Gẹnẹsisi 46 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 46:1-34

Jakọbu lọ sí Ejibiti

1Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.

2Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!”

Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”

3Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀. 4Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnrarẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”

5Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀: 646.6: Ap 7.14,15.Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti. 7Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.

846.8-27: Ek 1.1-4; Nu 26.4-50.Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti Ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti:

Reubeni àkọ́bí Jakọbu.

9Àwọn ọmọkùnrin Reubeni:

Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.

10Àwọn ọmọkùnrin Simeoni:

Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.

11Àwọn ọmọkùnrin Lefi:

Gerṣoni, Kohati àti Merari.

12Àwọn ọmọkùnrin Juda:

Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani).

Àwọn ọmọ Peresi:

Hesroni àti Hamulu.

13Àwọn ọmọkùnrin Isakari!

Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.

14Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni:

Seredi, Eloni àti Jahaleli.

15Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.

16Àwọn ọmọkùnrin Gadi:

Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.

17Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri:

Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera.

Àwọn ọmọkùnrin Beriah:

Heberi àti Malkieli.

18Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìn-dínlógún (16) lápapọ̀.

19Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu:

Josẹfu àti Benjamini.

20Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.

21Àwọn ọmọ Benjamini:

Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.

22Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá (14) lápapọ̀.

23Àwọn ọmọ Dani:

Huṣimu.

24Àwọn ọmọ Naftali:

Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.

25Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.

26Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìn-dín-ní-àádọ́rin (66). 2746.27: Ap 7.14.Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin (70) lápapọ̀.

28Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni, 29Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.

30Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”

31Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá. 32Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.” 33Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe, 34ẹ fún un lésì pé, “àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.” Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni. Nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.

Swedish Contemporary Bible

1 Moseboken 46:1-34

Jakobs hela familj flyttar till Egypten

1Israel gav sig alltså iväg med alla sina tillhörigheter. När han kom till Beer Sheva offrade han slaktoffer till sin far Isaks Gud. 2Under natten talade Gud i en syn till Israel. ”Jakob! Jakob!” sa han. ”Ja, här är jag”, svarade Jakob. 3”Jag är Gud”, sa Gud, ”din fars Gud. Var inte rädd för att resa ned till Egypten, för jag ska göra dig till ett stort folk där. 4Jag ska följa dig till Egypten, och jag ska föra dig tillbaka därifrån. Josefs hand kommer att sluta dina ögon.”

5Då lämnade Jakob Beer Sheva. Israels söner tog med sig sin far Jakob, tillsammans med sina barn och hustrur, och de reste med de vagnar som farao hade skickat för att hämta dem.

6De tog med sig sina djur och alla de ägodelar som de samlat i Kanaans land, och så kom Jakob och hela hans familj till Egypten. 7Jakob tog med sig alla sina barn, söner och döttrar, sonsöner och sondöttrar, hela sin släkt.

8Här följer namnen på Israels söner som kom till Egypten, Jakob och hans söner, av vilka Ruben var den förstfödde:

9Rubens söner var Henok, Pallu, Hesron och Karmi.

10Simons söner var Jemuel, Jamin, Ohad, Jakin, Sochar och Saul, vars mor var en kanaaneisk kvinna.

11Levis söner var Gershon, Kehat och Merari.

12Judas söner var Er, Onan, Shela, Peres och Serach. Er och Onan hade dock dött i Kanaan. Peres söner hette Hesron och Hamul.

13Isaskars söner var Tola, Puva, Jashuv och Shimron.

14Sebulons söner var Sered, Elon och Jachleel.

15Dessa var alla ättlingar till Jakob och Lea, och tillsammans med dottern Dina, som också föddes åt Jakob i Paddan Aram, var de trettiotre personer.

16Gads söner var Sifjon, Haggi, Shuni, Esbon, Eri, Arodi och Areli.

17Ashers söner var Jimna, Jishva och Jishvi, Beria och de hade en syster som hette Serach. Berias söner hette Hever och Malkiel.

18Dessa sexton personer var barn till Jakob och Silpa, den slavflicka som Lea fått av sin far Laban.

19Jakobs och hans hustru Rakels söner var Josef och Benjamin.

20Josefs söner var Manasse och Efraim, födda i Egypten av Asenat, dotter till Poti Fera, präst i On.

21Benjamins söner var Bela, Beker, Ashbel, Gera, Naaman, Echi, Rosh, Muppim, Huppim46:21 Namnen Echi, Rosh, Muppim, Huppim är osäkra; ev. Achiram, Shufam, Hufam. och Ard.

22Dessa var Rakels och Jakobs söner, sammanlagt fjorton personer.

23Dans son var Hushim.

24Naftalis söner var Jachseel, Guni, Jeser och Shillem.

25Dessa var Jakobs söner med Bilha, Rakels slavflicka som Laban gett sin dotter, sammanlagt sju personer.

26De ättlingar som reste med Jakob till Egypten var sextiosex till antalet, sönernas hustrur oräknade. 27Om man också räknar med Josefs två söner som föddes åt honom i Egypten, utgjorde Jakobs hela familj i Egypten totalt sjuttio personer.

28Jakob sände Juda i förväg till Josef för att hitta fram till Goshen. När de kom till Goshen, 29gjorde Josef sig beredd med sin vagn och mötte dem där. Så snart han fick se sin far kastade han sig i hans famn. De kramade om varandra och grät länge.

30Sedan sa Israel till Josef: ”Nu är jag beredd att dö, för jag har sett dig igen och vet att du lever.”

31Josef sa sedan till sina bröder och till hela sin fars familj: ”Jag ska gå och berätta för farao att mina bröder och hela min fars familj har kommit hit till mig från Kanaans land 32och att ni är herdar och att ni har fört med er era hjordar och allt ni äger. 33När sedan farao kallar på er och frågar er om ert yrke, 34så ska ni säga till honom: ’Vi, dina tjänare, har varit herdar ända sedan ungdomen, vi liksom våra förfäder.’ När han hör detta, kommer han att låta er bo här i Goshens land.” Herdar var nämligen avskydda av egypterna.