Gẹnẹsisi 29 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 29:1-35

Jakọbu dé Padani-Aramu

1Jakọbu sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò rẹ̀, ó sì dé ilẹ̀ àwọn ará ìlà-oòrùn. 2Ó sì rí kànga kan ní pápá, agbo àgùntàn mẹ́ta sì dúró láti mu omi ní ibi kànga náà, nítorí pé láti inú kànga náà ni wọ́n ti ń fi omi fún agbo àgùntàn. Òkúta tí a gbé dí ẹnu kànga náà sì tóbi gidigidi. 3Nígbà tí gbogbo agbo ẹran bá péjọpọ̀ sí ibẹ̀ tán ni àwọn darandaran yóò tó yí òkúta náà kúrò, tí wọn yóò sì fún àwọn ẹran náà ní omi, tí wọ́n bá sì ti ṣe bẹ́ẹ̀ tán, wọn yóò tún yí òkúta náà padà sí ẹnu kànga náà.

4Jakọbu béèrè lọ́wọ́ àwọn darandaran náà pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi níbo ni ẹ̀yin ti wá?”

Àwọn náà sì dáhùn pé, “Láti Harani ni.”

5Ó sì bi wọ́n pé, “Ǹjẹ́ ẹ mọ Labani ọmọ ọmọ Nahori?”

Wọ́n sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa mọ̀ ọ́n.”

6Jakọbu béèrè pé, “Ṣe àlàáfíà ni ó wà?”

Wọ́n sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni. Wò ó, Rakeli ọmọ rẹ̀ ni ó ń bọ̀ yìí pẹ̀lú agbo àgùntàn.”

7Ó sì wí pé, “Kíyèsi, ilẹ̀ ò tí ì ṣú, kò tì í tó àkókò fún àwọn ohun ọ̀sìn láti wọ̀. Ẹ fún àwọn ẹran wọ̀nyí ní omi, kí ẹ ba à le tètè dà wọ́n padà láti jẹun.”

8Wọ́n dá a lóhùn pé, “Àwa kì í yí òkúta kúrò ní ẹnu kànga láti pọn omi fún àwọn ẹran títí gbogbo àwọn darandaran àti àwọn ẹran yóò fi péjọ tán.”

9Bí wọ́n sì ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́ ni Rakeli dé pẹ̀lú agbo àgùntàn baba rẹ̀, nítorí darandaran ni òun náà. 10Nígbà tí Jakọbu rí Rakeli ọmọbìnrin Labani tí í ṣe ẹ̀gbọ́n ìyá rẹ̀, pẹ̀lú àgùntàn Labani, Jakọbu súnmọ́ kànga náà, ó sì yí òkúta kúrò lẹ́nu rẹ̀, ó sì fún àwọn ẹran arákùnrin ìyá rẹ̀ Labani ní omi. 11Jakọbu sì fẹnu ko Rakeli ní ẹnu. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún. 12Jakọbu sì wí fún Rakeli pé ìbátan baba rẹ̀ ni òun, àti pé, òun jẹ́ ọmọ Rebeka. Rakeli sì sáré lọ sọ fún baba rẹ̀.

13Ní kété tí Labani gbúròó Jakọbu ọmọ arábìnrin rẹ̀, ó jáde lọ pàdé Jakọbu, ó dì mọ́ ọn, ó fi ẹnu kò ó ní ẹnu, ó sì mú un lọ sí ilé. Nígbà náà ni Jakọbu ròyìn ohun gbogbo fún un. 14Labani sì wí pé, “Ẹran-ara àti ẹ̀jẹ̀ ara mi ni ìwọ jẹ́.”

Jakọbu fẹ́ àwọn ọmọ Labani Lea àti Rakeli

Lẹ́yìn tí Jakọbu sì wà pẹ̀lú rẹ̀ fún odidi oṣù kan, 15Labani wí fún Jakọbu pé, “Bí a tilẹ̀ jẹ́ ìbátan, kò yẹ kí o máa ṣiṣẹ́ fún mi lásán láìgba ohun kankan. Sọ ohun tì ìwọ fẹ́ gbà fún iṣẹ́ tí ìwọ ń ṣe fún mi!”

16Wàyí o, Labani ní ọmọbìnrin méjì, orúkọ èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Lea, orúkọ àbúrò sì ń jẹ́ Rakeli. 17Lea kò ní ẹwà púpọ̀, ṣùgbọ́n Rakeli ní ẹwà gidigidi. Ojú rẹ̀ sì fanimọ́ra. 18Jakọbu sì fẹ́ràn Rakeli, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò ṣiṣẹ́ sìn ọ fún ọdún méje, bí ìwọ yóò bá fún mi ní Rakeli ọmọ rẹ ní aya.”

