Gẹnẹsisi 47 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 47:1-31

1Josẹfu lọ sọ fún Farao pé, “Baba mi àti àwọn arákùnrin mi, pẹ̀lú agbo ẹran, agbo màlúù àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, ti dé láti ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì ti wà ní ilẹ̀ Goṣeni báyìí.” 2Ó yan márùn-ún àwọn arákùnrin rẹ́, ó sì fi wọ́n han Farao.

3Farao béèrè lọ́wọ́ àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Kí ni iṣẹ́ yín?”

Wọ́n sì fèsì pé, “Darandaran ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti jẹ́ darandaran” 4Wọ́n sì tún sọ fun un síwájú sí i pé, “A wá láti gbé ìhín yìí fún ìgbà díẹ̀ nítorí ìyàn náà mú púpọ̀ ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ohun ọ̀sìn àwa ìránṣẹ́ rẹ kò sì rí ewéko jẹ. Nítorí náà jọ̀wọ́ má ṣàì jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni.”

5Farao wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ tọ̀ ọ́ wá, 6Ilẹ̀ Ejibiti sì nìyí níwájú rẹ: Mú àwọn arákùnrin rẹ tẹ̀dó sí ibi tí ó dára jù nínú ilẹ̀ náà. Jẹ́ kí wọn máa gbé ní Goṣeni. Bí o bá sì mọ ẹnikẹ́ni nínú wọn tí ó ní ẹ̀bùn ìtọ́jú ẹran, fi wọ́n ṣe olùtọ́jú ẹran ọ̀sìn mi.”

7Nígbà náà ni Josẹfu mú Jakọbu baba rẹ̀ wọlé wá sí iwájú Farao. Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu súre fún Farao tán. 8Farao béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ọmọ ọdún mélòó ni ọ́?”

9Jakọbu sì dá Farao lóhùn, “Ọdún ìrìnàjò ayé mi jẹ́ àádóje (130), ọjọ́ mi kò pọ̀, ó sì kún fún wàhálà, síbẹ̀ kò ì tí ì tó ti àwọn baba mi.” 10Nígbà náà ni Jakọbu tún súre fún Farao, ó sì jáde lọ kúrò níwájú rẹ̀.

11Josẹfu sì fi baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sí ilẹ̀ Ejibiti, ó sì fún wọn ní ohun ìní ní ibi tí ó dára jù ní ilẹ̀ náà, ní agbègbè Ramesesi bí Farao ti pàṣẹ. 12Josẹfu sì pèsè oúnjẹ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi iye àwọn ọmọ wọn.

Josẹfu àti ìyàn ní ilẹ̀ Ejibiti

13Ṣùgbọ́n kò sí oúnjẹ ní gbogbo ilẹ̀ náà nítorí tí ìyàn náà mú púpọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ Ejibiti àti ilẹ̀ Kenaani gbẹ nítorí ìyàn náà. 14Josẹfu gba gbogbo owó tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti àti Kenaani ní ìpààrọ̀ fún ti ọkà tí wọn ń rà, ó sì mú owó náà wá sí ààfin Farao. 15Nígbà tí owó wọn tán pátápátá ní Ejibiti àti Kenaani, gbogbo Ejibiti wá bá Josẹfu, wọ́n wí pé, “Fún wa ní oúnjẹ, èéṣe tí a ó fi kú ní ojú rẹ? Gbogbo owó wa ni a ti ná tán.”

16Josẹfu wí pé, “Ẹ mú àwọn ẹran ọ̀sìn yín wá, èmi yóò fún un yín ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn yín, níwọ̀n bí owó yín ti tan.” 17Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn tọ Josẹfu wá, ó sì fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹṣin, àgùntàn, ewúrẹ́, màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn. Ó sì mú wọn la ọdún náà já, tí ó ń fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn wọn.

18Nígbà tí ọdún náà parí, wọn padà tọ̀ ọ́ wá ní ọdún tí ó tẹ̀lé, wọn wí pé, “A kò le fi pamọ́ fun olúwa wa pé níwọ̀n bí owó wa ti tan tí gbogbo ẹran ọ̀sìn wa sì ti di tirẹ̀ pé, kò sí ohunkóhun tókù fún olúwa wa bí kò ṣe ara wa àti ilẹ̀ wa. 19Èéṣe tí àwa yóò fi parun lójú rẹ, ra àwa tìkára wa àti ilẹ̀ wa ní ìpààrọ̀ fún oúnjẹ, àwa àti ilẹ̀ wa yóò sì wà nínú ìgbèkùn Farao. Fún wa ni oúnjẹ kí àwa kí ó má ba à kú, kí ilẹ̀ wa má ba à di ahoro.”

