Esekiẹli 3 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Esekiẹli 3:1-27

1Síwájú sí i, ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ohun tí ó wà níwájú rẹ, jẹ ìwé kíká yìí; kí o sì lọ fi bá ilé Israẹli sọ̀rọ̀.” 2Mo sì ya ẹnu mi, ó sì mú mi jẹ ìwé kíká náà.

3Ó tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ìwé kíká tí mo fún ọ yìí, fi bọ́ inú àti ikùn rẹ.” Nígbà náà ni mo jẹ ẹ́, dídùn rẹ̀ dàbí oyin ní ẹnu mi.

4Ó sì tún sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, lọ ni ìsinsin yìí bá mi sọ ọ̀rọ̀ mi fún ilé Israẹli. 5A kò rán ọ sí àwọn tó ń sọ èdè àjèjì tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè Israẹli ni mo rán ọ sí 6kì í ṣe sí ọ̀pọ̀ ènìyàn tó ń sọ àjèjì èdè tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, àwọn tí ọ̀rọ̀ wọn le fún ọ láti gbọ́ yé. Dájúdájú bí mo bá rán ọ sí wọn, wọn ìbá sì fetísílẹ̀ sí ọ. 7Ṣùgbọ́n ilé Israẹli kò fẹ́ gbọ́ tìrẹ nítorí pé wọn kò fẹ́ láti gbọ́ tèmi, torí pé aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle ni gbogbo ilé Israẹli. 8Ṣùgbọ́n bí i tiwọn lèmi náà yóò ṣe jẹ́ kí ojú àti ọkàn rẹ le. 9Èmi yóò ṣe iwájú orí rẹ bí òkúta tó le jùlọ, ànító le ju òkúta-ìbọn lọ. Má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí jẹ́ kí wọn ó dáyà já ọ. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdílé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.”

10Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, kí o sì gba gbogbo ọ̀rọ̀ yìí sí ọkàn rẹ. 11Lọ nísinsin yìí sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ tó wà ní ìgbèkùn. Sọ fún wọn pé báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí yálà wọ́n gbọ́ tàbí wọn kò gbọ́.”

12Nígbà náà ni Ẹ̀mí gbé mi sókè, mo sì gbọ́ ohùn ìró ńlá lẹ́yìn mi tó sọ pé, kí a gbé ògo Olúwa ga láti ibùgbé rẹ̀ wá! 13Bẹ́ẹ̀ ni mo tún gbọ́ ariwo ìyẹ́ apá àti kẹ̀kẹ́ àwọn ẹ̀dá alààyè náà pẹ̀lú ariwo tó dàbí àrá ńlá. 14Ẹ̀mí náà sì gbé mi sókè, ó sì mú mi lọ, mo lọ pẹ̀lú ọkàn kíkorò àti ìbínú nínú ẹ̀mí mi, pẹ̀lú ọwọ́ líle Olúwa ni ara mi. 15Nígbà náà ni mo lọ sí etí odò Kebari níbi tí àwọn ìgbèkùn ń gbé ni Teli-Abibu. Níbẹ̀ níbi tí wọ́n ń gbé, mo jókòó láàrín wọn pẹ̀lú ìyanu, fún ọjọ́ méje.

Ìkìlọ̀ sí Israẹli

163.16-21: El 33.1-9.Lẹ́yìn ọjọ́ méje, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé: 17“Ọmọ ènìyàn, mo ti fi ọ́ ṣe olùṣọ́ fún ilé Israẹli; nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, fún wọn ní ìkìlọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi. 18Bí mo bá sọ fún ènìyàn búburú pé, dájúdájú, ‘Ìwọ yóò kú,’ tí ìwọ kò sì kìlọ̀ fún ènìyàn búburú yìí láti dáwọ́ ìwà ibi rẹ̀ dúró, kí o sì gba ẹ̀mí rẹ̀ là, ènìyàn búburú náà yóò kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. 19Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún ènìyàn búburú, tí ó kọ̀ tí kò fi ìwà búburú rẹ̀ sílẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ṣùgbọ́n ọrùn tìrẹ ti mọ́.

20“Bákan náà, bí olódodo kan bá yípadà, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àìṣòdodo, tí mo sì fi ohun ìkọ̀sẹ̀ sí ọ̀nà rẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Nítorí pé ìwọ kọ̀ láti kìlọ̀ fún un, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, a ó gbàgbé gbogbo ìwà rere tó ti hù tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. 21Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún olódodo tó sì dáwọ́ ìwà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ dúró, dájúdájú òun yóò yè nítorí pé ó ti gba ìkìlọ̀, ọrùn tìrẹ sì mọ́.”

22Ọwọ́ Olúwa wà lára mi níbẹ̀, ó sì wí fún mi pé, “Dìde, lọ sí ibi tí ó tẹ́jú, èmi yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ níbẹ̀.” 23Mo sì dìde, mo lọ sí ibi tí ó tẹ́jú. Ògo Olúwa dúró níbẹ̀, ó dàbí irú ògo tí mo rí létí odò Kebari, mo sì dojúbolẹ̀.

24Nígbà náà ni Ẹ̀mí wọ inú mi, tí ó sì tún gbé mi dúró. Ó sì wí fún mi pé: “Lọ, ti ara rẹ mọ́ inú ilé rẹ 25ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, wọn yóò fi okùn dè ọ́ mọ́lẹ̀; dé ibi pé ìwọ kò ní í le rìn káàkiri láàrín àwọn ènìyàn. 26Èmi yóò mú kí ahọ́n rẹ lẹ̀ mọ́ àjà ẹnu rẹ, tó bẹ́ẹ̀ ti ìwọ yóò wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́. Ìwọ kò sì ní lè bá wọn wí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ní wọn 27Ṣùgbọ́n nígbà tí èmi bá bá ọ sọ̀rọ̀, Èmi yóò ṣí ọ lẹ́nu, ìwọ yóò sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’ Ẹni tó bá fẹ́ kí ó gbọ́, ẹni tó bá fẹ́ kọ̀, kó kọ̀ nítorí ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.