19Labani sì dáhùn wí pé, “Ó kúkú sàn kí ń fi fún ọ, ju kí ń fi fún ẹlòmíràn lọ, nítorí náà wà ní ọ̀dọ̀ mi.” 20Jakọbu sì ṣiṣẹ́ sin Labani fún ọdún méje láti fẹ́ Rakeli. Àwọn ọdún wọ̀nyí sì dàbí ọjọ́ díẹ̀ lára rẹ̀, nítorí ó fẹ́ràn rẹ̀.

21Jakọbu sì wí fún Labani pé, “Mo ti parí àsìkò tí a jọ ṣe àdéhùn rẹ̀, nítorí náà fún mi ní aya mi, kí òun lè ṣe aya fún mi.”

22Labani sì pe gbogbo ènìyàn ibẹ̀ jọ, ó sì ṣe àsè ìyàwó fún wọ́n. 23Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di òru, Labani mú Lea tọ Jakọbu lọ. Jakọbu sì bá a lòpọ̀. 24Labani sì fi Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Lea gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́.

25Sì kíyèsi, nígbà ti ilẹ̀ mọ́, Jakọbu rí i pé Lea ni! Ó sì wí fún Labani pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Ṣe bí nítorí Rakeli ni mo ṣe ṣiṣẹ́ sìn ọ, èéṣe tí ìwọ tàn mi?”

26Labani sì dáhùn pé, “Kò bá àṣà wa mu láti fi àbúrò fún ọkọ ṣáájú ẹ̀gbọ́n rẹ̀. 27Mú sùúrù parí ọ̀sẹ̀ ìgbéyàwó yìí náà, nígbà náà ni èmi yóò fi àbúrò rẹ̀ fún ọ pẹ̀lú, bí ìwọ ó bá ṣiṣẹ́ sìn mi fún ọdún méje mìíràn.”

28Jakọbu sì gbà láti sin Labani fún ọdún méje mìíràn. Labani sì fi Rakeli ọmọ rẹ̀ fún un bí aya. 29Labani sì fi Biliha ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Rakeli bí ìránṣẹ́. 30Jakọbu sì bá Rakeli náà lòpọ̀. Ó sì fẹ́ràn Rakeli ju Lea lọ, ó sì ṣiṣẹ́ sin Labani fún ọdún méje mìíràn.

Àwọn ọmọ Jakọbu

31Nígbà tí Ọlọ́run sì ri pé, Jakọbu kò fẹ́ràn Lea, ó ṣí i ni inú ṣùgbọ́n Rakeli yàgàn. 32Lea sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Reubeni, nítorí ó wí pé, “Nítorí Ọlọ́run ti mọ ìpọ́njú mi, dájúdájú, ọkọ mi yóò fẹ́ràn mi báyìí.”

33Ó sì tún lóyún, ó bí ọmọkùnrin kan. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Simeoni, wí pé “Nítorí tí Olúwa ti gbọ́ pé a kò fẹ́ràn mi, ó sì fi èyí fún mi pẹ̀lú.”

34Ó sì tún lóyún, ó bí ọmọkùnrin kan, ó sì wí pé, “Nígbà yìí ni ọkọ mi yóò fi ara mọ́ mi, nítorí tí mo ti bí ọmọkùnrin mẹ́ta fún un,” nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Lefi.

35Ó sì tún lóyún, ó sì tún jẹ́ pé ọmọkùnrin ni ó bí, ó sì wí pé, “Nígbà yìí ni èmi yóò yin Olúwa.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Juda. Ó sì dáwọ́ ọmọ bíbí dúró.

Persian Contemporary Bible

پيدايش 29:1-35

يعقوب به فَدّان ارام می‌رسد

1يعقوب به سفر خود ادامه داد تا به ديار مشرق رسيد. 2در صحرا چاهی ديد كه سه گله گوسفند كنار آن خوابيده‌اند، زيرا از آن چاه، گله‌ها را آب می‌دادند. اما سنگی بزرگ بر دهانه چاه قرار داشت. 3(رسم بر اين بود كه وقتی همهٔ گله‌ها جمع می‌شدند، آن سنگ را از سر چاه برمی‌داشتند و پس از سيراب كردن گله‌ها، دوباره سنگ را بر سر چاه می‌غلتانيدند.) 4يعقوب نزد چوپانان رفت و از آنها پرسيد كه از كجا هستند. آنها گفتند كه از حران هستند. 5به ايشان گفت: «آيا لابان پسر ناحور را می‌شناسيد؟»

گفتند: «بلی، او را می‌شناسيم.»

6يعقوب پرسيد: «حالِ او خوب است؟»

گفتند: «بلی، حالش خوب است. آن هم دختر اوست كه با گله‌اش می‌آيد.»

7يعقوب گفت: «هنوز تا غروب خيلی مانده است. چرا به گوسفندها آب نمی‌دهيد تا دوباره بروند و بچرند؟»

8جواب دادند: «تا همهٔ گله‌ها سر چاه نيايند ما نمی‌توانيم سنگ را برداريم و گله‌هايمان را سيراب كنيم.»

