Ìpè láti tún ilé Olúwa kọ́
1Ní ọdún kejì ọba Dariusi ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹfà, ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai sí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti Sọ́dọ̀ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
2Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí pé, ‘Kò tí ì tó àkókò láti kọ́ ilé Olúwa.’ ”
3Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá láti ọ̀dọ̀ wòlíì Hagai wí pé: 4“Ǹjẹ́ àkókò ni fún ẹ̀yin fúnrayín láti máa gbé ní ilé tí a ṣe ní ọ̀ṣọ́ nígbà tí ilé yìí wà ni ahoro?”
5Ní ṣinṣin yìí, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín. 6Ẹ̀yin ti gbìn ohun ti ó pọ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kórè díẹ̀ níbẹ̀; Ẹ̀yin jẹun, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò yó. Ẹ̀yin mu ṣùgbọ́n kò tẹ́ ẹ yín lọ́run; ẹ̀yin wọ aṣọ, ṣùgbọ́n kò mú òtútù yin lọ; ẹyin gba owó iṣẹ́ ṣùgbọ́n ẹ ń gbà á sínú ajádìí àpò.”
7Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín. 8Ẹ gun orí àwọn òkè ńlá lọ, kí ẹ sì mú igi wá pẹ̀lú yín. Kí ẹ sì kọ́ ilé náà, kí inú mi bà le è dùn sí i, kí a sì yín mí lógo,” ni Olúwa wí. 9“Ẹyin ti ń retí ọ̀pọ̀, ṣùgbọ́n kíyèsi i, o yípadà sí díẹ̀. Ohun tí ẹ̀yin mú wa ilé, èmi sì fẹ́ ẹ dànù. Nítorí kí ni?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí ilé mi tí ó dahoro; tí olúkúlùkù yín sì ń sáré fún ilé ara rẹ̀. 10Nítorí yín ni àwọn ọ̀run ṣe dá ìrì dúró tí ilẹ̀ sì kọ̀ láti mu èso jáde. 11Mo sì ti pe ọ̀dá sórí ilẹ̀ àti sórí àwọn òkè ńlá, sórí ọkà àti sórí wáìnì tuntun, sórí òróró àti sórí ohun ti ilẹ̀ ń mú jáde, sórí ènìyàn, sórí ẹran àti sórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín.”
12Nígbà náà ni Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ìyókù, gba ohùn Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́ àti ọ̀rọ̀ wòlíì Hagai, nítorí Olúwa Ọlọ́run ni ó rán an. Àwọn ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa.
13Nígbà náà ni Hagai ìránṣẹ́ Olúwa ń jíṣẹ́ Olúwa fún àwọn ènìyàn pé, “Èmí wà pẹ̀lú yín,” ni Olúwa wí. 14Nítorí náà, Olúwa ru ẹ̀mí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli sókè, baálẹ̀ Juda àti ẹ̀mí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti ẹ̀mí gbogbo ènìyàn ìyókù. Wọ́n sì wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ lórí ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run wọn, 15ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ní ọdún kejì ọba Dariusi.
دعوت به بازسازی خانهٔ خدا
1در سال دوم سلطنت داريوش، در روز اول ماه ششم، خداوند پيامی توسط حجی نبی برای زروبابل (پسر شئلتیئيل) حاكم يهودا، و برای يهوشع (پسر يهوصادق) كاهن اعظم، فرستاد.
2خداوند قادر متعال به حجی نبی فرمود: «اين قوم میگويند كه اكنون وقت بازسازی خانهٔ خدا نيست.» 3سپس، خداوند اين پيام را توسط حجی نبی برای قوم فرستاد: 4«آيا اين درست است كه شما در خانههای نوساخته زندگی كنيد ولی خانهٔ من خراب بماند؟ 5به نتيجهٔ كارهايتان نگاه كنيد: 6بذر زياد میكاريد، ولی محصول كم برداشت میكنيد؛ میخوريد ولی سير نمیشويد؛ مینوشيد ولی تشنگیتان رفع نمیگردد؛ لباس میپوشيد اما گرم نمیشويد؛ مزد میگيريد ولی گويی آن را در جيبهای سوراخدار میگذاريد.
7«خوب فكر كنيد و ببينيد چه كردهايد و نتيجهاش چه بوده است! 8حال به كوه رفته، چوب بياوريد و خانهٔ مرا دوباره بسازيد تا من از آن راضی شوم و در آنجا مردم احترام مرا بجا آورند.
9«انتظار محصول فراوانی داشتيد، اما خيلی كم به دست آورديد؛ و وقتی همان مقدار كم را هم به منزل آورديد، آن را از بين بردم. میدانيد چرا؟ چون خانهٔ من خراب مانده و شما فقط به فكر خانههای خود هستيد. 10به همين علت است كه آسمان نمیبارد و زمين محصول خود را نمیدهد. 11من در سرزمين شما خشكسالی پديد آوردهام و اين خشكسالی تمام كوهها، مزرعهها، تاكستانها، باغهای زيتون و ساير محصولات و حتی انسان و حيوان و تمام حاصل دسترنج شما را فرا خواهد گرفت.»
12آنگاه زروبابل و يهوشع و تمام كسانی كه از اسارت برگشته بودند از خداوند ترسيدند و پيام حجی نبی را كه خداوند، خدايشان به او داده بود اطاعت كردند.
13سپس خداوند بار ديگر توسط نبی خود حجی به قوم فرمود: «من با شما هستم.» 14-15خداوند در زروبابل و يهوشع و تمام قوم علاقه و اشتياق ايجاد كرد تا خانهٔ او را بسازند. پس، در سال دوم سلطنت داريوش در روز بيست و چهارم ماه ششم همه جمع شده، به بازسازی خانهٔ خداوند قادر متعال، خدای خود پرداختند.