Gẹnẹsisi 38 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 38:1-30

Juda àti Tamari

1Ní àkókò náà, Juda lọ kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ láti lọ dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin ará Adullamu kan tí ń jẹ́ Hira. 2Juda sì pàdé ọmọbìnrin Kenaani kan níbẹ̀ ẹni ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣua. Ó sì fi ṣe aya, ó sì bá a lòpọ̀; 3ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, tí ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Eri. 4Ó sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Onani. 5Ó sì tún bí ọmọkùnrin mìíràn, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Ṣela. Ní Kesibu ni ó wà nígbà tí ó bí i.

6Juda sì fẹ́ aya fún Eri, àkọ́bí rẹ̀, orúkọ aya náà ni Tamari. 7Ṣùgbọ́n Eri àkọ́bí Juda ṣe ènìyàn búburú níwájú Olúwa, Ọlọ́run sì pa á.

8Nígbà náà ni Juda wí fún Onani, “Bá aya arákùnrin rẹ lòpọ̀, kí o ṣe ojúṣe rẹ fun un gẹ́gẹ́ bí àbúrò ọkọ, kí ó ba à le bí ọmọ fún un ní orúkọ arákùnrin rẹ.” 9Ṣùgbọ́n Onani mọ̀ pé àwọn ọmọ náà kì yóò jẹ́ ti òun, nítorí náà ni gbogbo ìgbà tí ó bá wọlé tọ aya arákùnrin rẹ̀ lọ, ilẹ̀ ni ó ń da nǹkan ọkùnrin rẹ̀ sí, kí ó má bá a bímọ fún arákùnrin rẹ̀. 10Ohun tí ó ń ṣe yìí burú lójú Olúwa, ó sì pa òun náà pẹ̀lú.

11Nígbà náà ni Juda wí fún Tamari, ìyàwó ọmọ rẹ̀ pé, “Lọ máa gbé bí opó ní ilé baba rẹ, títí tí Ṣela yóò fi dàgbà ó lérò pé òun náà lè kú bí àwọn arákùnrin rẹ̀ tókù.” Nígbà náà ni Tamari ń lọ gbé ilé baba rẹ̀.

12Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ìyàwó Juda, ọmọbìnrin Ṣua sì kú, nígbà tí ọjọ́ ọ̀fọ̀ Juda sì pé, ó gòkè lọ sí Timna, sí ọ̀dọ̀ àwọn tí ń bá a rẹ́run àgùntàn rẹ̀, Hira ará Adullamu tí í ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀ sì bá a lọ.

13Nígbà tí ẹnìkan sọ fún Tamari pé, “Baba ọkọ ọ̀ rẹ̀ wà ní ọ̀nà àjò rẹ̀ sí Timna láti rẹ́run àgùntàn rẹ̀.” 14Ó bọ́ aṣọ opó rẹ̀, ó sì fi ìbòjú bo ojú ara rẹ̀ kí wọn má ba à mọ̀ ọ́n. Ó sì jókòó sí ẹnu-bodè Enaimu, èyí tí ó wà ní ọ̀nà Timna. Nítorí ó rí i wí pé, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Ṣela ti dàgbà, síbẹ̀, a kò fi òun fún un gẹ́gẹ́ bí aya.

15Nígbà tí Juda rí i, ó rò pé panṣágà ni, nítorí ó ti bo ojú rẹ̀. 16Láìmọ̀ pé, aya ọmọ òun ní í ṣe, ó yà tọ̀ ọ́ ní ẹ̀bá ọ̀nà, ó wí pé, “Wá kí èmi kí ó lè wọlé tọ̀ ọ́.”

Òun sì wí pé “Kín ni ìwọ yóò fi fún mi kí ìwọ kó lè wọlé tọ̀ mí.”

17Ó sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọ ewúrẹ́ kan ránṣẹ́ sí ọ láti inú agbo ẹran.”

Obìnrin náà sì dáhùn pé, “Ṣé ìwọ yóò fún mi ní ohun kan gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí títí tí ìwọ yóò fi fi ránṣẹ́?”

18Juda sì bi í pé, “Ẹ̀rí wo ni kí n fún ọ?”

