Hagai 2 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Hagai 2:1-23

Ẹwà Tẹmpili tuntun náà

1Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù keje, ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai wí pé: 2“Sọ fún Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn yòókù. Béèrè lọ́wọ́ wọn pé, 3‘Ta ni nínú yín tí ó kù tí ó sì ti rí ilé yìí ní ògo rẹ̀ àkọ́kọ́? Báwo ni ó ṣe ri sí yín nísinsin yìí? Ǹjẹ́ kò dàbí asán lójú yín? 4Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, múra gírí, ìwọ Serubbabeli,’ ni Olúwa wí. ‘Múra gírí, ìwọ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà. Ẹ sì múra gírí gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ilẹ̀ náà;’ ni Olúwa wí, ‘kí ẹ sì ṣiṣẹ́. Nítorí èmi wà pẹ̀lú yín;’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. 5‘Èyí ni ohun tí Èmi fi bá a yín dá májẹ̀mú nígbà tí ẹ jáde kúrò ní Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni Ẹ̀mí ì mi sì wà pẹ̀lú yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù.’

6“Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: ‘Láìpẹ́ jọjọ, Èmi yóò mi àwọn ọrun àti ayé, Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i. 7Èmi yóò mi gbogbo orílẹ̀-èdè, ìfẹ́ gbogbo orílẹ̀-èdè yóò fà sí tẹmpili yìí, Èmi yóò sì kún ilé yìí pẹ̀lú ògo;’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. 8‘Tèmi ni fàdákà àti wúrà,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. 9‘Ògo ìkẹyìn ilé yìí yóò pọ̀ ju ti ìṣáájú lọ;’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Àti ní ìhín yìí ni Èmi ó sì fi àlàáfíà fún ni,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”

Ìbùkún fún àwọn ènìyàn tí a sọ di àìmọ́

10Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Hagai wá pé: 11“Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà ohun tí òfin wí pé: 12Bí ẹnìkan bá gbé ẹran mímọ́ ní ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, tí ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀ kan àkàrà tàbí ọbẹ̀, wáìnì, òróró tàbí oúnjẹ mìíràn, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ mímọ́ bí?’ ”

Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”

13Nígbà náà ni Hagai wí pé, “Bí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífi ara kan òkú bá fi ara kan ọ̀kan lára nǹkan wọ̀nyí, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ aláìmọ́?”

Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, yóò jẹ́ aláìmọ́.”

14Nígbà náà ni Hagai dáhùn ó sì wí pé, “ ‘Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn wọ̀nyí rí, bẹ́ẹ̀ sì ni orílẹ̀-èdè yìí rí níwájú mi,’ ni Olúwa wí. ‘Bẹ́ẹ̀ sì ni olúkúlùkù iṣẹ́ ọwọ́ wọn; èyí tí wọ́n sì fi rú ẹbọ níbẹ̀ jẹ́ aláìmọ́.

15“ ‘Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ ro èyí dáradára láti òní yìí lọ, ẹ kíyèsi bí nǹkan ṣe rí tẹ́lẹ̀, a to òkúta kan lé orí èkejì ní tẹmpili Olúwa. 16Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi òkìtì òṣùwọ̀n ogun, mẹ́wàá péré ni yóò ba níbẹ̀. Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi ìfúntí wáìnì láti wọn àádọ́ta ìwọ̀n, ogún péré ni yóò ba níbẹ̀. 17Mo fi ìrẹ̀dànù, ìmúwòdù àti yìnyín bá gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín jẹ; síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí ọ̀dọ̀ mi,’ ni Olúwa wí. 18‘Láti òní lọ, láti ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán yìí kí ẹ kíyèsi, kí ẹ sì rò ó dáradára, ọjọ́ ti a fi ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa lélẹ̀, rò ó dáradára: 19Ǹjẹ́ èso ha wà nínú abà bí? Títí di àkókò yìí, àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ àti pomegiranate, àti igi olifi kò ì tí ì so èso kankan.

“ ‘Láti òní lọ ni èmi yóò bùkún fún un yin.’ ”

Serubbabeli òrùka èdìdì Olúwa

20Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ Hagai wá nígbà kejì, ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù náà pé: 21“Sọ fún Serubbabeli baálẹ̀ Juda pé èmi yóò mi àwọn ọ̀run àti ayé. 22Èmi yóò bi ìtẹ́ àwọn ìjọba ṣubú, Èmi yóò sì pa agbára àwọn aláìkọlà run; Èmi yóò sì dojú àwọn kẹ̀kẹ́ ogun dé, àti àwọn tí ń gùn wọ́n; ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin yóò ṣubú; olúkúlùkù nípa idà arákùnrin rẹ̀.”

23Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní ọjọ́ náà, ìwọ ìránṣẹ́ mi Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Èmi yóò mú ọ, Èmi yóò sì sọ ọ di bí òrùka èdìdì mi, nítorí mo ti yan ọ, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”

Persian Contemporary Bible

حجی 2:1-23

شكوه خانهٔ خدا

1در روز بيست و يكم ماه هفتم همان سال، خداوند به حجی گفت:

2«از حاكم و كاهن اعظم و همهٔ قوم اين سؤال را بكن: 3آيا كسی در بين شما هست كه شكوه و عظمت خانهٔ خدا را آن طوری كه در سابق بود به خاطر آورد؟ آيا اين خانه‌ای كه می‌سازيد در مقايسه با خانهٔ قبلی به نظر شما ناچيز نمی‌آيد؟

4«هر چند به ظاهر چنين است اما مأيوس نشويد. ای زروبابل و يهوشع و همهٔ قوم، قوی دل باشيد و كار كنيد، چون من با شما هستم. 5وقتی از مصر بيرون می‌آمديد به شما وعده دادم كه روح من در ميان شما می‌ماند؛ پس ترسان نباشيد!»

6خداوند قادر متعال می‌فرمايد: «بزودی آسمانها و زمين، درياها و خشكی را به لرزه درمی‌آورم. 7تمام قومها را سرنگون می‌كنم، و ثروت آنها به اين خانه سرازير می‌شود2‏:7 «ثروت آنها به اين خانه سرازير می‌شود» يا «آرزوی آنها به اين خانه خواهد آمد». جملهٔ دوم، به نظر برخی مفسرين اشاره است به ظهور مسيح موعود.‏ و من اين محل را با جلال خود پر می‌سازم. 8تمام طلا و نقرهٔ دنيا از آن من است. 9شكوه و عظمت آيندهٔ اين خانه از شكوه و عظمت خانهٔ قبلی بيشتر خواهد بود و در اين مكان به قوم خود صلح و سلامتی خواهم بخشيد.» اين است آنچه خداوند قادر متعال می‌فرمايد.

سؤال حجی از كاهنان

10در روز بيست و چهارم ماه نهم از دومين سال سلطنت داريوش، اين پيام از جانب خداوند قادر متعال به حجی نبی نازل شد:

11«از كاهنان بخواه تا جواب شرعی اين سؤال را بدهند: 12اگر كسی قسمتی از گوشت مقدس قربانی را در دامن ردايش گذاشته آن را حمل كند و برحسب اتفاق ردايش با نان، آش، شراب، روغن و يا هر نوع خوراک ديگری تماس پيدا كند، آيا آن خوراک مقدس می‌شود؟»

وقتی حجی از كاهنان اين سؤال را كرد آنها جواب دادند: «نه، مقدس نمی‌شود؟»

13سپس حجی پرسيد: «و اما اگر شخصی به جسد مرده‌ای دست بزند و بدين ترتيب شرعاً نجس شود و بعد به يكی از اين خوراكها دست بزند، آيا آن خوراک نجس می‌شود؟»

كاهنان جواب دادند: «بلی، نجس می‌شود.»

14پس حجی گفت: «خداوند می‌فرمايد شما نيز در نظر من همينطور نجس هستيد و هر کاری كه می‌كنيد و هر قربانی كه به خانه من می‌آوريد، نجس است.»

وعدهٔ بركت

15خداوند می‌فرمايد: «خوب فكر كنيد و ببينيد قبل از اينكه دست به كار ساختن خانهٔ خداوند بزنيد وضع شما چگونه بود. 16در آن روزها وقتی انتظار داشتيد دو خروار محصول برداشت كنيد، فقط نصف آن به دستتان می‌رسيد، و هنگامی كه به اميد پنجاه ليتر شراب به سراغ خمره‌هايتان می‌رفتيد، بيشتر از بيست ليتر نمی‌يافتيد. 17من محصولات شما را با باد سوزان، آفت و تگرگ از بين بردم، اما با وجود همهٔ اينها به سوی من بازگشت نكرديد. 18ولی از امروز كه روز بيست و چهارم ماه نهم و روزی است كه بنياد خانهٔ خدا گذاشته شده است، ببينيد من برای شما چه خواهم كرد. 19اگرچه غله‌ای در انبارها باقی نمانده، و هنوز درختان انگور، انجير، انار و زيتون ميوه نداده‌اند، ولی من به شما بركت خواهم داد.»

وعدهٔ خداوند به زروبابل

20در همان روز پيام ديگری از جانب خداوند به حجی رسيد:

21«به زروبابل، حاكم يهودا بگو كه بزودی آسمانها و زمين را به لرزه درمی‌آورم، 22تختهای فرمانروايان را واژگون می‌سازم و قدرت آنان را از بين می‌برم. عرابه‌ها و سواران را سرنگون می‌كنم، و اسبها كشته می‌شوند و سوارانشان يكديگر را با شمشير از پای در می‌آورند. 23اما وقتی كه اين امور واقع گردد، ای زروبابل، خدمتگزار من، تو برای من مانند نگين انگشتر خواهی بود، زيرا تو را برگزيده‌ام.» اين است آنچه خداوند قادر متعال می‌فرمايد.