20Nítorí náà Josẹfu ra gbogbo ilẹ̀ tí ó wà ní Ejibiti fún Farao, kò sí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù ní Ejibiti tí kò ta ilẹ̀ tirẹ̀ nítorí ìyàn náà mú jù fún wọn. Gbogbo ilẹ̀ náà sì di ti Farao, 21Josẹfu sì sọ gbogbo ará Ejibiti di ẹrú láti igun kan dé èkejì 22Ṣùgbọ́n ṣá, kò ra ilẹ̀ àwọn àlùfáà, nítorí wọ́n ń gba ìpín oúnjẹ lọ́wọ́ Farao, wọn sì ní oúnjẹ tí ó tó láti inú ìpín tí Farao ń fún wọn. Ìdí nìyí tí wọn kò fi ta ilẹ̀ wọn.

23Josẹfu wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Níwọ́n ìgbà tí mo ti ra ẹ̀yin àti ilẹ̀ yín tan lónìí fún Farao, irúgbìn rèé, ẹ lọ gbìn ín sí ilẹ̀ náà. 24Ṣùgbọ́n nígbà tí ìre oko náà bá jáde, ẹ ó mú ìdákan nínú ìdámárùn-ún rẹ̀ fún Farao. Ẹ le pa ìdámẹ́rin tókù mọ́ fún ara yín àti ìdílé yín àti àwọn ọmọ yín.”

25Wọ́n dá á lóhùn pé, “O ti gbà wá là, Ǹjẹ́ kí a rí ojúrere níwájú olúwa wa, àwa yóò di ẹrú Farao.”

26Nítorí náà Josẹfu sọ ọ́ di òfin nípa ọ̀rọ̀ ilẹ̀ ni Ejibiti, ó sì wà bẹ́ẹ̀ di òní olónìí pé, ìdákan nínú ìdámárùn-ún ìre oko jẹ́ ti Farao, ilẹ̀ àwọn àlùfáà nìkan ni kò di ti Farao.

27Àwọn ará Israẹli sì tẹ̀dó sí Ejibiti ní agbègbè Goṣeni. Wọ́n ní ohun ìní fún ara wọn, wọ́n sì bí sí i tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n pọ̀ si gidigidi ní iye.

28Jakọbu gbé ní Ejibiti fún ọdún mẹ́tà-dínlógún (17) iye ọdún ọjọ́ ayé rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀tàdín ní àádọ́jọ (147). 2947.29,30: Gẹ 49.29-32; 50.6.Nígbà tí àkókò ń súnmọ́ etílé fún Israẹli láti kú, ó pe Josẹfu, ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Bí mo bá rí ojúrere ni ojú rẹ̀ fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi, kí o sì ṣe ìlérí pé ìwọ yóò fi àánú àti òtítọ́ hàn sí mi. Má ṣe sin òkú mi sí ilẹ̀ Ejibiti, 30Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo bá sinmi pẹ̀lú àwọn baba mi, gbé mí jáde kúrò ní Ejibiti kí o sì sin mí sí ibi tí wọ́n sin àwọn baba mi sí.”

Josẹfu sì dáhùn wí pé, “Èmi ó ṣe bí ìwọ ti wí.”

31Jakọbu wí pé, “Búra fún mi,” Josẹfu sì búra fún un. Israẹli sì tẹ orí rẹ̀ ba, bí ó ti sinmi lé orí ibùsùn rẹ̀.

Swedish Contemporary Bible

1 Moseboken 47:1-31

1Josef gick och berättade för farao: ”Min far och mina bröder har kommit hit från Kanaans land med alla sina hjordar och tillhörigheter. De befinner sig nu i Goshens land.”

2Han hade tagit med sig fem av sina bröder och presenterade dem för farao. 3Farao frågade dem: ”Vad har ni för yrke?” De svarade: ”Vi, dina tjänare, är herdar, som våra förfäder. 4Vi har kommit för att bo en tid här i Egypten, för det finns inget bete för våra hjordar i Kanaan. Hungersnöden har varit mycket svår där. Vi ber dig om tillstånd att få bosätta oss i Goshens land.”

