Gẹnẹsisi 38 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 38:1-30

Juda àti Tamari

1Ní àkókò náà, Juda lọ kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ láti lọ dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin ará Adullamu kan tí ń jẹ́ Hira. 2Juda sì pàdé ọmọbìnrin Kenaani kan níbẹ̀ ẹni ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣua. Ó sì fi ṣe aya, ó sì bá a lòpọ̀; 3ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, tí ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Eri. 4Ó sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Onani. 5Ó sì tún bí ọmọkùnrin mìíràn, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Ṣela. Ní Kesibu ni ó wà nígbà tí ó bí i.

6Juda sì fẹ́ aya fún Eri, àkọ́bí rẹ̀, orúkọ aya náà ni Tamari. 7Ṣùgbọ́n Eri àkọ́bí Juda ṣe ènìyàn búburú níwájú Olúwa, Ọlọ́run sì pa á.

8Nígbà náà ni Juda wí fún Onani, “Bá aya arákùnrin rẹ lòpọ̀, kí o ṣe ojúṣe rẹ fun un gẹ́gẹ́ bí àbúrò ọkọ, kí ó ba à le bí ọmọ fún un ní orúkọ arákùnrin rẹ.” 9Ṣùgbọ́n Onani mọ̀ pé àwọn ọmọ náà kì yóò jẹ́ ti òun, nítorí náà ni gbogbo ìgbà tí ó bá wọlé tọ aya arákùnrin rẹ̀ lọ, ilẹ̀ ni ó ń da nǹkan ọkùnrin rẹ̀ sí, kí ó má bá a bímọ fún arákùnrin rẹ̀. 10Ohun tí ó ń ṣe yìí burú lójú Olúwa, ó sì pa òun náà pẹ̀lú.

11Nígbà náà ni Juda wí fún Tamari, ìyàwó ọmọ rẹ̀ pé, “Lọ máa gbé bí opó ní ilé baba rẹ, títí tí Ṣela yóò fi dàgbà ó lérò pé òun náà lè kú bí àwọn arákùnrin rẹ̀ tókù.” Nígbà náà ni Tamari ń lọ gbé ilé baba rẹ̀.

12Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ìyàwó Juda, ọmọbìnrin Ṣua sì kú, nígbà tí ọjọ́ ọ̀fọ̀ Juda sì pé, ó gòkè lọ sí Timna, sí ọ̀dọ̀ àwọn tí ń bá a rẹ́run àgùntàn rẹ̀, Hira ará Adullamu tí í ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀ sì bá a lọ.

13Nígbà tí ẹnìkan sọ fún Tamari pé, “Baba ọkọ ọ̀ rẹ̀ wà ní ọ̀nà àjò rẹ̀ sí Timna láti rẹ́run àgùntàn rẹ̀.” 14Ó bọ́ aṣọ opó rẹ̀, ó sì fi ìbòjú bo ojú ara rẹ̀ kí wọn má ba à mọ̀ ọ́n. Ó sì jókòó sí ẹnu-bodè Enaimu, èyí tí ó wà ní ọ̀nà Timna. Nítorí ó rí i wí pé, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Ṣela ti dàgbà, síbẹ̀, a kò fi òun fún un gẹ́gẹ́ bí aya.

15Nígbà tí Juda rí i, ó rò pé panṣágà ni, nítorí ó ti bo ojú rẹ̀. 16Láìmọ̀ pé, aya ọmọ òun ní í ṣe, ó yà tọ̀ ọ́ ní ẹ̀bá ọ̀nà, ó wí pé, “Wá kí èmi kí ó lè wọlé tọ̀ ọ́.”

Òun sì wí pé “Kín ni ìwọ yóò fi fún mi kí ìwọ kó lè wọlé tọ̀ mí.”

17Ó sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọ ewúrẹ́ kan ránṣẹ́ sí ọ láti inú agbo ẹran.”

Obìnrin náà sì dáhùn pé, “Ṣé ìwọ yóò fún mi ní ohun kan gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí títí tí ìwọ yóò fi fi ránṣẹ́?”

