew da mu nyinaa.

6“Hwɛ; wɔakyerɛw ato hɔ wɔ mʼanim se,

merenyɛ komm, metua so ka pɛpɛɛpɛ;

metua so ka agu wɔn asrɛ so,

7mo ne mo agyanom bɔne nti,”

sɛɛ na Awurade se.

“Esiane sɛ wɔhyew afɔrebɔde wɔ mmepɔw so

na wotwirii me wɔ nkoko so nti

mesusuw bɔne a wɔyɛɛ kan no so akatua pɛpɛɛpɛ

agu wɔn asrɛ so.”

8Sɛɛ na Awurade se:

“Sɛnea wonya nsu fi bobe kasiaw mu,

na nnipa ka se, ‘Monnsɛe no,

efisɛ ade pa bi da so wɔ mu’ no

saa ara na mʼasomfo no nti mɛyɛ.

Merensɛe wɔn nyinaa.

9Mede Yakob asefo bɛba,

na me mmepɔw no sodifo afi Yuda aba;

me nkurɔfo a mapaw wɔn no bedi wɔn ade,

na hɔ na mʼasomfo bɛtena.

10Saron bɛyɛ nguankuw adidibea,

na Akor bon no ayɛ anantwikuw homebea

ama me nkurɔfo a wɔhwehwɛ me.

11“Na mo a mo de mugyaw Awurade

na mo werɛ fi ne bepɔw kronkron no,

mo a moto pon ma Ahonya

na mohyɛ afrasa wɔ nkuruwa mu ma Nkrabea no,

12mede mo bɛto afoa ano,

na mo nyinaa akotow ama wɔakum mo;

efisɛ mefrɛe nanso moannye so,

mekasae nanso moantie.

Moyɛɛ nea ɛyɛ mʼani so bɔne

na moyɛɛ nea mempɛ.”

13Enti sɛɛ na Otumfo Awurade se:

“Mʼasomfo bedidi,

nanso ɔkɔm bɛde mo,

mʼasomfo bɛnom,

nanso osukɔm bɛde mo;

mʼasomfo ani begye,

nanso mo anim begu ase.

14Mʼasomfo bɛto nnwom

afi koma mu anigye mu

na mobɛteɛ mu asu

afi mo koma ahoyeraw mu,

na mubetwa adwo afi honhom a ayɛ mmrɛw mu.

15Wubegyaw din bi a ɛbɛyɛ mmusu

ama wɔn a mapaw wɔn;

Otumfo Awurade bekum wo

na nʼasomfo de, mɛma wɔn din foforo.

16Obiara a ɔsrɛ nhyira wɔ asase no so no,

bɛyɛ wɔ nokware Nyankopɔn koro no mu;

obiara a ɔka ntam wɔ asase no so

bɛka no wɔ nokware Nyankopɔn koro no mu.

Na ɔhaw a atwa mu no wɔn werɛ befi

na wɔde behintaw me.

17“Hwɛ! Mɛbɔ

ɔsorosoro foforo ne asase foforo.

Wɔrenkae nneɛma a atwam no bio,

na ɛremma adwene mu nso.

18Nanso momma mo ani nnye na munni ahurusi afebɔɔ

wɔ nea merebɛbɔ ho,

efisɛ mɛbɔ Yerusalem ama ayɛ anigye,

na mu nnipa ayɛ anigye farebae.

19Mɛsɛpɛw me ho wɔ Yerusalem mu,

na madi ahurusi wɔ me nkurɔfo ho.

Na wɔrente agyaadwo ne osu nnyigyei

wɔ mu bio.

20“Ɛrensi bio wɔ mu

abofra a ne nkwanna yɛ kakraa bi,

anaa akwakoraa a onni ne mfe nwie;

nea odi mfe ɔha na owu no

wɔbɛfa no sɛ ɔbabun bi kɛkɛ;

na nea wannya mfe ɔha no

wɔbɛfa no sɛ wɔadome no.

21Wobesisi afi na wɔatena mu,

wɔbɛyɛ bobe nturo na wɔadi mu aba.

22Wɔrensisi afi mma afoforo mmɛtena mu bio,

na wɔrennua mma afoforo mmedi.

Na nna a dua di no,

saa ara na me nkurɔfo nna bɛyɛ;

me nkurɔfo a mapaw wɔn no bedi

wɔn nsa ano adwuma so aba akyɛ.

23Wɔremmrɛ ngu

na wɔrenwo mma a wɔn nkrabea nye;

efisɛ wɔbɛyɛ nnipa a Awurade ahyira wɔn,

wɔne wɔn asefo.

24Mebua wɔn ansa, mpo, na wɔafrɛ me.

Bere a wogu so rekasa no metie.

25Pataku ne oguamma bedidi abɔ mu

gyata bɛwe sare sɛ nantwi,

nanso mfutuma bɛyɛ ɔwɔ aduan.

Wɔrempira obi anaa wɔrensɛe obi

wɔ me bepɔw kronkron so nyinaa,”

sɛnea Awurade se ni.