Ó sì dáhùn pé, “Èdìdì ìdámọ̀ okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ rẹ ti ń bẹ ní ọwọ́ rẹ.” Ó sì kó wọn fún un, ó sì sùn tì í, obìnrin náà sì lóyún nípasẹ̀ rẹ̀. 19Lẹ́yìn ìgbà tí ó lọ, ó bọ́ ìbòjú ojú rẹ̀, ó sì tún wọ aṣọ opó rẹ̀ padà.

20Juda sì rán ọmọ ewúrẹ́ náà láti ọwọ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀, ará Adullamu náà lọ láti gba ògo nnì wá lọ́wọ́ obìnrin náà. Ṣùgbọ́n wọn kò bá obìnrin náà níbẹ̀. 21Ó béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn àdúgbò náà pé, “Níbo ni alágbèrè ojúbọ òrìṣà tí ó wà ní etí ọ̀nà Enaimu wà?”

Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Kò sí alágbèrè ojúbọ òrìṣà kankan níbí.”

22Ó sì padà lọ sọ́dọ̀ Juda ó wí fún un pé, “Èmí kò rí i, à ti pé àwọn aládùúgbò ibẹ̀ sọ pé kò sí alágbèrè ojúbọ òrìṣà kankan níbẹ̀.”

23Nígbà náà ni Juda wí pé, “Jẹ́ kí ó máa kó àwọn ohun tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ lọ bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ a ó di ẹlẹ́yà. Mo sá à fi ọmọ ewúrẹ́ ránṣẹ́ sí i, ṣùgbọ́n ìwọ kò rí òun.”

24Lẹ́yìn nǹkan bí oṣù mẹ́ta, wọn sọ fún Juda pé, “Tamari aya ọmọ rẹ̀ ṣe àgbèrè, ó sì ti lóyún.”

Juda sì wí pé, “Ẹ mú un jáde, kí ẹ sì dá iná sun ún.”

25Bí wọ́n sì ti ń mú un jáde, ó ránṣẹ́ sí baba ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó ni àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó fún mi lóyún. Wò ó, bóyá o lè mọ ẹni tí ó ni èdìdì ìdámọ̀, okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ wọ̀nyí.”

26Juda sì dá wọn mọ̀, ó sì wí pé, “O ṣe olódodo jù mí lọ, níwọ̀n ìgbà tí n kò fi fún Ṣela ọmọ mi.” Kò sì bá a lòpọ̀ mọ́ láti ọjọ́ náà.

27Nígbà tí àsìkò ìbímọ rẹ̀ tó. Ìbejì ọkùnrin ni ó bí. 28Bí ó sì ti ń bímọ, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ náà na ọwọ́ jáde; agbẹ̀bí sì so okùn òdòdó mọ́ ọmọ náà ní ọrùn ọwọ́. Ó sì wí pé, “Èyí ni o kọ́kọ́ jáde.” 29Ṣùgbọ́n nígbà tí ó fa ọwọ́ rẹ̀ padà, èkejì rẹ̀ jáde. Tamari sì wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Peresi. 30Nígbà náà ni èkejì tí a ti so okùn olódòdó mọ́ lọ́rùn ọwọ́ jáde, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ni Sera.

Persian Contemporary Bible

پيدايش 38:1-30

يهودا و تامار

1در همان روزها بود كه يهودا خانهٔ پدر خود را ترک نموده، به عدولام رفت و نزد شخصی به نام حيره ساكن شد. 2در آنجا او دختر مردی كنعانی به نام شوعا را به زنی گرفت 3و از او صاحب پسری شد كه او را عير ناميد. 4شوعا بار ديگر حامله شد و پسری زاييد و او را اونان نام نهاد. 5وقتی آنها در كزيب بودند، زن يهودا پسر سوم خود را به دنيا آورد و او را شيله ناميد.

6وقتی عير، پسر ارشد يهودا، بزرگ شد پدرش دختری را به نام تامار برای او به زنی گرفت. 7اما چون عير شخص شروری بود، خداوند او را كُشت.

