Filipi 2 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Filipi 2:1-30

Kọ́ ìwà ìrẹ̀lẹ̀ Kristi

12.1: 2Kọ 13.14.Bí ìwọ bá ní ìmúlọ́kànle nítorí pé ìwọ wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú Kristi, bi ìtùnú kan bá wà nínú ìfẹ́ rẹ̀, bí ìdàpọ̀ Ẹ̀mí kan bá wà, bí ìyọ́nú àti ìṣeun bá wà, 2síbẹ̀ ẹ mú ayọ̀ mi kún nínú ìṣọ̀kan yín, nípa ìfẹ́ kan náà, wíwà ní ẹ̀mí kan náà àti ète kan náà. 32.3-4: Ro 12.10; 15.1-2.Ẹ má ṣe ohunkóhun nínú ìlépa ara tàbí ògo asán, ṣùgbọ́n ní ìrẹ̀lẹ̀ ọkàn kí olúkúlùkù ro àwọn ẹlòmíràn sí ẹni ti ó sàn ju òun lọ. 4Kí olúkúlùkù yín má ṣe ro ohun ti ara rẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n ti ẹlòmíràn pẹ̀lú.

52.5-8: Mt 11.29; 20.28; Jh 1.1; 2Kọ 8.9; Hb 5.8.Nínú ìbáṣepọ̀ yin pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn, ẹ ni irú ìlépa ọkàn náà bí ti Kristi Jesu.

6Ẹni tí, bí o tilẹ̀ jẹ́ ìrísí Ọlọ́run,

kò kà á sí ohun tí ìbá fi ìwọra gbámú láti bá Ọlọ́run dọ́gba.

7Ṣùgbọ́n ó bọ́ ògo rẹ̀ sílẹ̀,

ó sì mú àwọ̀ ìránṣẹ́,

a sì ṣe é ni àwòrán ènìyàn.

8Ó sì wà ní àwòrán ènìyàn,

ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀,

o sì tẹríba títí de ojú ikú,

àní ikú lórí àgbélébùú.

92.9-11: Ro 10.9; 14.9; Ef 1.20-21.Nítorí náà, Ọlọ́run

ti gbé e ga sí ipele tí ó ga jùlọ,

ó sì ti fi orúkọ kan ti ó borí gbogbo orúkọ fún un

10Pé ni orúkọ Jesu ni kí gbogbo eékún máa wólẹ̀,

ní ọ̀run, àti ní orí ilẹ̀ ayé àti ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,

11Àti pé kí gbogbo ahọ́n jẹ́wọ́ pé, Jesu Kristi ni Olúwa,

fún ògo Ọlọ́run Baba.

Títàn gẹ́gẹ́ bí àwọn ìràwọ̀

12Nítorí náà ẹ̀yin ará mi, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ń gbọ́rọ̀ nígbà gbogbo, kì í ṣe nígbà ti mo wà lọ́dọ̀ yín nìkan, ṣùgbọ́n pàápàá nísinsin yìí tí èmi kò sí ni àárín yín, ẹ máa ṣiṣẹ́ ìgbàlà yín yọrí pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìwárìrì, 132.13: 1Kọ 15.10.Nítorí pé Ọlọ́run ni ó n ṣiṣẹ́ nínú yín, láti fẹ́ àti láti ṣiṣẹ́ fún ète rere rẹ̀.

14Ẹ máa ṣe ohun gbogbo láìsí ìkùnsínú àti ìjiyàn. 152.15: Mt 5.45,48.Kí ẹ̀yin lè jẹ́ aláìlẹ́gàn àti oníwà mímọ́, ọmọ Ọlọ́run, aláìlábàwọ́n, láàrín oníwà wíwọ́ àti alárékérekè orílẹ̀-èdè láàrín àwọn ẹni tí a ń rí yín bí ìmọ́lẹ̀ ní ayé. 16Bí ẹ sì ṣe di ọ̀rọ̀ ìyè mú gírígírí, kí èmi lè ṣògo ni ọjọ́ Kristi pé èmi kò sáré lásán, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ṣe làálàá lásán. 17Ṣùgbọ́n, bí a tilẹ̀ ń dà mí bí ọtí-ìrúbọ sórí ẹbọ iṣẹ́ ìsìn ìgbàgbọ́ yín, inú mi dùn, mo sì ń bá gbogbo yín yọ̀ pẹ̀lú. 18Bákan náà ni kí ẹ̀yin máa yọ̀, kí ẹ sì máa bá mi yọ̀ pẹ̀lú.

Timotiu àti Epafiroditu

19Mo ni ìrètí nínú Jesu Olúwa, láti rán Timotiu sí yín ni àìpẹ́ yìí, kí èmi pẹ̀lú lè ni ìfọ̀kànbalẹ̀ nígbà tí mo bá gbúròó yín. 20Nítorí èmi kò ni ẹlòmíràn tí ó dàbí rẹ̀, tí yóò máa fi tinútinú ṣe àníyàn yín. 21Nítorí gbogbo wọn ni ó tọ́jú nǹkan ti ara wọn, kì í ṣe àwọn nǹkan ti Jesu Kristi. 22Ṣùgbọ́n ẹ̀yin mọ̀ pé Timotiu pegedé, gẹ́gẹ́ bí ọmọ lọ́dọ̀ baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó sì ti ń bá mi ṣiṣẹ́ pọ̀, nínú iṣẹ́ ìhìnrere. 23Nítorí náà, mo ní ìrètí láti rán sí yín ní àìpẹ́ tí mo bá wòye bí yóò ti rí fún mi. 24Ṣùgbọ́n mo ní gbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa, pé èmi tìkára mi pẹ̀lú yóò wá ní àìpẹ́.

