Gẹnẹsisi 39 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 39:1-23

Josẹfu àti aya Potiferi

139.1,2,21: Ap 7.9.Nígbà tí wọ́n mú Josẹfu dé Ejibiti, Potiferi, ará Ejibiti tí i ṣe ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao. Òun ni olórí àwọn ọmọ-ogun Farao. Ó ra Josẹfu lọ́wọ́ àwọn ará Iṣmaeli tí wọ́n mú un lọ síbẹ̀.

2Olúwa sì wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì bùkún un, ó sì ń gbé ní ilé ọ̀gá rẹ̀ ará Ejibiti. 3Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ rí i pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀, àti pé Olúwa jẹ́ kí ó máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́ rẹ̀ lé. 4Josẹfu sì rí ojúrere Potiferi, ó sì di aṣojú rẹ̀, Potiferi fi Josẹfu ṣe olórí ilé rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní. 5Láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu jẹ olórí ilé rẹ̀ àti ohun ìní rẹ̀ gbogbo, ni Ọlọ́run ti bẹ̀rẹ̀ sí ní bùkún àwọn ará Ejibiti nítorí Josẹfu. Ìbùkún Olúwa wà lórí gbogbo ohun tí Potiferi ní, nílé àti lóko. 6Ó sì fi Josẹfu ṣe àkóso gbogbo ohun tí ó ní. Kò sì ṣe ìyọnu lórí ohunkóhun mọ àyàfi nípa oúnjẹ tí ó ń jẹ láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu ṣe àkóso ilé e rẹ̀.

Josẹfu sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin ní ìdúró àti ìrísí rẹ̀, 7lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, aya rẹ̀ ṣe àkíyèsí Josẹfu, ó sì wí fún un pé, “Wá bá mi lòpọ̀!”

8Ṣùgbọ́n Josẹfu kọ̀, ó sì wí fún aya ọ̀gá rẹ̀ pé, “Kíyèsi, Olúwa mi kò fi ohunkóhun dù mi nínú ilé yìí, gbogbo ohun ìní rẹ̀ ni ó fi lé mi lọ́wọ́. 9Kò sí ẹni tí ó jù mi lọ nínú ilé yìí, ọ̀gá mi kò fi ohunkóhun dù mi àyàfi ìwọ, tí í ṣe aya rẹ̀. Báwo ni mo ṣe lè ṣe ohun búburú yìí, kí ń sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run?” 10Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ìgbà ni ó ń tẹnumọ́ èyí fún Josẹfu, Josẹfu kọ̀ láti bá a lòpọ̀. Ó tilẹ̀ kọ̀ láti máa dúró ni ibi tí ó bá wà.

11Ní ọjọ́ kan, Josẹfu lọ sínú ilé láti ṣe iṣẹ́, kò sì sí èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ ní tòsí. 12Ó sì di aṣọ Josẹfu mú, ó sì wí pé, “Wá bá mi lòpọ̀!” Ṣùgbọ́n Josẹfu fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí i lọ́wọ́, ó sì sá jáde.

13Nígbà tí ó rí i pé ó ti fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí òun lọ́wọ́, ó sì ti sá jáde, 14ó pe àwọn ìránṣẹ́ ilé náà, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wò ó, ọkọ ọ̀ mi mú Heberu kan wọlé tọ̀ wá wá láti fi wá ṣe ẹlẹ́yà. Ó wọlé tọ̀ mí wá, láti bá mi lòpọ̀, ṣùgbọ́n mo kígbe. 15Nígbà tí ó gbọ́ pé mo gbé ohùn mi sókè, tí mo sì kígbe, ó jọ̀wọ́ aṣọ rẹ̀ sọ́dọ̀ mi, ó sì sá, ó bọ́ sóde.”

16Ó sì fi aṣọ náà sọ́dọ̀ títí tí ọkọ rẹ̀ fi dé. 17Ó rò fún un pé, “Ẹrú ará Heberu tí o rà wá ilé láti fi wá ṣẹlẹ́yà wá láti bá mi lòpọ̀. 18Ṣùgbọ́n bí mo ti kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ó sì sá kúrò nínú ilé.”

