Daniẹli 11 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Daniẹli 11:1-45

1Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ará Media, mo dúró láti tì í lẹ́yìn àti láti dáàbò bò ó.)

Àwọn ọba gúúsù àti àríwá

2“Ní ìsinsin yìí, mo sọ òtítọ́ fún ọ ọba mẹ́ta yóò dìde sí i ní Persia, àti ẹ̀kẹrin tí yóò jẹ́ ọlọ́rọ̀ ju gbogbo wọn lọ. Tí ó bá ti di alágbára nípa ọrọ̀ rẹ̀, yóò sì ru gbogbo wọn sókè lòdì sí ìjọba Giriki. 3Nígbà náà ni ọba alágbára kan yóò fi ara hàn, yóò ṣe àkóso pẹ̀lú agbára ńlá, yóò sì ṣe bí ó ti wù ú. 4Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá fi ara hàn tán, ìjọba rẹ̀ yóò fọ́, yóò sì pín sí mẹ́rin ní orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé, ìjọba náà kò sì ṣọ́wọ́ àwọn ìran rẹ̀ tàbí kí ó ní agbára tí ó ń lò tẹ́lẹ̀, nítorí, a ó fa ìjọba rẹ̀ tu a ó sì fi fún àwọn mìíràn.

5“Ọba ìhà gúúsù yóò di alágbára ṣùgbọ́n ọ̀kan lára àwọn aláṣẹ rẹ̀ yóò di alágbára jù ú lọ, yóò sì ṣe àkóso ìjọba rẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá. 6Lẹ́yìn ọdún púpọ̀ wọn yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà, ọmọbìnrin ọba gúúsù yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ọba àríwá láti bá a dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n òun kì yóò lè di agbára apá a rẹ̀ mú, bẹ́ẹ̀ ni òun kì yóò lè dádúró, ṣùgbọ́n a ó tẹrí i rẹ̀ ba àti àwọn tí ó mú un wá, àti ọmọ tí ó bí, àti ẹni tí ó ń mu lọ́kàn le ní gbogbo àkókò wọ̀nyí.

7“Ọ̀kan lára àwọn ìdílé e rẹ̀, ọmọbìnrin ọba gúúsù yóò dìde láti gba ipò o rẹ̀. Yóò sì kọlu ogun ọba àríwá, yóò sì wó odi alágbára; yóò bá wọn jà yóò sì borí. 8Yóò gba òrìṣà wọn, ère dídá àti ohun èlò oníye lórí ti fàdákà àti ti wúrà, yóò sì kó wọn lọ sí Ejibiti. Fún ọdún díẹ̀ yóò fi ọba àríwá lọ́rùn sílẹ̀. 9Nígbà náà, ni ọba àríwá yóò gbógun ti ilẹ̀ ọba, gúúsù, ṣùgbọ́n yóò padà sí orílẹ̀-èdè Òun fúnrarẹ̀ 10Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò múra ogun wọn yóò kó ogun ńlá jọ, èyí tí a ó gbá lọ bí àgbàrá omi ńlá, yóò sì gbá a lọ títí dé ìlú olódi rẹ̀.

11“Nígbà náà ni ọba gúúsù yóò jáde pẹ̀lú ìbínú, yóò sì bá ọba àríwá jà, ẹni tí yóò kó ọmọ-ogun púpọ̀ jọ, ṣùgbọ́n ọba gúúsù yóò borí i wọn. 12Nígbà tí a bá kó ogun náà lọ, ọba gúúsù yóò kún fún agbára, yóò sì pa ẹgbẹgbẹ̀rún ní ìpakúpa síbẹ̀ kì yóò ṣẹ́gun. 13Nítorí ọba àríwá yóò lọ kó ogun mìíràn jọ, tí ó pọ̀ ju ti àkọ́kọ́ lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún, yóò jáde pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun tí ó ti dira ogun fún dáradára.

