Esekiẹli 2 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Esekiẹli 2:1-10

Ọlọ́run pe Esekiẹli

1Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, dìde dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ. Èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀.” 2Bí ó ṣe ń sọ̀rọ̀, ẹ̀mí sì wọ inú mi ó mú mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi, mo sì ń gbọ́ tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀.

3Ó sọ pé, “Ọmọ ènìyàn, mo ń rán ọ sí àwọn ọmọ Israẹli, sí ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi; àwọn àti baba ńlá wọn ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi títí di òní olónìí. 4Àwọn ènìyàn tí mo ń rán ọ sí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle. Sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí’ 5Bí wọn fetísílẹ̀ tàbí wọn kò fetísílẹ̀—nítorí pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n—wọn yóò mọ̀ pé wòlíì kan wà láàrín wọn. 6Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn, má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí ọ̀rọ̀ ẹnu wọn. Má ṣe bẹ̀rù, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òṣùṣú àti ẹ̀gún yí ọ ká, tí o sì ń gbé àárín àwọn àkéekèe. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n ń sọ tàbí bẹ̀rù wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ìdílé ni wọ́n. 7Ìwọ gbọdọ̀ sọ ọ̀rọ̀ mi fún wọn, bí wọ́n gbọ́ bí wọn kọ̀ láti gbọ́ torí pé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n. 82.8–3.3: If 5.1; 10.8-10.Ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, gbọ́ ohun tí mo ń sọ fún ọ. Má ṣe ṣọ̀tẹ̀ bí i ti ìdílé ọlọ́tẹ̀; la ẹnu rẹ kí o sì jẹ ohun tí mo fún ọ.”

9Mo sì wò, mo sì rí ọwọ́ kan tí a nà sí mi. Ìwé kíká sì wà níbẹ̀, 10ó sì tú ìwé náà fún mi. Ní ojú àti ẹ̀yìn ìwé náà ni a kọ ìpohùnréré ẹkún, ọ̀fọ̀ àti ègún sí.

La Bible du Semeur

Ezéchiel 2:1-10

La mission d’Ezéchiel

1Il me dit : Fils d’homme, tiens-toi debout, et je vais te parler.

2Dès qu’il m’eut adressé ces mots, l’Esprit entra en moi et me fit tenir debout, et j’entendis celui qui me parlait. 3Il me dit : Fils d’homme, je t’envoie vers les Israélites, vers cette foule de rebelles qui se sont révoltés contre moi. Jusqu’à ce jour, eux et leurs ancêtres se sont soulevés contre moi. 4C’est vers ces gens à la tête dure et au cœur insensible que je t’envoie pour que tu leur dises : « Voici ce que déclare le Seigneur, l’Eternel. » 5Alors, soit qu’ils écoutent, soit qu’ils refusent d’écouter – car c’est une communauté rebelle – ils sauront du moins qu’il y a un prophète au milieu d’eux.

6Quant à toi, fils d’homme, ne les crains pas, et ne crains pas leurs paroles, bien que tu sois au milieu d’orties et de ronces et que tu habites avec des scorpions. Ne crains pas leurs paroles et ne tremble pas devant eux, car c’est une communauté rebelle. 7Tu leur transmettras donc mes paroles, soit qu’ils écoutent, soit qu’ils refusent d’écouter à cause de leur esprit rebelle.

La vision du rouleau

8Et toi, fils d’homme, écoute ce que je te dis : Ne sois pas toi-même rebelle comme cette communauté rebelle ; ouvre ta bouche et mange ce que je te donne.

9Je regardai, et je vis une main tendue vers moi qui tenait le rouleau d’un livre2.9 2.9 à 3.3 : voir Ap 10.9-10.. 10Elle le déroula devant moi : il était couvert d’inscriptions au recto et au verso2.10 Normalement, l’écriture ne figurait que d’un côté. Le rouleau était saturé de paroles de jugement (Za 5.3 ; Ap 5.1). : c’étaient des plaintes, des lamentations et des cris de malheur.