5Farao sa då till Josef: ”Din far och dina bröder har alltså kommit till dig. 6Hela landet är öppet för dig. Låt dem bo i den bästa delen av landet – Goshen passar utmärkt. Och om du vet några av dem som är skickliga nog, så ge dem ansvaret också för mina hjordar.”

7Sedan tog Josef sin far Jakob till farao och Jakob hälsade farao med en välsignelse. 8”Hur gammal är du?” frågade farao honom. 9Jakob svarade: ”Min vandringstid har bara blivit 130 få och hårda år, inte alls som mina förfäders.” 10Sedan välsignade Jakob farao innan han gick därifrån.

11Josef lät sin far och sina bröder bosätta sig i Egypten och gav dem land i de bästa områdena, i Ramses land, precis som farao hade befallt. 12Josefs far och bröder och hela hans fars husfolk fick också sitt underhåll av Josef, alltefter familjernas storlek.

13Hungersnöden blev allt värre i hela regionen, hela Egypten och Kanaans land var utan mat och höll på att gå under av svält. 14Josef tog emot alla de pengar som fanns i Egypten och Kanaan i utbyte mot säd och förde dem till faraos palats. 15När även pengarna tog slut både i Egypten och i Kanaan, kom egypterna till Josef och sa:

”Våra pengar är slut, men ge oss bröd! Varför ska vi behöva dö här inför dig?” 16”Nåväl”, svarade Josef. ”Om era pengar är slut, får ni ge mig era djur i utbyte mot mat.”

17Då förde de sin boskap till Josef i utbyte mot mat. Josef försörjde dem det året i utbyte mot alla hästar, hjordar, kreatur och åsnor i hela Egypten.

18Följande år kom de tillbaka igen och sa: ”Vi kan inte dölja detta för dig, herre. Våra pengar är slut och vår boskap är borta, och det finns inget vi kan erbjuda dig annat än oss själva och den mark vi äger. 19Varför ska vi behöva förgås här inför dig, både vi och vår jord? Köp oss och marken vi äger, i utbyte mot mat, så ska vi med vår mark bli slavar åt farao. Vi överlämnar oss själva i utbyte mot mat, så att vi får leva och så att vårt land inte blir ödelagt.”

20Då köpte Josef upp all mark i Egypten åt farao. Alla egypter sålde sina åkrar till honom, eftersom svälten var så svår, och till slut ägde farao hela landet. 21På så sätt blev hela Egyptens folk faraos slavar47:21 Enligt den samaritanska texten och Septuaginta (och även den latinska Vulgata). Enligt den masoretiska texten blir översättningen: …förflyttades människorna till städer.. 22Det enda land han inte köpte var prästernas, för de fick sitt underhåll från farao och fick således mat av farao och behövde alltså inte sälja sin jord.

23Sedan sa Josef till folket: ”Nu har jag köpt både er och all mark åt farao. Här får ni utsäde till åkrarna. 24Men när ni skördar, så tillhör en femtedel av allt ni får farao. Behåll de resterande fyra femtedelarna till utsäde och till mat åt er själva och era familjer och era barn.” 25”Du har räddat våra liv”, sa de. ”Låt oss alltid få möta din välvilja, herre! Vi blir gärna faraos slavar.”

26Då stiftade Josef en lag för hela Egyptens land och den gäller fortfarande: farao ska ha en femtedel av all skörd som skatt. Detta gällde dock inte det land som ägdes av prästerna.

Jakob och Josef dör i Egypten

Jakob välsignar Josef

27Israeliterna47:27 Israel var det namn Gud gav Jakob i 32:28. Israeliterna betyder alltså Jakobs släkt. bodde alltså i Goshens land i Egypten och skaffade sig mark där. De var fruktsamma och förökade sig mycket.

28Jakob levde sjutton år i Egypten och blev 147 år gammal. 29När tiden närmade sig för honom att dö, kallade han på sin son Josef och sa till honom: ”Visa mig den välviljan att lägga handen under min höft och svär47:29 Se not till 24:3. att du ska visa mig den godheten och trofastheten att du inte begraver mig i Egypten, 30utan när jag gått till vila hos mina fäder47:30 Gå till vila hos sina fäder var ett vanligt sätt att beteckna döden., ta mig ut ur Egypten och begrav mig i deras grav.” Och Josef lovade att göra som han sa. 31”Lova det med en ed”, fortsatte Jakob. Då svor Josef eden, och Israel böjde sig ner, lutad mot sin stav47:31 Enligt Septuaginta och Heb 11:21. Enligt den masoretiska texten: Israel böjde knä vid sängens huvudgärd..