14“Ní àkókò ìgbà náà, ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò dìde sí ọba gúúsù. Àwọn ọlọ̀tẹ̀ nínú àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò ṣọ̀tẹ̀ ní ìmúṣẹ ìran náà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò borí. 15Nígbà náà ni ọba àríwá yóò wá yóò sì gbé ogun tì í, yóò sì kó ìlú olódi. Ogun ọba gúúsù kò ní ní agbára láti kọjú ìjà sí i; Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọ̀wọ́ ogun tó dára jù kò ní ní agbára láti dúró. 16Ẹni tí ó gbóguntì í yóò máa ṣe bí ó ti wù ú, kò sì ṣí ẹni tí yóò le è dojúkọ ọ́. Yóò sì fún ara rẹ̀ ní ibùjókòó ní ilẹ̀ tí ó dára, yóò sì ní agbára láti bà á jẹ́. 17Yóò pinnu láti wá pẹ̀lú agbára ìjọba rẹ̀, yóò sì ní májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú ọba gúúsù yóò sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ fún un láti fẹ́ ẹ ní ìyàwó nítorí kí ó lè gba ìjọba, ṣùgbọ́n ète rẹ̀ yìí kì yóò dúró tàbí ṣe ìrànlọ́wọ́ fún un. 18Nígbà náà ni yóò yí ara padà sí ilẹ̀ etí Òkun, yóò mú ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n aláṣẹ kan yóò mú òpin bá àfojúdi rẹ̀, yóò sì yí àfojúdi rẹ̀ padà sí orí rẹ̀. 19Lẹ́yìn èyí, yóò sì yí padà sí ìlú olódi ti orílẹ̀-èdè òun fúnrarẹ̀, ṣùgbọ́n yóò kọsẹ̀ yóò sì ṣubú, a kì yóò sì rí i mọ́.

20“Arọ́pò rẹ̀ yóò rán agbowó orí kan jáde láti fi ìdí ipò ọlá ọba múlẹ̀ ṣùgbọ́n ní ìwọ̀n ọdún díẹ̀, a ó pa á run, kì yóò jẹ́ nípa ìbínú tàbí nínú ogun.

21“Ẹni tí kò níláárí kan yóò rọ́pò rẹ̀, ẹni tí a kò tí ì fi ọlá ọba fún rí. Yóò sì gbógun sí ìjọba nígbà tí ọkàn àwọn ènìyàn balẹ̀ láìbẹ̀rù, yóò sì gbà á pẹ̀lú àrékérekè. 22Nígbà náà, ni a ó gbà ogunlọ́gọ̀ ogun kúrò níwájú u rẹ̀, pẹ̀lú òun àti ọmọ-aládé ti májẹ̀mú náà ni a ó parun. 23Lẹ́yìn tí ó wá ṣe ìpinnu pẹ̀lú u rẹ̀, yóò hùwà ẹ̀tàn, pẹ̀lú ìwọ̀nba ènìyàn kékeré ni yóò gba ìjọba. 24Nígbà tí àwọn agbègbè tí ó lọ́rọ̀ gidigidi wà láìbẹ̀rù ni yóò gbóguntì wọ́n, yóò ṣe ohun tí baba rẹ̀ tàbí baba ńlá rẹ̀ kò ṣe rí, yóò pín ìkógun ẹrù àti ọrọ̀ fún àwọn ọmọ lẹ́yìn in rẹ̀. Yóò pète àti bi àwọn ìlú olódi ṣubú, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀ ni.

