Heberu 2 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Heberu 2:1-18

Ìkìlọ̀ láti ṣe ìgbọ́ràn

1Nítorí náà, ó yẹ kí àwa máa fi iyè sí àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì gidigidi tí àwa ti gbọ́, kí a má ba à gbá wa lọ kúrò nínú wọn nígbà kan. 2Nítorí bí ọ̀rọ̀ tí a tí ẹnu àwọn angẹli sọ bá sì dúró ṣinṣin, àti tí olúkúlùkù ẹ̀ṣẹ̀ sí òfin àti àìgbọ́ràn gba ìjìyà tí ó tọ́ sí i, 3kín ni ohun náà tí ó mú wa lérò pé a lè bọ́ kúrò nínú ìjìyà bí a kò bá náání ìgbàlà ńlá yìí? Ìgbàlà tí Olúwa fúnrarẹ̀ kọ́kọ́ kéde, èyí tí a sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ fún wa láti ọwọ́ àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà lẹ́nu rẹ̀. 4Ọlọ́run jẹ́rìí sí i nípa àwọn iṣẹ́ ààmì àti ìyanu àti oríṣìíríṣìí iṣẹ́ agbára àti nípa ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ tí a pín gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀.

Jesu bí arákùnrin rẹ̀

5Nítorí pé, kì í ṣe abẹ́ ìṣàkóso àwọn angẹli ni ó fi ayé tí ń bọ̀, tí àwa ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ sí. 62.6-9: Sm 8.4-6.Ṣùgbọ́n ibìkan wà tí ẹnìkan tí jẹ́rìí pé:

“Kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣe ìrántí rẹ̀,

tàbí ọmọ ènìyàn, tí ìwọ fi ń bẹ̀ ẹ́ wò?

7Ìwọ dá a ní onírẹ̀lẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ;

ìwọ fi ògo àti ọlá de e ni adé,

ìwọ sì fi í jẹ olórí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ:

8Ìwọ fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.”

Ní ti fífi ohun gbogbo sábẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n àwa kò ì tí ì rí ohun kan tí ó kù tí kò sí ní abẹ́ àkóso rẹ̀. Síbẹ̀ nísinsin yìí àwa kò ì tí ì rí pé ó fi ohun gbogbo sábẹ́ ìṣàkóso rẹ̀ 9Ṣùgbọ́n àwa rí Jesu ẹni tí a rẹ̀ sílẹ̀ díẹ̀ ju àwọn angẹli lọ fún àkókò díẹ̀, àní Jesu, ẹni tí a fi ògo àti ọlá dé ní adé nítorí ìjìyà wa; kí ó lè tọ́ ikú wò fún olúkúlùkù ènìyàn nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.

10Nítorí pé ó yẹ fún Ọlọ́run, nítorí nípasẹ̀ ẹni tí ohun gbogbo ṣẹ̀ wà, láti mú àwọn ọmọ púpọ̀ wá sínú ògo, láti ṣe balógun ìgbàlà wọn ni àṣepé nípa ìjìyà. 11Nítorí àti ẹni tí ń sọ ni di mímọ́ àti àwọn tí a ń sọ di mímọ́, láti ọ̀dọ̀ ẹnìkan ṣoṣo ni gbogbo wọn ti wá: Nítorí èyí ni kò ṣe tijú láti pè wọ́n ni arákùnrin. 122.12: Sm 22.22.Àti wí pé,

“Èmi ó sọ̀rọ̀ orúkọ rẹ̀ fún àwọn ará mi,

ni àárín ìjọ ni èmi yóò kọrin ìyìn rẹ̀.”

132.13: Isa 8.17-18.Àti pẹ̀lú,

“Èmi yóò gbẹ́kẹ̀ mi lé e.”

Àti pẹ̀lú,

“Kíyèsi í, èmi rèé, èmi àti àwọn ọmọ tí Ọlọ́run fi fún mi.”

14Ǹjẹ́ ni ìwọ̀n bí àwọn ọmọ tí ṣe alábápín ará àti ẹ̀jẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni òun pẹ̀lú sì ṣe alábápín nínú ohun kan náà; kí ó lè ti ipa ikú rẹ̀ pa ẹni tí ó ní agbára ikú run, èyí ni èṣù. 15Kí o sì lè gba gbogbo àwọn tí ó tìtorí ìbẹ̀rù ikú wà lábẹ́ ìdè lọ́jọ́ ayé wọn gbogbo kúrò lọ́wọ́ ìbẹ̀rù. 162.16: Isa 41.8-9.Nítorí pé, nítòótọ́, kì í ṣe àwọn angẹli ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún, ṣùgbọ́n àwọn irú-ọmọ Abrahamu ni ó ṣe ìrànlọ́wọ́ fún. 17Nítorí náà, ó yẹ pé nínú ohun gbogbo kí ó dàbí àwọn ará rẹ̀, kí ó lè jẹ́ aláàánú àti olóòtítọ́ alábojútó Àlùfáà nínú ohun tí i ṣe ti Ọlọ́run, kí o lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn. 18Nítorí níwọ̀n bí òun tìkára rẹ̀ ti jìyà tí a sì ti dán an wò, òun ní agbára láti ran àwọn tí a ń dánwò lọ́wọ́.

