Gẹnẹsisi 7 – YCB & CCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 7:1-24

1Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Noa pé, “Wọ inú ọkọ̀ lọ ìwọ àti gbogbo ìdílé rẹ, nítorí ìwọ nìkan ni mo rí bí olódodo nínú ìran yìí. 2Mú méje méje nínú àwọn ẹran tí ó mọ́, akọ àti abo, mú méjì méjì takọ tabo nínú àwọn ẹran aláìmọ́. 3Sì mú méje méje pẹ̀lú nínú onírúurú ẹyẹ, takọ tabo ni kí o mú wọn, wọlé sínú ọkọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí á ba à lè pa wọ́n mọ́ láààyè ní gbogbo ayé. 4Nítorí ní ọjọ́ méje sí ìhín, èmi yóò rọ òjò sórí ilẹ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi yóò sì pa gbogbo ohun alààyè tí mo ti dá run kúrò lórí ilẹ̀.”

5Noa sì ṣe ohun gbogbo tí Ọlọ́run pàṣẹ fún un.

6Noa jẹ́ ọmọ ẹgbẹ̀ta ọdún (600) nígbà tí ìkún omi dé sórí ilẹ̀. 77.7: Mt 24.38; Lk 17.27.Noa àti ìyàwó rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn aya ọmọ rẹ̀ sì wọ inú ọkọ láti sá àsálà fún ìkún omi. 8Méjì méjì ni àwọn ẹran tí ó mọ́ àti aláìmọ́, ti ẹyẹ àti ti gbogbo àwọn ẹ̀dá afàyàfà, 9akọ àti abo ni wọ́n wọlé pẹ̀lú Noa sínú ọkọ̀ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún Noa. 10Lẹ́yìn ọjọ́ keje, ìkún omi sì dé sí ayé.

117.11,12: 2Pt 3.6.Ní ọjọ́ kẹtà-dínlógún oṣù kejì, tí Noa pé ọmọ ẹgbẹ̀ta ọdún, ni gbogbo ìsun ibú ya, fèrèsé ìṣàn omi ọ̀run sì ṣí sílẹ̀. 12Òjò àrọ̀ìrọ̀dá sì rọ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.

13Ní ọjọ́ tí ìkún omi yóò bẹ̀rẹ̀ gan an ni Noa àti Ṣemu, Hamu àti Jafeti pẹ̀lú aya Noa àti aya àwọn ọmọ rẹ̀ wọ inú ọkọ̀. 14Wọ́n mú ẹranko igbó àti ohun ọ̀sìn ní onírúurú wọn, àwọn ẹ̀dá afàyàfà àti ẹyẹ àti àwọn ohun abìyẹ́ ni onírúurú wọn. 15Méjì méjì ni gbogbo ẹ̀dá tí ó ní èémí ìyè nínú wọlé pẹ̀lú Noa sínú ọkọ̀. 16Gbogbo wọ́n wọlé ní takọ tabo bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún Noa, Olúwa sì tì wọn mọ́ inú ọkọ̀.

17Òjò náà sì rọ̀ ní àrọ̀ìrọ̀dá fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, ọkọ̀ náà sì ń léfòó lórí omi, kúrò lórí ilẹ̀ bí omi náà ti ń pọ̀ sí i. 18Bí omi náà ti ń pọ̀ sí i, bẹ́ẹ̀ náà ni ọkọ̀ náà sì ń léfòó lójú omi. 19Omi náà pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó bo gbogbo àwọn òkè gíga tí ó wà lábẹ́ ọ̀run. 20Omi náà kún bo àwọn òkè, bí ìwọ̀n ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún. 21Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ parun: ẹyẹ, ohun ọ̀sìn, ẹranko igbó, àwọn ẹ̀dá afàyàfà àti ènìyàn. 22Gbogbo ohun tí ó wà lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ tó ní èémí ìyè ní ihò imú wọn ni ó kú. 23Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé ni a parẹ́: ènìyàn àti ẹranko, àwọn ohun tí ń rìn nílẹ̀, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run pátápátá ló ṣègbé. Noa àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ọkọ̀ ni ó ṣẹ́kù.

24Omi náà sì bo ilẹ̀ fún àádọ́jọ ọjọ́ (150).

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

创世记 7:1-24

洪水泛滥

1耶和华对挪亚说:“你和你一家都进入方舟,因为这个世代只有你在我眼中是义人。 2洁净的动物,你要每样带七公七母,不洁净的动物每样带一公一母, 3飞鸟每样带七公七母,叫它们以后可以在地上繁衍后代。 4因为七天之后,我要在地上降雨四十昼夜,毁灭我所造的一切生灵。” 5凡耶和华所吩咐的,挪亚都照办了。

6洪水泛滥的那一年,挪亚正好六百岁。 7挪亚与妻子、儿子们和儿媳们都进了方舟,躲避洪水。 8洁净的动物、不洁净的动物、飞禽和地上的一切爬虫, 9都一公一母成对地到挪亚那里,进了方舟,正如上帝对挪亚的吩咐。 10那七天过后,洪水在地上泛滥起来。

11挪亚六百岁那年的二月7:11 二月”按犹太历计算,本卷书所用月份都是按犹太历计算。十七日,所有深渊的泉源都裂开了,天上的水闸也打开了, 12地上倾盆大雨降了四十昼夜。 13那天,挪亚与他的儿子雅弗,还有挪亚的妻子和三个儿媳妇都进了方舟。 14所有的野兽、牲畜、地上的爬虫和飞鸟都按种类进入方舟。 15-16这些动物都一公一母成对地到挪亚那里,进入方舟,正如上帝对挪亚的吩咐。耶和华关上了方舟的门。

17洪水在地上泛滥了四十天,水不断地往上涨,把方舟漂了起来。 18洪水来势汹汹,淹没大地,方舟漂浮在水面上。 19水势越来越大,把天下各处的高山都淹没了。 20水淹没了群山,水面高出群山七米。 21世上所有的飞禽、走兽、牲畜、爬虫和人类都死了。 22在陆地上所有用鼻孔呼吸的生灵都死了。 23地上的人类、飞禽走兽和爬虫等一切生灵都被毁灭了,只剩下挪亚和跟他同在方舟里的生灵。 24洪水淹没大地一百五十天。