Daniẹli 12 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Daniẹli 12:1-13

Ìgbà ìkẹyìn

112.1: Mt 24.21; Mk 13.19; If 12.7; 16.18.“Ní àkókò náà, ni Mikaeli, ọmọ-aládé ńlá, ẹni tí o ń dáàbò bo àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò dìde. Àkókò ìpọ́njú yóò wà, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí láti ìbẹ̀rẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè títí di àkókò náà. Ṣùgbọ́n ní àkókò náà àwọn ènìyàn rẹ̀, gbogbo àwọn tí a bá ti rí orúkọ wọn nínú ìwé ni a ó gbàlà. 212.2: Mt 25.46.Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn tí ó sùn nínú erùpẹ̀ ilẹ̀ ni yóò jí: àwọn mìíràn sí ìyè àìnípẹ̀kun, àwọn tókù sí ìtìjú àti sí ẹ̀gàn àìnípẹ̀kun. 312.3: Mt 13.43.Àwọn tí ó jẹ́ ọlọ́gbọ́n yóò máa tàn bí ìmọ́lẹ̀ ọ̀run, àti àwọn tí ó ń tọ́nisọ́nà sí òdodo, yóò máa tàn bí ìràwọ̀ láé àti láéláé. 412.4: If 22.10.Ṣùgbọ́n ìwọ Daniẹli, pa ìwé náà dé kí o sì pa ọ̀rọ̀ ọ rẹ̀ mọ́ títí àkókò ìgbẹ̀yìn. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò máa lọ sí ìhín sí ọ̀hún láti jẹ́ kí ìmọ̀ wọn di púpọ̀.”

5Nígbà náà, ni èmi Daniẹli, wò, ní iwájú mi àwọn méjì mìíràn dúró, ọ̀kan dúró sí apá ìhín ní etí bèbè odò ẹnìkan náà ní apá òdìkejì ọ̀hún etí i bèbè. 6Ọ̀kan lára wọn sọ fún ọkùnrin tí ó wọ aṣọ àlà, ẹni tí ó wà lórí omi odò pé, “Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó kí àwọn nǹkan ìyanu wọ̀nyí tó wá sí ìmúṣẹ?”

712.7: If 4.9; 10.5; 12.14.Ọkùnrin tí ó wọ aṣọ àlà, ẹni tí ó wà lórí omi odò, gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti ọwọ́ òsì rẹ̀, mo gbọ́ tí ó fi ẹni tí ó wà títí láé búra, ó sọ wí pé, “Yóò ṣe ní àkókò kan, àkókò méjì àti ààbọ̀. Nígbà tí agbára àwọn ẹni mímọ́ yóò ti fọ́ tán pátápátá, gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò sì parí.”

8Èmi gbọ́, ṣùgbọ́n kò yé mi. Nígbà náà ni mo béèrè pé, “Olúwa mi, kí ni yóò jẹ́ àbábọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí?”

9Ó sì dáhùn pé, “Máa lọ ní ọ̀nà rẹ, Daniẹli nítorí tí a ti pa ọ̀rọ̀ náà dé, a sì ti fi èdìdì dì í di ìgbà ìkẹyìn. 10Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni a ó fọ̀ mọ́, wọn yóò wà láìlábàwọ́n, a ó sì tún wọn ṣe, ṣùgbọ́n àwọn ẹni búburú yóò máa ṣe búburú lọ, kò sí ẹni búburú tí òye yóò yé ṣùgbọ́n òye yóò yé àwọn ọlọ́gbọ́n.

1112.11: Da 9.27; 11.31; Mt 24.15; Mk 13.14.“Láti àkókò tí a ó mú ẹbọ ojoojúmọ́ kúrò, tí a ó sì gbé ìríra tí ó ń fa ìsọdahoro kalẹ̀ yóò sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún àti igba lé àádọ́rùn-ún ọjọ́ (1,290). 12Ìbùkún ni fún ẹni tí ó dúró, ti ó sì di òpin ẹgbẹ̀rún àti ọ̀ọ́dúnrún lé àrùndínlógójì ọjọ́ (1,335).

13“Ṣùgbọ́n ìwọ, máa lọ ní ọ̀nà rẹ, títí di òpin. Ìwọ yóò sinmi, àti ní òpin ọjọ́ ìwọ yóò dìde láti gba èrè rẹ.”

New Serbian Translation

Књига пророка Данила 12:1-13

Васкрсење мртвих

1У то време ће се појавити Михаило, велики кнез, бранитељ твог народа. То ће бити време невоље какве није било од кад народ постоји. У то време ће бити избављен твој народ, свако ко се нађе записан у Књизи. 2Пробудиће се многи који почивају у праху земаљском, једни за вечни живот, а други за срамоту и вечни презир. 3Тада ће разборити засјати као светлост с небеског свода, и они који многе воде к праведности, као звезде у веке векова. 4А ти, Данило, држи у тајности ове речи и запечати ову књигу док не дође време краја. Многи ће ићи с једног краја на други, и знање ће се умножити.“

5Ја, Данило, погледао сам и видео другу двојицу како стоје, један на једној обали реке, а други на другој обали. 6Тада је неко рекао човеку обученом у ланену одећу, који је био изнад речне воде: „Када ће доћи крај тим чудесима?“

7Тада сам чуо човека обученог у ланену одећу, оног што је био изнад речне воде. Он је подигао своју десну и леву руку према небу и заклео се оним који живи заувек: „За једно време, за два времена и пола времена12,7 Вероватно значење је три и по године. – када се оконча слом снаге светог народа – све ће се то завршити.“

8Ја сам то чуо, али нисам разумео. Питао сам: „Господару мој, како ће се то завршити?“

9Он је одговорио: „Иди сад, Данило, јер су те речи тајне и запечаћене до времена краја. 10Многи ће се очистити, избелити и прекалити, а зли ће устрајати у злу. И ниједан од злих неће разумети, али ће разборити разумети.

11Од часа кад се укине дневна жртва и постави се страшна гадост биће хиљаду две стотине деведесет дана. 12Благо ономе ко истраје и дочека хиљаду три стотине тридесет пет дана.

13А ти, настави до краја, па ћеш се одморити и примити свој део на крају дана.“