25“Pẹ̀lú ogun púpọ̀, yóò sì ru agbára rẹ̀ àti ìgboyà rẹ̀ sókè sí ọba gúúsù. Ọba gúúsù yóò dìde ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ-ogun tí ó lágbára gidigidi, ṣùgbọ́n kò ní le è dúró, nítorí ọ̀tẹ̀ tí ó gbèrò sí i. 26Àwọn tí ó jẹ nínú oúnjẹ ọba yóò gbìyànjú láti parun: a ó gbá ogun rẹ̀ dànù, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni yóò ṣubú sí ogun. 27Àwọn ọba méjèèjì, ọkàn wọn tẹ̀ sí búburú, wọn yóò jókòó lórí tábìlì kan, wọn yóò máa parọ́ sí ara wọn, ṣùgbọ́n kò ní yọrí sí nǹkan kan nítorí òpin yóò wá ní àsìkò tí a yàn. 28Ọba àríwá yóò padà sí ilẹ̀ rẹ̀ pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀, ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ yóò lòdì sí májẹ̀mú mímọ́, yóò sì ṣiṣẹ́ lòdì sí i, yóò sì padà sí orílẹ̀-èdè òun fúnrarẹ̀.

29“Ní àsìkò tí a yàn, yóò gbógun sí gúúsù lẹ́ẹ̀kan sí i, ṣùgbọ́n ní ìgbà yí àyọríṣí yóò yàtọ̀ sí ti ìṣáájú. 30Nítorí pé, ọkọ̀ ojú omi àwọn ilẹ̀ etídò ìwọ̀-oòrùn yóò takò ó, ọkàn rẹ̀ yóò sì pami. Nígbà náà, ni yóò padà, yóò sì bínú sí májẹ̀mú mímọ́, yóò sì padà, yóò sì fi ojúrere hàn sí àwọn tí ó kọ májẹ̀mú mímọ́ náà.

3111.31: Da 9.27; 12.11; Mt 24.15; Mk 13.14.“Agbára ọmọ-ogun rẹ̀ yóò dìde láti ba ohun mímọ́ ilé olódi tẹmpili jẹ́, yóò sì pa ẹbọ ojoojúmọ́ rẹ́. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ìríra tí ó fa ìsọdahoro kalẹ̀. 32Pẹ̀lú irú àwọn tí ń ṣe búburú sí májẹ̀mú ní yóò fi ọ̀rọ̀ ìpọ́nni mú ṣọ̀tẹ̀, ṣùgbọ́n, àwọn tí ó mọ Ọlọ́run wọn yóò mú ọkàn le. Wọn yóò sì máa ṣe iṣẹ́ agbára.

33“Àwọn tí ó mòye yóò máa kọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀, wọn yóò máa ṣubú nípa idà tàbí kí a jó wọn tàbí ìgbèkùn tàbí nípa ìkógun. 34Nígbà tí wọ́n bá ṣubú, wọn yóò rí ìrànlọ́wọ́ díẹ̀, ọ̀pọ̀ àwọn tó ṣe aláìṣòótọ́ yóò sì darapọ̀ mọ́ wọn. 35Lára àwọn tí ó mòye yóò kọsẹ̀, nítorí kí a ba à tún wọn ṣe, wọ́n di mímọ́ àti aláìlábàwọ́n títí di ìgbà ìkẹyìn nítorí yóò sì wá ní àkókò tí a yàn.

Ọba tí ó gbé ara rẹ̀ ga

36“Ọba yóò ṣe bí ó ti wù ú yóò sì gbé ara rẹ̀ ga, ju gbogbo òrìṣà lọ, yóò máa sọ àwọn ọ̀rọ̀ tí kò-ṣe-é-gbọ́-létí sí Ọlọ́run àwọn Ọlọ́run, yóò sì máa yege títí àkókò ìbínú yóò fi parí, nítorí ohun tí a ti pinnu yóò ṣẹlẹ̀. 37Òun kò ní ka òrìṣà àwọn baba rẹ̀ sí tàbí èyí tí àwọn fẹ́, òun kò ní ka nǹkan kan sí, ṣùgbọ́n yóò gbé ara rẹ̀ ga ju gbogbo wọn lọ. 38Ṣùgbọ́n dípò wọn, yóò bu ọlá fún òrìṣà àwọn ìlú olódi: òrìṣà tí àwọn baba rẹ̀ kò mọ̀ ni yóò bu ọlá fún pẹ̀lú wúrà àti fàdákà, pẹ̀lú òkúta iyebíye àti ẹ̀bùn tí ó lówó lórí. 39Yóò kọlu àwọn ìlú olódi tí ó lágbára pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ òrìṣà àjèjì, yóò sì bu ọláńlá fún ẹni tí ó jẹ́wọ́ rẹ̀. Yóò mú wọn ṣe alákòóso lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, yóò sì pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí èrè.