19Nígbà tí Potiferi gbọ́ ọ̀rọ̀ aya rẹ̀ pé báyìí ni ẹrú rẹ̀ ṣe sí aya rẹ̀, ó bínú gidigidi. 20Ó sì ju Josẹfu sí ẹ̀wọ̀n, níbi tí a ń ju àwọn ẹlẹ́wọ̀n ọba sí.

Ṣùgbọ́n, nígbà tí Josẹfu wà nínú ẹ̀wọ̀n níbẹ̀, 2139.21: Ap 7.9.Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì ṣàánú fún un, ó sì mú kí ó rí ojúrere àwọn alábojútó ọgbà ẹ̀wọ̀n (wọ́dà). 22Nítorí náà, alábojútó ọgbà ẹlẹ́wọ̀n fi Josẹfu ṣe alákòóso ohun gbogbo tí ó wà nínú ẹ̀wọ̀n, àti ohun tí wọn ń ṣe níbẹ̀. 23Wọ́dà náà kò sì mikàn nípa gbogbo ohun tí ó fi sí abẹ́ àkóso Josẹfu, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì ń jẹ́ kí ó ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé.

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

Начало 39:1-23

Юсуф в доме Потифара

1Юсуфа привели в Египет, и египтянин Потифар, сановник фараона и начальник его стражи, купил Юсуфа у исмоильтян, которые его туда привели.

2Вечный был с Юсуфом, и он преуспевал, живя в доме у своего египетского господина. 3Его господин увидел, что Вечный с Юсуфом и что Он даёт ему успех во всём, что он делает. 4Юсуф нашёл расположение в его глазах и стал его личным слугой. Потифар поставил его над своим домом и доверил ему все свои владения. 5И с тех пор как он поставил его над своим домом и всеми владениями, Вечный благословил дом египтянина ради Юсуфа. Благословение Вечного было на всём, что было у Потифара, – и в доме, и в поле. 6Поэтому он доверил Юсуфу всё, что у него было; благодаря Юсуфу он мог ни о чём не заботиться, кроме того, чтобы поесть.

Юсуф же был хорошо сложён и красив, 7и через некоторое время жена его господина стала заглядываться на него и сказала:

– Ложись со мной!

8Но он отказался, сказав:

– При мне мой господин может ни о чём не заботиться в доме; всё, чем он владеет, он доверил мне. 9В этом доме я самый главный; мой господин не отказал мне ни в чём, кроме тебя, потому что ты – его жена. Как же я могу совершить такое великое зло и грех против Всевышнего?

10И хотя она уговаривала его каждый день, он отказывался лечь с ней и даже быть с ней.

11Однажды он вошёл в дом по своим делам, когда никого из домашних не было в доме. 12Она схватила его за одежду и сказала:

– Ложись со мной!

Но он вырвался и убежал, оставив верхнюю одежду у неё в руках. 13Увидев, что он убежал и оставил одежду у неё в руках, 14она позвала домашнюю прислугу и сказала им:

– Смотрите, этого еврея привели к нам в дом, а он оскорбляет нас! Он пришёл сюда и хотел лечь со мной, но я стала кричать, 15а он от моего крика оставил свою одежду и убежал.

16Она держала одежду Юсуфа у себя, пока не пришёл домой его хозяин. 17Она рассказала ему ту же историю:

– Этот раб-еврей, которого ты к нам привёл, пришёл ко мне и хотел надо мной надругаться, 18но я стала кричать, и он, оставив у меня свою одежду, убежал.

Заключение Юсуфа в темницу

19Когда его господин выслушал рассказ жены, которая сказала: «Вот как твой раб обошёлся со мной», он сильно разгневался. 20Он взял Юсуфа и посадил его в темницу, где были заключены царские узники; и так Юсуф оказался в темнице.

21Но и там Вечный был с ним; Он явил ему милость и даровал ему расположение в глазах главного надзирателя. 22Главный надзиратель поставил Юсуфа над всеми узниками, и он отвечал за все дела в темнице. 23Главный надзиратель мог не заботиться о том, что было вверено Юсуфу, потому что Вечный был с Юсуфом и давал ему успех во всех делах.