18Juda sì bi í pé, “Ẹ̀rí wo ni kí n fún ọ?”

Ó sì dáhùn pé, “Èdìdì ìdámọ̀ okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ rẹ ti ń bẹ ní ọwọ́ rẹ.” Ó sì kó wọn fún un, ó sì sùn tì í, obìnrin náà sì lóyún nípasẹ̀ rẹ̀. 19Lẹ́yìn ìgbà tí ó lọ, ó bọ́ ìbòjú ojú rẹ̀, ó sì tún wọ aṣọ opó rẹ̀ padà.

20Juda sì rán ọmọ ewúrẹ́ náà láti ọwọ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀, ará Adullamu náà lọ láti gba ògo nnì wá lọ́wọ́ obìnrin náà. Ṣùgbọ́n wọn kò bá obìnrin náà níbẹ̀. 21Ó béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn àdúgbò náà pé, “Níbo ni alágbèrè ojúbọ òrìṣà tí ó wà ní etí ọ̀nà Enaimu wà?”

Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Kò sí alágbèrè ojúbọ òrìṣà kankan níbí.”

22Ó sì padà lọ sọ́dọ̀ Juda ó wí fún un pé, “Èmí kò rí i, à ti pé àwọn aládùúgbò ibẹ̀ sọ pé kò sí alágbèrè ojúbọ òrìṣà kankan níbẹ̀.”

23Nígbà náà ni Juda wí pé, “Jẹ́ kí ó máa kó àwọn ohun tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ lọ bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ a ó di ẹlẹ́yà. Mo sá à fi ọmọ ewúrẹ́ ránṣẹ́ sí i, ṣùgbọ́n ìwọ kò rí òun.”

24Lẹ́yìn nǹkan bí oṣù mẹ́ta, wọn sọ fún Juda pé, “Tamari aya ọmọ rẹ̀ ṣe àgbèrè, ó sì ti lóyún.”

Juda sì wí pé, “Ẹ mú un jáde, kí ẹ sì dá iná sun ún.”

25Bí wọ́n sì ti ń mú un jáde, ó ránṣẹ́ sí baba ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó ni àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó fún mi lóyún. Wò ó, bóyá o lè mọ ẹni tí ó ni èdìdì ìdámọ̀, okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ wọ̀nyí.”

26Juda sì dá wọn mọ̀, ó sì wí pé, “O ṣe olódodo jù mí lọ, níwọ̀n ìgbà tí n kò fi fún Ṣela ọmọ mi.” Kò sì bá a lòpọ̀ mọ́ láti ọjọ́ náà.

27Nígbà tí àsìkò ìbímọ rẹ̀ tó. Ìbejì ọkùnrin ni ó bí. 28Bí ó sì ti ń bímọ, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ náà na ọwọ́ jáde; agbẹ̀bí sì so okùn òdòdó mọ́ ọmọ náà ní ọrùn ọwọ́. Ó sì wí pé, “Èyí ni o kọ́kọ́ jáde.” 29Ṣùgbọ́n nígbà tí ó fa ọwọ́ rẹ̀ padà, èkejì rẹ̀ jáde. Tamari sì wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Peresi. 30Nígbà náà ni èkejì tí a ti so okùn olódòdó mọ́ lọ́rùn ọwọ́ jáde, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ni Sera.

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

Начало 38:1-30

Иуда и Фамарь

1Иуда в то время оставил братьев и поселился у одного человека из Адуллама по имени Хира. 2Там Иуда встретил дочь ханонея, которого звали Шуа. Он женился на ней и стал с ней жить; 3она забеременела и родила сына, которого назвали Ир. 4Она вновь забеременела и родила сына, и назвала его Онан. 5Она родила ещё одного сына и назвала его Шела. Она родила его в Хезиве38:5 Или: «Иуда был в Хезиве, когда она его родила»..

6Иуда взял для своего первенца Ира жену по имени Фамарь. 7Но Ир, первенец Иуды, был грешен в глазах Вечного, и Вечный предал его смерти.