40“Ní ìgbà ìkẹyìn, ọba gúúsù yóò gbé ogun de sí i, ọba àríwá yóò sì jáde bí ìjì láti kọlù ú pẹ̀lú u kẹ̀kẹ́ ogun àti ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkọ̀ ojú omi. Yóò gbógun wọ orílẹ̀-èdè púpọ̀, yóò sì bo wọn mọ́lẹ̀ bí ìkún omi. 41Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì tún gbógun ti ilẹ̀ ológo náà pẹ̀lú, ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò ṣubú, ṣùgbọ́n Edomu, Moabu àti àwọn olórí Ammoni yóò bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀. 42Yóò lo agbára rẹ̀ lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè; Ejibiti kì yóò là. 43Yóò gba àkóso ìṣúra wúrà àti fàdákà àti gbogbo ọrọ̀ Ejibiti, pẹ̀lú ti Libia àti Kuṣi nígbà tí ó mú wọn tẹríba. 44Ṣùgbọ́n ìròyìn láti ìlà-oòrùn àti láti ìwọ̀-oòrùn yóò mú ìdáríjì bá a, yóò sì fi ìbínú ńlá jáde lọ láti parun, àti láti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ run pátápátá. 45Yóò sì pàgọ́ ọ rẹ̀ láàrín Òkun kọjú sí àárín òkè mímọ́ ológo Síbẹ̀ yóò wá sí òpin rẹ̀, ẹnìkan kò ní ràn án lọ́wọ́.

New Serbian Translation

Књига пророка Данила 11:1-45

1У првој години Дарија Међанина, ја сам се заузео да га охрабрим и заштитим.

Цареви југа и севера

2Сада ћу ти рећи истину: ево, још ће три цара настати у Персији, али четврти ће бити богатији од свих њих. А кад стекне моћ својим богатством, све ће подићи на грчко царство. 3Затим ће настати моћни цар који ће владати великим царством и радити шта хоће. 4Али, пошто дође на власт, распашће се његово царство. Оно ће бити раздељено на четири небеска ветра, али не између његовог потомства. Оно неће имати исту силу као када је он владао, јер ће његово царство бити сломљено и предано другима, а не њима.

5Затим ће јужни цар постати моћан, али ће га надмашити један од његових кнезова, који ће владати већим царством него што је његово. 6После неколико година, они ће се спријатељити, па ће ћерка јужног цара доћи к северном цару да склопи савез. Међутим, неће задржати силу, а ни њено потомство неће опстати: биће предана заједно са својом пратњом, својим дететом и оним који ће јој помагати у тим временима.

7Али на његово место ће доћи један од потомака из њене лозе. Он ће кренути против војске, ући у тврђаву северног цара, борити се с њима и свладати их. 8Однеће и њихове богове, њихове ливене кипове, њихове драгоцене предмете од сребра и злата, као плен у Египат. Неколико година ће оставити на миру северног цара. 9Овај ће, затим, напасти царство јужног цара, али ће се вратити у своју земљу. 10Његови синови ће поћи у рат; скупиће огромну војску, која ће кренути, навалити као силна поплава, пробити се и наставити рат све до његовог утврђења.

11Тада ће се јужни цар разбеснети и изаћи у рат против северног цара, који ће подићи огромну војску. Ипак, то ће мноштво бити предано у руке оног другог. 12А кад порази то мноштво, јужни цар ће се узохолити и побити хиљаде и хиљаде, али неће надвладати. 13Наиме, северни цар ће се вратити и скупити већу војску од прве. Онда ће после неколико година доћи с великом војском и великом опремом.