Persian Contemporary Bible

عبرانيان 2:1-18

توجه به پيام نجاتبخش انجيل

1پس حال كه پی برديم عيسی مسيح دارای چه مقام والايی است، بايد به پيغام و كلامی كه شنيده‌ايم، به دقت توجه نماييم، مبادا ايمان خود را از دست بدهيم. 2زيرا اگر پيغام و كلامی كه بوسيلهٔ فرشتگان آورده شد، دارای اعتبار و لازم‌الاجرا بود، و هر كه از آن تخلف و نافرمانی می‌كرد، به حق مجازات می‌شد، 3چگونه امكان دارد كه ما از مجازات بگريزيم، اگر نسبت به چنين نجات عظيمی بی‌اعتنا باشيم؟ زيرا اين مژده را ابتدا عيسای خداوند اعلام نمود، و بعد كسانی كه آن را از دهان او شنيدند، آن را برای ما تائيد كردند.

4خدا نيز با علامات، كارهای شگفت‌انگيز، معجزات گوناگون و عطايايی كه روح‌القدس مطابق اراده خود می‌بخشد، صحت كلام ايشان را ثابت نمود.

فرزند خدا به شكل انسان درآمد

5به ياد داشته باشيد كه دنيای آينده كه از آن سخن می‌گوييم، بوسيلهٔ فرشتگان اداره نخواهد شد، بلكه مسيح آن را اداره خواهد كرد. 6زيرا داوود پيغمبر در كتاب زبور به خدا می‌گويد: «انسان چيست كه تا اين اندازه او را مورد توجه قرار می‌دهی؟ اين پسر انسان كيست كه تا اين حد او را سرافراز می‌گردانی؟ 7زيرا هر چند برای مدتی كوتاه او را پایینتر از فرشتگان قرار دادی، اما اكنون تاج جلال و افتخار را بر سر او گذارده‌ای، 8و همه چيز را تحت فرمان او درآورده‌ای.»

ما تا به حال نديده‌ايم كه همه چيز تحت فرمان انسان درآمده باشد؛ 9اما عيسی را می‌بينيم كه اندک زمانی پایینتر از فرشتگان قرار گرفت و اكنون در اثر فدا كردن جان خود در راه ما، خدا تاج جلال و افتخار را بر سر او گذاشته است. بلی، به سبب رحمت عظيم خدا، عيسی به جای تمام مردم جهان، طعم مرگ را چشيد. 10و اين درست و بجا بود كه خدا، همان خدايی كه همه چيز را برای جلال خود آفريد، اجازه دهد كه عيسی عذاب ببيند، زيرا با اين كار، بسياری از فرزندان خدا را به سوی جلال آسمان هدايت می‌نمايد. در واقع، عذابی كه عيسی كشيد، باعث شد او پيشوايی كامل گردد، پيشوايی كه می‌تواند ايشان را به سوی نجات رهبری نمايد.

11حال كه ما بوسيلهٔ عيسی، مقدس شده‌ايم، پدر او، پدر ما نيز محسوب می‌شود. به همين علت، عيسی عار ندارد كه ما را برادران خود بخواند؛ 12چنانكه در كتاب زبور نيز فرموده است: «دربارهٔ پدرم خدا، با برادرانم سخن خواهم گفت، و همگی با هم او را حمد و سپاس خواهيم گفت». 13در جای ديگر نيز فرموده است: «من با برادران خود، بر خدا توكل خواهم نمود.» همچنين در جای ديگر گفته است: «ببينيد، اين من و اين هم فرزندانی كه خدا به ما عطا فرموده است.»

14از آنجا كه اين فرزندان خدا، انسان هستند و دارای گوشت و خون می‌باشند، او نيز گوشت و خون شد و به شكل انسان درآمد؛ زيرا فقط با انسان شدن می‌توانست جانش را در راه ما فدا كند و بميرد، و با مرگ خود، قدرت شيطان را نابود سازد، شيطانی كه صاحب اختيار مرگ بود. 15تنها از اين راه بود كه می‌توانست آنانی را كه در تمام عمرشان در وحشت مرگ به سر می‌بردند و اسير ترس بودند، رهايی بخشد.

16همهٔ ما می‌دانيم كه او برای كمک به فرشتگان نيامد، بلكه به اين جهان آمد تا انسانهايی را كه به گفتهٔ كتاب آسمانی، از «نسل ابراهيم» می‌باشند، دستگيری نمايد. 17به همين جهت لازم بود كه او نيز از هر لحاظ مانند برادران خود گردد تا در حضور خدا، برای انسانها كاهن اعظمی دلسوز و وفادار باشد و به هنگام كفارهٔ گناهان، بتواند در همان حال كه نسبت به انسان رحيم و كريم می‌باشد، نسبت به خدا نيز وفادار بماند. 18زيرا از آنجا كه او خود عذاب ديد و وسوسه شد، قادر است درد انسان را به هنگام عذاب و وسوسه درک كند و به كمک او بشتابد.