9در حالی كه اين گفتگو ادامه داشت، راحيل با گلهٔ پدرش سر رسيد، زيرا او نيز چوپان بود. 10وقتی يعقوب دختر دايی خود، راحيل را ديد كه با گله لابان می‌آيد، سنگ را از سر چاه برداشت و گلهٔ او را سيراب نمود. 11سپس يعقوب، راحيل را بوسيده، شروع به گريستن نمود! 12يعقوب خود را معرفی كرد و گفت كه خويشاوند پدرش و پسر ربكاست. راحيل به محض شنيدن سخنان او، دوان‌دوان به منزل شتافت و پدرش را باخبر كرد. 13چون لابان خبر آمدن خواهرزادهٔ خود يعقوب را شنيد به استقبالش شتافت و او را در آغوش گرفته، بوسيد و به خانهٔ خود آورد. آنگاه يعقوب داستان خود را برای او شرح داد. 14لابان به او گفت: «تو از گوشت و استخوان من هستی!»

يعقوب، ليه و راحيل را به زنی می‌گيرد

يک ماه بعد از آمدن يعقوب، 15لابان به او گفت: «تو نبايد به دلیل اينكه خويشاوند من هستی برای من مجانی كار كنی. بگو چقدر مزد به تو بدهم؟» 16لابان دو دختر داشت كه نام دختر بزرگ لَيه و نام دختر كوچک راحيل بود. 17ليه چشمانی ضعيف داشت، اما راحيل زيبا و خوش‌اندام بود. 18يعقوب عاشق راحيل شده بود. پس به لابان گفت: «اگر راحيل، دختر كوچكت را به همسری به من بدهی، هفت سال برای تو كار می‌كنم.»

19لابان جواب داد: «قبول می‌كنم. ترجيح می‌دهم دخترم را به تو كه از بستگانم هستی بدهم تا به يک بيگانه.»

20يعقوب برای ازدواج با راحيل هفت سال برای لابان كار كرد، ولی به قدری راحيل را دوست می‌داشت كه اين سالها در نظرش چند روز آمد.

21آنگاه يعقوب به لابان گفت: «مدت قرارداد ما تمام شده و موقع آن رسيده است كه راحيل را به زنی بگيرم.»

22لابان همهٔ مردم آنجا را دعوت كرده، ضيافتی بر پا نمود. 23وقتی هوا تاريک شد، لابان دختر خود ليه را به حجله فرستاد و يعقوب با وی همبستر شد. 24(لابان كنيزی به نام زلفه به ليه داد تا او را خدمت كند.) 25اما صبح روز بعد، يعقوب به جای راحيل، ليه را در حجلهٔ خود يافت. پس رفته، به لابان گفت: «اين چه كاری بود كه با من كردی؟ من هفت سال برای تو كار كردم تا راحيل را به من بدهی. چرا مرا فريب دادی؟»

26لابان جواب داد: «رسم ما بر اين نيست كه دختر كوچكتر را زودتر از دختر بزرگتر شوهر بدهيم. 27صبر كن تا هفتهٔ عروسی ليه بگذرد، بعد راحيل را نيز به زنی بگير، مشروط بر اينكه قول بدهی هفت سال ديگر برايم كار كنی.»

28يعقوب قبول كرد و لابان پس از پايان هفتهٔ عروسی ليه، دختر كوچک خود راحيل را هم به يعقوب داد. 29(لابان كنيزی به نام بلهه به راحيل داد تا او را خدمت كند.) 30يعقوب با راحيل نيز همبستر شد و او را بيشتر از ليه دوست می‌داشت و به خاطر او هفت سال ديگر برای لابان كار كرد.

فرزندان يعقوب

31وقتی خداوند ديد كه يعقوب ليه را دوست ندارد، ليه را مورد لطف خود قرار داد و او بچه‌دار شد، ولی راحيل نازا ماند. 32آنگاه ليه حامله شد و پسری زاييد. او گفت: «خداوند مصيبت مرا ديده است و بعد از اين شوهرم مرا دوست خواهد داشت.» پس او را رئوبين (يعنی «خداوند مصيبت مرا ديده است») نام نهاد. 33او بار ديگر حامله شده، پسری زاييد و گفت: «خداوند شنيد كه من مورد بی‌مهری قرار گرفته‌ام و پسر ديگری به من داد.» پس او را شمعون (يعنی «خداوند شنيد») ناميد. 34ليه باز هم حامله شد و پسری زاييد و گفت: «اينک مطمئناً شوهرم به من دلبسته خواهد شد، زيرا اين سومين پسری است كه برايش زاييده‌ام.» پس او را لاوی (يعنی «دلبستگی») ناميد. 35بار ديگر او حامله شد و پسری زاييد و گفت: «اين بار خداوند را ستايش خواهم نمود.» و او را يهودا (يعنی «ستايش») ناميد. آنگاه ليه از زاييدن باز ايستاد.