8آنگاه يهودا به اونان برادر عير گفت: «مطابق رسم ما، تو بايد با زن برادرت تامار ازدواج كنی تا نسل برادرت از بين نرود.» 9اونان با تامار ازدواج كرد، اما چون نمی‌خواست فرزندش از آنِ كس ديگری باشد، هر وقت با او نزديكی می‌كرد، جلوگيری نموده، نمی‌گذاشت تامار بچه‌ای داشته باشد كه از آنِ برادر مرده‌اش شود. 10اين كار اونان در نظر خداوند ناپسند آمد و خدا او را نيز كشت. 11يهودا به عروس خود تامار گفت: «به خانهٔ پدرت برو و بيوه بمان تا اين كه پسر كوچكم شيله بزرگ شود. آن وقت می‌توانی با او ازدواج كنی.» (ولی يهودا قلباً راضی به اين كار نبود، چون می‌ترسيد شيله نيز مثل دو برادر ديگرش هلاک شود.) پس تامار به خانه پدرش رفت.

12پس از مدتی، زن يهودا مُرد. وقتی كه روزهای سوگواری سپری شد، يهودا با دوستش حيرهٔ عدولامی برای نظارت بر پشمچينی گوسفندان به تمنه رفت.

13به تامار خبر دادند كه پدر شوهرش برای چيدنِ پشمِ گوسفندان به طرف تمنه حركت كرده است. 14تامار لباس بيوگی خود را از تن درآورد و برای اين كه شناخته نشود چادری بر سر انداخته، دم دروازهٔ عينايم سر راه تمنه نشست، زيرا او ديد كه هر چند شيله بزرگ شده ولی او را به عقد وی در نياورده‌اند.

15يهودا او را ديد، ولی چون او روی خود را پوشانيده بود، او را نشناخت و پنداشت زن بدكاره‌ای است. 16پس به كنار جاده به طرف او رفته، به او پيشنهاد كرد كه با وی همبستر شود، غافل از اين كه عروس خودش می‌باشد. تامار به او گفت: «چقدر می‌خواهی به من بدهی؟»

17يهودا گفت: «بزغاله‌ای از گله‌ام برايت خواهم فرستاد.»

زن گفت: «برای اين كه مطمئن شوم كه بزغاله را می‌فرستی بايد چيزی نزد من گرو بگذاری.»

18يهودا گفت: «چه چيزی را گرو بگذارم؟»

زن جواب داد: «مُهر و عصايت را.» پس يهودا آنها را به او داد و با وی همبستر شد و در نتيجه تامار آبستن شد. 19پس از اين واقعه تامار بازگشت و دوباره لباس بيوِگی خود را پوشيد.

20يهودا بزغاله را به دوستش حيرهٔ عدولامی سپرد تا آن را برای آن زن ببرد و اشیا گرويی را پس بگيرد، اما حيره آن زن را نيافت. 21پس، از مردم آنجا پرسيد: «آن زن بدكاره‌ای كه دمِ دروازه، سر راه نشسته بود كجاست؟»

به او جواب دادند: «ما هرگز چنين زنی در اينجا نديده‌ايم.»

22حيره نزد يهودا بازگشت و به او گفت: «او را نيافتم و مردمان آنجا هم می‌گويند چنين زنی را در آنجا نديده‌اند.»

23يهودا گفت: «بگذار آن اشیا مال او باشد، مبادا رسوا شويم. به هر حال من بزغاله را برای او فرستادم، ولی تو نتوانستی او را پيدا كنی.»

24حدود سه ماه بعد از اين واقعه، به يهودا خبر دادند كه عروسش تامار زنا كرده و حامله است. يهودا گفت: «او را بيرون آوريد و بسوزانيد.»

25در حالی كه تامار را بيرون می‌آوردند تا او را بكشند اين پيغام را برای پدر شوهرش فرستاد: «مردی كه صاحب اين مُهر و عصا می‌باشد، پدر بچهٔ من است، آيا او را می‌شناسی؟»

26يهودا مُهر و عصا را شناخت و گفت: «او تقصيری ندارد، زيرا من به قول خود وفا نكردم و او را برای پسرم شيله نگرفتم.» يهودا ديگر با او همبستر نشد.

27چون وقت وضع حمل تامار رسيد، دوقلو زاييد. 28در موقع زايمان، يكی از پسرها دستش را بيرون آورد و قابله نخ قرمزی به مچ دست او بست. 29اما او دست خود را عقب كشيد و پسر ديگر، اول به دنيا آمد. قابله گفت: «چگونه بيرون آمدی؟» پس او را فارص (يعنی «بيرون آمدن») ناميدند. 30اندكی بعد، پسری كه نخ قرمز به دستش بسته شده بود متولد شد و او را زارح (يعنی «قرمز») ناميدند.