14У то време ће многи устати против јужног цара; побуниће се и насилници из твога народа да испуне виђење, али ће поклекнути. 15Потом ће доћи северни цар, подићи насипе и заузети утврђени град. Снаге југа неће одолети; чак ни најбољи од војске неће имати снаге да се одупру. 16А његов противник ће радити шта хоће и нико неће моћи да му се одупре; он ће се зауставити у Дивној земљи, а његова рука донеће уништење. 17Он ће бити решен да силом заузме све његово царство, али ће склопити савез са њим; даће му своју ћерку за жену како би срушио царство. Ипак, неће успети; то му се неће остварити. 18Онда ће се окренути према острвима и освојити многа од њих, али ће један војвода стати на крај срамоти коју чини, да му врати за његову срамоту. 19Затим ће се окренути ка тврђавама у својој земљи, али ће посрнути, пасти и више га неће бити.

20Његово место заузеће човек који ће послати утеривача пореза за царску раскош. Ипак, пропашће за неколико дана без гнева и боја.

21На његово место ће доћи ништарија, коме није намењена царска част. Он ће доћи у време мира и сплеткама се докопати царства. 22Силне ће војске бити уништене пред њим. Чак ће и владар савеза бити разбијен. 23Он ће преварити и оне који склопе савез са њим, и тако постати веома моћан уз помоћ малог броја људи. 24Он ће напасти најбогатије покрајине у време спокојства, и чинити оно што нису чинили ни његови очеви, ни очеви његових очева, делећи међу својима плен, грабеж и богатство. Смишљаће и лукавства против утврђења, али само за неко време.

25Потом ће, с великом војском, скупити снагу и храброст против јужног цара. Јужни цар ће поћи у рат с веома великом и моћном војском, али неће одолети, јер ће се ковати завере против њега. 26Уништиће га они што се хране царевом храном. Његова ће војска бити збрисана; многи ће пасти побијени. 27Оба цара ће у срцу смишљати зло; седеће за истим столом и лагати један другог, али без успеха, јер ће до свршетка доћи тек у одређено време.

28Северни цар ће се вратити у своју земљу с великим богатством, али ће срцем бити против светог савеза. Кад тако уради, вратиће се у своју земљу. 29У одређено време ће се вратити и опет напасти југ, али овај пут неће бити као први пут. 30На њега ће доћи китимски бродови и он ће се обесхрабрити. Онда ће се вратити и искалити свој бес на светом савезу. Кад то учини, вратиће се и показати наклоност према онима који су напустили свети савез.

31Његове снаге ће устати и оскрнавити тврђаву Светилишта и укинути дневну жртву. Затим ће поставити тамо страшну гадост. 32Он ће ласкањем навести на отпадништво прекршиоце савеза, али ће народ који познаје свога Бога остати постојан и ступити на дело.

33Разборити међу народом поучиће многе, али ће за неко време страдати од мача и пламена, ропства и пљачке. 34Док буду страдали, примиће малу помоћ, али многи ће им се неискрено придружити. 35Неки од разборитих ће проћи кроз страдање, да буду прекаљени, прочишћени и чисти, док не дође време краја, јер одређено време тек треба да дође.

Самоузвишени цар

36Цар ће чинити шта хоће. Он ће се узохолити и узвисивати се више сваког бога. Говориће погрдно против Бога над боговима, и напредоваће док се не доврши гнев, јер што је одређено, то ће се испунити. 37Он неће марити за богове својих очева, ни за љубимца жена; он неће марити ни за каквог бога, него ће себе уздизати. 38Уместо њих, он ће славити бога тврђава, бога за кога нису знали његови очеви. Славиће га златом и сребром, драгим камењем и скупоценостима. 39Уз помоћ тог страног бога напашће најтврђа утврђења и указаће велику част онима који га буду прихватили. Њима ће дати власт над многима, и разделити земљу по одређеној цени.

40А у време краја, јужни цар ће укрстити рогове с њим, али ће се северни цар оборити на њега са борбеним колима и коњаницима, и с многим лађама. