Gẹnẹsisi 12 – YCB & CCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 12:1-20

Ìpè Abramu

112.1: Ap 7.3; Hb 11.8.Olúwa sì wí fún Abramu, “Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.

212.2: Gẹ 15.5; 17.4,5; 18.18; 22.17; 28.14; 32.12; 35.11; 46.3.“Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá

Èmi yóò sì bùkún fún ọ.

Èmi yóò sọ orúkọ rẹ di ńlá,

ìbùkún ni ìwọ yóò sì jásí.

312.3: Gẹ 18.18; 22.17,18; 26.4; 28.14; Ga 3.8.Èmi yóò bùkún fún àwọn tí ó súre fún ọ,

ẹni tí ó fi ọ́ ré ni Èmi yóò fi ré;

nínú rẹ ni a ó bùkún

gbogbo ìdílé ayé.”

4Bẹ́ẹ̀ ni Abramu lọ bí Olúwa ti sọ fún un. Lọti náà sì bá a lọ. Abramu jẹ́ ẹni àrùndínlọ́gọ́rin (75) ọdún nígbà tí ó jáde kúrò ní Harani. 5Abramu sì mú Sarai aya rẹ̀, àti Lọti ọmọ arákùnrin rẹ̀: gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti kójọ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n ní ní Harani. Wọ́n sì jáde lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Wọ́n sì gúnlẹ̀ síbẹ̀.

6Abramu sì rìn la ilẹ̀ náà já títí dé ibi igi ńlá kan tí à ń pè ni More ní Ṣekemu. Àwọn ará Kenaani sì wà ní ilẹ̀ náà. 712.7: Gẹ 13.15; 15.18; 17.8; 24.7; 26.3; 28.4,13; 35.12; 48.4; Ap 7.5; Ga 3.16.Olúwa sì farahan Abramu, ó sì wí fún un pé, “Irú-ọmọ rẹ ni Èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún.” Abramu tẹ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa tí ó fi ara hàn án.

8Ó sì kúrò níbẹ̀ lọ sí agbègbè àwọn òkè kan ní ìhà ìlà-oòrùn Beteli, ó sì pàgọ́ rẹ̀ síbẹ̀. Beteli wà ní ìwọ̀-oòrùn, Ai wà ní ìlà-oòrùn. Ó tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ó sì ké pe orúkọ Olúwa.

9Nígbà náà ni Abramu tẹ̀síwájú sí ìhà gúúsù.

Abramu ní Ejibiti

1012.10-20: Gẹ 20.1-18; 26.7-11.Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, Abramu sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ṣe àtìpó níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, nítorí ìyàn náà mú gidigidi. 11Bí ó ti ku díẹ̀ kí ó wọ Ejibiti, ó wí fún Sarai, aya rẹ̀ pé, “Mo mọ̀ pé arẹwà obìnrin ni ìwọ, 12nígbà tí àwọn ará Ejibiti bá rí ọ, wọn yóò wí pé, ‘Aya rẹ̀ nìyí.’ Wọn yóò si pa mí, ṣùgbọ́n wọn yóò dá ọ sí. 13Nítorí náà, sọ pé, arábìnrin mi ni ìwọ, wọn yóò sì ṣe mí dáradára, a ó sì dá ẹ̀mí mi sí nítorí tìrẹ.”

14Nígbà tí Abramu dé Ejibiti, àwọn ará Ejibiti ri i pé aya rẹ̀ rẹwà gidigidi. 15Nígbà tí àwọn ìjòyè Farao sì rí i, wọ́n ròyìn rẹ̀ níwájú Farao, wọ́n sì mú un lọ sí ààfin, 16Ó sì kẹ́ Abramu dáradára nítorí Sarai, Abramu sì ní àgùntàn àti màlúù, akọ àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin, pẹ̀lú ìbákasẹ.

17Olúwa sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn búburú sí Farao àti ilé rẹ̀, nítorí Sarai aya Abramu. 18Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Abramu, ó sì wí fun pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé aya rẹ ní í ṣe? 19Èéṣe tí o fi wí pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ tí èmi sì fi fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya? Nítorí náà nísinsin yìí, aya rẹ náà nìyí, mú un kí o sì máa lọ.” 20Nígbà náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nípa Abramu, wọ́n sì lé e jáde ti òun ti aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

创世记 12:1-20

上帝呼召亚伯兰

1耶和华对亚伯兰说:“你要离开家乡、亲族和父亲的家,到我要指示你的地方去。 2我必使你成为大国,我必赐福给你,使你声名远播。你必成为别人的祝福。 3我必赐福给那些祝福你的人,咒诅那些咒诅你的人。世上万族必因你而蒙福。”

4亚伯兰就照耶和华的吩咐离开哈兰,侄儿罗得与他同行。那时亚伯兰七十五岁。 5亚伯兰带着妻子撒莱、侄儿罗得以及在哈兰积攒的财物和所得的奴仆启程来到迦南。到了迦南以后, 6亚伯兰继续前行,来到示剑摩利橡树12:6 橡树”希伯来文是“大树”,也可能指灵树或圣树,下同13:1814:1318:135:435:8那里。当时迦南人住在那地方。 7耶和华向亚伯兰显现,对他说:“我要把这片土地赐给你的后裔。”亚伯兰就在那里为向他显现的耶和华筑了一座坛。 8然后,他们又启程前往伯特利东面的山区,在那里搭起帐篷。他们的西面是伯特利,东面是亚伯兰又在那里筑了一座坛,求告耶和华。 9之后,亚伯兰继续前往南地。

亚伯兰逃荒到埃及

10当时,那地方闹饥荒,灾情非常严重,亚伯兰便下到埃及暂住。 11快要到埃及的时候,他对妻子撒莱说:“我知道你是个美貌的女子, 12埃及人看见你,一定会因为你是我的妻子而杀了我,让你活着。 13所以,请你说你是我的妹妹,这样他们会因为你而善待我,留我一命。” 14亚伯兰一行到了埃及撒莱的美貌引起了埃及人的注意。 15法老的官员见了撒莱,就在法老面前称赞她的美貌,她便被带进法老的王宫。 16因为撒莱的缘故,法老厚待亚伯兰,赏给他许多牛、羊、驴、骆驼和仆婢。

17耶和华因亚伯兰妻子撒莱的缘故使法老和他全家患重病。 18法老便召见亚伯兰,说:“你做的是什么事?为什么不告诉我她是你妻子? 19为什么说她是你妹妹,以致我娶她为妻呢?现在你妻子在这里,带她走吧!” 20法老就吩咐人把亚伯兰、他妻子以及他所有的一切都送走了。