Gẹnẹsisi 22 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 22:1-24

Ọlọ́run dán Abrahamu wò

122.1-18: Hb 11.17-19.Nígbà tí ó ṣe, Ọlọ́run dán Abrahamu wò, ó pè é, ó sì wí pé, “Abrahamu.”

Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”

222.2: 2Ki 3.1.Ọlọ́run sì wí pé, “Mú ọmọ rẹ, àní Isaaki ọmọ rẹ kan ṣoṣo nì, tí ìwọ fẹ́ràn, lọ sí ilẹ̀ Moriah, kí o sì fi rú ẹbọ sísun níbẹ̀ lórí ọ̀kan nínú àwọn òkè tí èmi yóò sọ fún ọ.”

3Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì mú méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì ṣẹ́ igi fún ẹbọ sísun, ó sì gbéra lọ sí ibi tí Ọlọ́run ti sọ fún un. 4Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹta, Abrahamu gbé ojú sókè, ó sì rí ibi tí ó ń lọ ní òkèrè, 5Abrahamu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin, ẹ dúró níhìn-ín pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, èmi àti ọmọ yìí yóò lọ sí ohunkóhun láti sin Ọlọ́run, a ó sì tún padà wá bá a yín.”

6Abrahamu sì gbé igi ẹbọ sísun náà ru Isaaki, òun fúnrarẹ̀ sì mú iná àti ọ̀bẹ. Bí àwọn méjèèjì ti ń lọ, 7Isaaki sì sọ fún Abrahamu baba rẹ̀ wí pé, “Baba mi.”

Abrahamu sì dalóhùn pé, “Èmi nìyí ọmọ mi.”

Isaaki sì tún wí pé, “Wò ó iná àti igi nìyí, ṣùgbọ́n níbo ni ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà wà?”

8Abrahamu sì dáhùn pé, “Ọmọ mi, Ọlọ́run fúnrarẹ̀ ni yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì jùmọ̀ ń lọ.

922.9,10,12: Jk 2.21.Nígbà tí wọn sì dé ibi tí Ọlọ́run sọ fún Abrahamu, ó mọ pẹpẹ kan, ó sì to igi lé e lórí, ó sì di Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì da dùbúlẹ̀ lórí pẹpẹ náà. 10Abrahamu sì nawọ́ mú ọ̀bẹ, láti dúńbú ọmọ rẹ̀. 11Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa ké sí i láti ọ̀run wá wí pé “Abrahamu! Abrahamu!”

Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”

12Angẹli Olúwa sì wí pé, “Má ṣe fọwọ́ kan ọmọ náà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣe é ni ohun kan. Nísinsin yìí ni mo mọ̀ pé o bẹ̀rù Ọlọ́run, nítorí pé ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí.”

13Abrahamu sì gbójú sókè, ó sì rí àgbò kan tí ó fi ìwo há pàǹtírí, ó sì lọ mú un, ó sì fi rú ẹbọ sísun dípò ọmọ rẹ̀. 14Abrahamu sì pe orúkọ ibẹ̀ ni, Olúwa yóò pèsè (Jehofah Jire). Bẹ́ẹ̀ ni a sì ń wí títí di òní olónìí pé, “Ní orí òkè Olúwa, ni a ó ti pèsè.”

15Angẹli Olúwa sì tún pe Abrahamu láti ọ̀run wá lẹ́ẹ̀kejì. 1622.16,17: Lk 1.73; Hb 6.13,14; 11.12.Ó sì wí pé, Olúwa wí pé, “Mo fi ara mi búra, níwọ̀n bí ìwọ ti ṣe èyí, tí ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí, 1722.17: Hb 11.12.Nítòótọ́, ní bíbùkún èmi ó bùkún fún ọ, àti ní bíbísí èmi ó sì mú ọ bí sí i bí i ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti bí iyanrìn etí Òkun. Irú-ọmọ rẹ yóò sì gba ẹnu ibodè àwọn ọ̀tá wọn, 1822.18: Ap 3.25; Ga 3.16.àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó ti bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nítorí tí ìwọ gbọ́rọ̀ sí mi lẹ́nu.”

19Nígbà náà ni Abrahamu padà tọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn sì padà lọ sí Beerṣeba. Abrahamu sì jókòó ní Beerṣeba.

Àwọn ọmọ Nahori

20Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni a wí fún Abrahamu pé, “Milka aya Nahori bí àwọn ọmọkùnrin fún un.