25Mo kà á sí pé n kò lè ṣàìrán Epafiroditu arákùnrin mi sí yín, àti olùbáṣiṣẹ́ pọ̀ mi, àti ọmọ-ogun ẹlẹgbẹ́ mi, ìránṣẹ́ yín pẹ̀lú, tí ẹ rán láti ṣè ránṣẹ́ fún mi nínú àìní mi. 26Nítorí tí ọkàn rẹ̀ fà sí gbogbo yín, ó sì kún fún ìbànújẹ́, nítorí tí ẹ̀yin gbọ́ pé ó ṣe àìsàn. 27Nítòótọ́ ni ó ti ṣe àìsàn títí dé ojú ikú, ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti ṣàánú fún un; kì í sì í ṣe fún òun nìkan, ṣùgbọ́n fún èmi pẹ̀lú kí èmi má ṣe ni ìbànújẹ́ lórí ìbànújẹ́. 28Nítorí náà ni mo ṣe ní ìtara láti rán an, pé nígbà tí ẹ̀yin bá sì tún rí i, kí ẹ̀yin lè yọ̀ àti kí ìkáyà sókè mi lè dínkù. 29Nítorí náà, ẹ fi ayọ̀ púpọ̀ gbà á nínú Olúwa; kí ẹ sì máa bu ọlá fún irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀. 30Nítorí iṣẹ́ Kristi ni ó ṣe súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú, tí ó sì fi ẹ̀mí ara rẹ̀ wéwu, láti mu àìtó iṣẹ́ ìsìn yín sí mi kún.

New Serbian Translation

Филипљанима 2:1-30

1Ако сте, дакле, примили икакву утеху по Христу, икакво љубављу прожето охрабрење, ако имате икакво заједништво са Духом, ако сте примили икакво милосрђе и саосећање, 2испуните ме, онда, радошћу: свој ум усмерите на исто, имајте исту љубав, будите једнодушни, на једно мислећи. 3Ништа не чините ради себичног истицања, нити из безвредног частољубља, него у понизности сматрајте једни друге већим од себе. 4Не гледајте само на властиту корист, него свако да гледа и на корист других. 5У себи носите исту мисао коју је Христос Исус носио:

6Он, по обличју Бог,

није сматрао да бити једнак Богу,

јесте плен који треба отимати,

7него је лишио себе части,

узевши обличје слуге,

поставши сличан људима.

Као човек се појави,

8те понизи себе самог,

и поста послушан до смрти,

до смрти на крсту.

9Бог га зато преузвиси,

и дарова му име,

име које је над сваким именом,

10да се пред именом Исусовим,

свако колено приклони,

оних на небу, на земљи, и под земљом,

11и да сваки језик призна да је Исус Христос Господ,

на славу Бога Оца.

Хришћани – светлост света

12Сходно томе, вољени моји, ви који сте увек били послушни, не само у моме присуству, него још више сад, у мом одсуству, са страхом и трепетом спроводите у дело своје спасење. 13Бог је, наиме, тај који чини у вама да желите и чините оно што је њему угодно. 14Све чините без гунђања и расправљања, 15да будете без мане и чисти, неокаљана деца Божија усред исквареног и изопаченог нараштаја, међу којима светлите као звезде у свемиру, 16чврсто држећи реч живота, да бих се поносио у дан Христов, да нисам узалуд трчао, нити се узалуд трудио. 17Но, ако се и приносим као жртва изливница за вас у служби ваше вере, радостан сам и радујем се са свима вама. 18Тако и ви будите радосни и радујте се са мном.

Тимотеј и Епафродит

19Надам се у Господу Исусу да ћу вам ускоро послати Тимотеја, да се и ја охрабрим када сазнам како сте ви. 20Немам, наиме, никог толико блиског себи ко би се тако ваљано бринуо о вашим потребама. 21Јер сви траже своје, а не оно што припада Христу Исусу. 22Али ви знате за његову прокушаност, да је, као дете са оцем, заједно са мном служио у навештавању Радосне вести. 23Надам се, дакле, да ћу вам њега послати чим видим како стоје ствари са мном. 24Уверен сам у Господу да ћу ускоро и ја лично доћи.

25Ипак, сматрам за потребно да вам пошаљем Епафродита, мог брата, сарадника и саборца, који је од вас послан да ми се нађе у потребама. 26Јер, он је чезнуо за свима вама и био узнемирен што сте чули да је болестан. 27И заиста је тако оболео да је скоро умро, али Бог му се смиловао, и не само њему, него и мени, да ми не дође жалост на жалост. 28Утолико више желим да га пошаљем, да бисте се обрадовали када га видите, и да бих ја мање бринуо. 29Примите га, стога, са свом радошћу и цените такве. 30Јер он је ради Христовог дела скоро умро, изложивши свој живот погибељи да надопуни оно у чему ми ви нисте могли послужити.