8Тогда Иуда сказал Онану:

– Ты должен лечь с женой брата и исполнить долг деверя: произвести потомство для брата38:8 По широко распространённому древнему обычаю левиратного брака (от лат. levir – деверь) брат умершего бездетным мужчины должен был жениться на его вдове, чтобы произвести наследника покойному (см. Втор. 25:5-10)..

9Но Онан знал, что потомство будет не его, и поэтому всякий раз, ложась с женой брата, он изливал семя на землю, чтобы не произвести потомства для брата. 10То, что он делал, было грешно в глазах Вечного, поэтому Он предал смерти и Онана.

11Тогда Иуда сказал своей невестке Фамари:

– Живи вдовой в доме у твоего отца, пока не вырастет мой сын Шела, – потому что он подумал: «Как бы и Шела не умер вслед за братьями».

И Фамарь отправилась жить в дом отца. 12Много времени спустя жена Иуды, дочь Шуа, умерла. Когда Иуда утешился по ней, он пошёл в Тимну, к людям, которые стригли его овец, и его друг адулламитянин Хира пошёл с ним.

13Фамари сказали:

– Твой свёкор держит путь в Тимну стричь своих овец.

14Она сняла вдовьи одежды, покрылась накидкой, чтобы её не узнали, и села у входа в Енаим, который на дороге в Тимну, потому что она видела, что хотя Шела уже вырос, её не отдали ему в жёны.

15Когда Иуда увидел Фамарь, он принял её за блудницу, потому что у неё было закрыто лицо. 16Он свернул с дороги к ней и сказал:

– Пойдём, я хочу лечь с тобой, – ведь он не знал, что это его невестка.

Она спросила:

– А что ты дашь мне за то, чтобы лечь со мной?

17Он ответил:

– Я пошлю тебе козлёнка из моего стада.

Она спросила:

– А ты дашь мне залог до тех пор, пока не пришлёшь козлёнка?

18Он сказал:

– Какой залог тебе дать?

Она ответила:

– Твою печать на шнурке и посох, который у тебя в руке.

Он дал ей всё это и переспал с ней, и она забеременела от него. 19Уйдя оттуда, она сняла своё покрывало и вновь надела вдовьи одежды.

20Тем временем Иуда послал через своего друга адулламитянина козлёнка, чтобы получить назад залог у той женщины, но друг не нашёл её. 21Он спросил у местных жителей:

– Где та храмовая блудница38:21 Храмовая блудница – имеется в виду одна из «жриц любви», которые были неотъемлемой частью весьма распространённых в те дни языческих культов плодородия., которая сидела у дороги в Енаим?

Они ответили:

– Здесь не было никакой храмовой блудницы.

22Он вернулся к Иуде и сказал:

– Я не нашёл её, и жители того места сказали: «Здесь нет никакой храмовой блудницы».

23Иуда сказал:

– Пусть оставит себе то, что взяла, иначе мы станем посмешищем. Я ведь посылал ей козлёнка, но ты её не нашёл.

24Месяца три спустя Иуде сказали:

– Твоя невестка Фамарь впала в блуд и от этого забеременела.

Иуда сказал:

– Выведите её, и пусть она будет сожжена!

25Но когда её уводили, она послала к свёкру с такими словами:

– Я беременна от человека, которому принадлежат эти вещи.

Ещё она сказала:

– Посмотри, не узнаёшь, чьи это печать, шнур и посох?

26Иуда узнал их и сказал:

– Она правее, чем я, потому что я не отдал её за моего сына Шелу.

И он больше не ложился с ней.

27Когда пришло ей время рожать, в утробе у неё оказались мальчики-близнецы. 28Когда она уже рожала, один из них высунул руку; тогда женщина, принимавшая роды, взяла алую нить, обвязала ему запястье и сказала:

– Этот вышел первым.

29Но он втянул руку обратно, и вышел его брат; тогда она сказала:

– Как это ты прорвался?

И его назвали Фарец («прорыв»). 30Затем вышел и тот, у которого на запястье была алая нить, и ему дали имя Зерах («алый свет зари»).