Habakuku 3 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Habakuku 3:1-19

Àdúrà Habakuku

1Àdúrà wòlíì Habakuku gẹ́gẹ́ bí sígónótì. Ohun èlò orin.

2Olúwa mo tí gbọ́ ohùn rẹ;

ẹ̀rù sì ba mi fún iṣẹ́ rẹ Olúwa

sọ wọn di ọ̀tún ní ọjọ́ ti wa,

ní àkókò tiwa, jẹ́ kó di mí mọ̀;

ni ìbínú, rántí àánú.

3Ọlọ́run yóò wa láti Temani,

ibi mímọ́ jùlọ láti Òkè Parani

ògo rẹ̀ sí bo àwọn ọ̀run,

ilé ayé sì kún fún ìyìn rẹ

4Dídán rẹ sí dàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn

ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ jáde wa láti ọwọ́ rẹ,

níbi tí wọn fi agbára rẹ̀ pamọ́ sí.

5Àjàkálẹ̀-ààrùn ń lọ ni iwájú rẹ;

ìyọnu sí ń tọ ẹsẹ̀ rẹ lọ.

6Ó dúró, ó sì mi ayé;

ó wò, ó sì mú àwọn orílẹ̀-èdè wárìrì

a sì tú àwọn òkè ńlá ayérayé ká,

àwọn òkè kéékèèkéé ayérayé sì tẹríba:

ọ̀nà rẹ ayérayé ni.

7Mo rí àgọ́ Kuṣani nínú ìpọ́njú

àti àwọn ibùgbé Midiani nínú ìrora.

8Ǹjẹ́ ìwọ ha ń bínú sí àwọn Odò nì, Olúwa?

Ǹjẹ́ ìbínú rẹ wa lórí àwọn odò ṣíṣàn bí?

Ìbínú rẹ ha wá sórí Òkun

tí ìwọ fi ń gun ẹṣin,

àti kẹ̀kẹ́ ìgbàlà rẹ?

9A ṣí ọrun rẹ sílẹ̀ pátápátá,

gẹ́gẹ́ bí ìbúra àwọn ẹ̀yà, àní ọ̀rọ̀ rẹ,

ìwọ sì fi odò pín ilẹ̀ ayé.

10Àwọn òkè ńlá ri ọ wọn sì wárìrì

àgbàrá òjò ń sàn án kọjá lọ;

ibú ń ké ramúramù

ó sì gbé irú omi sókè.

11Òòrùn àti Òṣùpá dúró jẹ́ẹ́jẹ́ ni ibùgbé wọn,

pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ ọfà rẹ ni wọn yára lọ,

àti ni dídán ọ̀kọ̀ rẹ ti ń kọ mànà.

12Ní ìrunú ni ìwọ rin ilẹ̀ náà já,

ní ìbínú ni ìwọ tí tẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè rẹ.

13Ìwọ jáde lọ láti tú àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀,

àti láti gba ẹni ààmì òróró rẹ là;

Ìwọ ti run àwọn olórí kúrò nínú ilẹ̀ àwọn ènìyàn búburú,

ó sì bọ ìhámọ́ra rẹ láti orí de ẹsẹ̀

14Pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ kí ó fi gún orí rẹ

nígbà tí àwọn jagunjagun rẹ̀

jáde láti tú wá ká:

ayọ̀ wọn sì ni láti jẹ tálákà run ní ìkọ̀kọ̀.

15Ìwọ fi ẹṣin rẹ rìn Òkun já,

ó sì da àwọn omi ńlá ru.

16Mo gbọ́, ọkàn mi sì wárìrì,

ètè mi sì gbọ̀n sí ìró náà;

ìbàjẹ́ sì wọ inú egungun mi lọ,

ẹsẹ̀ mi sì wárìrì,

mo dúró ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ fún ọjọ́ ìdààmú

láti de sórí àwọn ènìyàn tó ń dojúkọ wá.

17Bí igi ọ̀pọ̀tọ́ ko tilẹ̀ tanná,

tí èso kò sí nínú àjàrà;

tí igi olifi ko le so,

àwọn oko ko sì mú oúnjẹ wá;

tí a sì ké agbo ẹran kúrò nínú agbo,

tí kò sì sí ọwọ́ ẹran ni ibùso mọ́,

18síbẹ̀, èmi ó láyọ̀ nínú Olúwa,

èmi yóò sí máa yọ nínú Ọlọ́run ìgbàlà mi.

19Olúwa Olódùmarè ni agbára mi,

òun yóò sí ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín,

yóò sí mú mi rìn lórí ibi gíga.

Nova Versão Internacional

Habacuque 3:1-19

A Oração de Habacuque

1Oração do profeta Habacuque. Uma confissão.

2Senhor, ouvi falar da tua fama;

tremo diante dos teus atos, Senhor.

Realiza de novo, em nossa época, as mesmas obras,

faze-as conhecidas em nosso tempo;

em tua ira, lembra-te da misericórdia.

3Deus veio de Temã,

o Santo veio do monte Parã.

Pausa3.3 Hebraico: Selá; também nos versículos 9 e 13.

Sua glória cobriu os céus,

e seu louvor encheu a terra.

4Seu esplendor era como a luz do sol;

raios lampejavam de sua mão,

onde se escondia o seu poder.

5Pragas iam adiante dele;

doenças terríveis seguiam os seus passos.

6Ele parou, e a terra tremeu;

olhou, e fez estremecer as nações.

Montes antigos se desmancharam;

colinas antiquíssimas se desfizeram.

Os caminhos dele são eternos.

7Vi a aflição das tendas de Cuchã;

tremiam as cortinas das tendas de Midiã.

8Era com os rios que estavas irado, Senhor?

Era contra os riachos o teu furor?

Foi contra o mar que a tua fúria transbordou

quando cavalgaste com os teus cavalos

e com os teus carros vitoriosos?

9Preparaste o teu arco;

pediste muitas flechas.

Pausa

Fendeste a terra com rios;

10os montes te viram e se contorceram.

Torrentes de água desceram com violência;

o abismo estrondou,

erguendo as suas ondas.

11O sol e a lua pararam em suas moradas,

diante do reflexo de tuas flechas voadoras,

diante do lampejo de tua lança reluzente.

12Com ira andaste a passos largos por toda a terra

e com indignação pisoteaste as nações.

13Saíste para salvar o teu povo,

para libertar o teu ungido.

Esmagaste o líder da nação ímpia,

tu o desnudaste da cabeça aos pés.

Pausa

14Com as suas próprias flechas lhe atravessaste a cabeça,

quando os seus guerreiros saíram

como um furacão para nos espalhar

com maldoso prazer,

como se estivessem prestes a devorar

o necessitado em seu esconderijo.

15Pisaste o mar com teus cavalos,

agitando as grandes águas.

16Ouvi isso, e o meu íntimo estremeceu,

meus lábios tremeram;

os meus ossos desfaleceram;

minhas pernas vacilavam.

Tranquilo, esperarei o dia da desgraça,

que virá sobre o povo que nos ataca.

17Mesmo não florescendo a figueira

e não havendo uvas nas videiras,

mesmo falhando a safra de azeitonas

e não havendo produção de alimento nas lavouras,

nem ovelhas no curral,

nem bois nos estábulos,

18ainda assim eu exultarei no Senhor

e me alegrarei no Deus da minha salvação.

19O Senhor, o Soberano, é a minha força;

ele faz os meus pés como os do cervo;

faz-me andar em lugares altos.

Para o mestre de música. Para os meus instrumentos de cordas.