21Usi, àkọ́bí rẹ̀, Busi arákùnrin rẹ̀,

Kemueli (Baba Aramu).

22Kesedi, Haso, Pildasi, Jidlafi, àti Betueli.”

23Betueli sì ni baba Rebeka.

Milka sì bí àwọn ọmọ mẹ́jọ wọ̀nyí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.

24Àlè rẹ̀ tí ń jẹ́ Reuma náà bí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí fun un:

Teba, Gahamu, Tahasi àti Maaka.

Persian Contemporary Bible

پيدايش 22:1-24

امتحان ابراهيم

1مدتی گذشت و خدا خواست ابراهيم را امتحان كند. پس او را ندا داد: «ای ابراهيم!» ابراهيم جواب داد: «بلی، خداوندا!»

2خدا فرمود: «يگانه پسرت يعنی اسحاق را كه بسيار دوستش می‌داری برداشته، به سرزمين موريا برو و در آنجا وی را بر يكی از كوههايی كه به تو نشان خواهم داد به عنوان هديهٔ سوختنی، قربانی كن!»

3ابراهيم صبح زود برخاست و مقداری هيزم جهت آتش قربانی تهيه نمود، الاغ خود را پالان كرد و پسرش اسحاق و دو نفر از نوكرانش را برداشته، به سوی مكانی كه خدا به او فرموده بود، روانه شد. 4پس از سه روز راه، ابراهيم آن مكان را از دور ديد. 5پس به نوكران خود گفت: «شما در اينجا پيش الاغ بمانيد تا من و پسرم به آن مكان رفته، عبادت كنيم و نزد شما برگرديم.»

6ابراهيم هيزمی را كه برای قربانی سوختنی آورده بود، بر دوش اسحاق گذاشت و خودش كارد و وسيله‌ای را كه با آن آتش روشن می‌كردند برداشت و با هم روانه شدند.

7اسحاق پرسيد: «پدر، ما هيزم و آتش با خود داريم، اما برهٔ قربانی كجاست؟»

8ابراهيم در جواب گفت: «پسرم، خدا برهٔ قربانی را مهيا خواهد ساخت.» و هر دو به راه خود ادامه دادند.

9وقتی به مكانی كه خدا به ابراهيم فرموده بود رسيدند، ابراهيم قربانگاهی بنا كرده، هيزم را بر آن نهاد و اسحاق را بسته او را بر هيزم گذاشت. 10سپس او كارد را بالا برد تا اسحاق را قربانی كند. 11در همان لحظه، فرشتهٔ خداوند از آسمان ابراهيم را صدا زده گفت: «ابراهيم! ابراهيم!»

او جواب داد: «بلی خداوندا!»

12فرشته گفت: «كارد را بر زمين بگذار و به پسرت آسيبی نرسان. الان دانستم كه مطيع خدا هستی، زيرا يگانه پسرت را از او دريغ نداشتی.»

13آنگاه ابراهيم قوچی را ديد كه شاخهايش در بوته‌ای گير كرده است. پس رفته قوچ را گرفت و آن را در عوض پسر خود به عنوان هديهٔ سوختنی قربانی كرد. 14ابراهيم آن مكان را «يهوه يری» (يعنی «خداوند تدارک می‌بيند») ناميد كه تا به امروز به همين نام معروف است.

15بار ديگر فرشتهٔ خداوند از آسمان ابراهيم را صدا زده، به او گفت: 16«خداوند می‌گويد به ذات خود قسم خورده‌ام كه چون مرا اطاعت كردی و حتی يگانه پسرت را از من دريغ نداشتی، 17تو را چنان بركت دهم كه نسل تو مانند ستارگان آسمان و شنهای دريا بی‌شمار گردند. آنها بر دشمنان خود پيروز شده، 18موجب بركت همهٔ قومهای جهان خواهند گشت، زيرا تو مرا اطاعت كرده‌ای.» 19پس ايشان نزد نوكران باز آمده، به سوی منزل خود در بئرشِبَع حركت كردند.

نسل ناحور

20‏-23بعد از اين واقعه، به ابراهيم خبر رسيد كه مِلْكَه همسر ناحور برادر ابراهيم، هشت پسر زاييده است. اسامی آنها از اين قرار بود: پسر ارشدش عوص، و بعد بوز، قموئيل (پدر ارام)، كاسد، حزو، فلداش، يدلاف و بتوئيل (پدر ربكا). 24ناحور همچنين از كنيز خود به اسم رئومه، چهار فرزند ديگر داشت به نامهای طابح، جاحم، تاحش و معكه.