La Bible du Semeur

Ezéchiel 3:1-27

L’Eternel fortifie son prophète

1Celui qui me parlait me dit : Fils d’homme, mange ce qui t’est présenté, avale ce rouleau, puis va parler à la communauté d’Israël.

2J’ouvris la bouche et il me fit manger le rouleau. 3Puis il me dit : Fils d’homme, nourris ton corps et remplis ton ventre de ce rouleau que je te donne.

Je le mangeai donc et, dans ma bouche, il fut doux comme du miel. 4Il ajouta : Fils d’homme, va, rends-toi auprès des Israélites et communique-leur mes paroles. 5Car ce n’est pas vers un peuple qui parle une langue difficile et inintelligible que tu es envoyé, mais vers la communauté d’Israël.

6Si je t’envoyais vers de nombreux peuples à la langue difficile et inintelligible dont tu ne comprendrais pas les paroles, eux ils t’écouteraient. 7Mais la communauté d’Israël vers laquelle je t’envoie ne voudra pas t’écouter, car ils ne veulent pas m’écouter. En effet, tous ces Israélites sont des gens à la tête dure et au cœur insensible. 8Eh bien, je vais te donner un visage aussi obstiné que le leur et un front aussi résolu que le leur. 9Je vais rendre ton front aussi dur que le diamant, plus dur que le roc. Ne les crains donc pas et ne tremble pas en leur présence, bien que ce soit une communauté de rebelles.

10Puis il ajouta : Fils d’homme, écoute attentivement tout ce que je vais te dire et prends-le bien à cœur. 11Puis va te rendre auprès de tes compatriotes déportés pour leur parler, et – qu’ils t’écoutent ou qu’ils refusent de t’écouter – dis-leur : « Voici ce que déclare le Seigneur, l’Eternel. »

Emporté par l’Esprit de Dieu

12Alors l’Esprit me souleva et j’entendis derrière moi une grande clameur : Bénie soit la gloire de l’Eternel, du lieu où elle demeure.

13Je perçus aussi le bruit que faisaient les ailes des êtres vivants en battant l’une contre l’autre, et en même temps celui des roues, et la grande clameur. 14Alors l’Esprit me souleva de terre et m’emporta. Je partis, le cœur plein d’amertume et d’indignation, tandis que la main de l’Eternel agissait sur moi avec force. 15J’arrivai ainsi auprès des exilés, à Tel-Aviv3.15 Localité inconnue, colonie juive en Mésopotamie., chez ceux qui habitaient sur les bords du canal du Kebar, car c’est là qu’ils demeuraient. Je restai là sept jours, hébété, au milieu d’eux.

Les conditions d’exercice du ministère

Comme une sentinelle

16Au bout de ces sept jours, l’Eternel m’adressa la parole en ces termes :

17Fils d’homme, j’ai fait de toi une sentinelle pour la communauté d’Israël. Quand tu entendras une parole de ma bouche, tu les avertiras de ma part. 18Quand je dirai au coupable : « Tu vas mourir », si tu ne l’avertis pas, si tu ne parles pas pour avertir ce coupable et lui demander d’abandonner sa mauvaise conduite pour obtenir la vie sauve, alors, certes, ce coupable mourra à cause de sa faute, mais je te demanderai compte de sa mort. 19Si, par contre, tu as averti le coupable et qu’il ne se détourne pas de sa méchanceté ni de sa conduite coupable, il mourra pour sa faute, mais toi, tu auras la vie sauve.

20De même, si un homme juste se détourne de sa conduite juste pour faire le mal, alors je placerai quelque occasion de chute devant lui, et s’il meurt pour n’avoir pas été averti, certes, c’est à cause de sa faute qu’il mourra, et l’on ne tiendra pas compte de sa conduite juste du passé, mais je te demanderai compte de sa mort. 21Mais si tu as averti l’homme juste pour qu’il ne commette pas de faute, et qu’effectivement il n’en commette pas, alors il vivra pour avoir entendu tes avertissements et toi, tu auras la vie sauve.

Jours de silence

22La main de l’Eternel fut encore sur moi en ce lieu, et il me dit : Lève-toi, sors vers la vallée, et là je te parlerai.

23Je me levai donc et je sortis vers la vallée. Et voici que la gloire de l’Eternel se tenait là, identique à la gloire que j’avais contemplée près du canal du Kebar. Alors je tombai la face contre terre. 24Mais l’Esprit entra en moi et me fit tenir debout. Il me parla et me dit : Va t’enfermer dans ta maison. 25Or, fils d’homme, on viendra te ligoter avec des cordes, de sorte que tu ne pourras plus sortir au milieu de tes compatriotes. 26Je collerai ta langue à ton palais et tu seras muet ; ainsi tu cesseras d’intercéder pour eux, car c’est un peuple rebelle. 27Mais quand je te parlerai, je t’ouvrirai la bouche. Alors tu leur diras : « Voici ce que déclare le Seigneur, l’Eternel : Celui qui veut écouter, qu’il écoute, et celui qui refuse d’écouter, qu’il n’écoute pas – car c’est une communauté rebelle. »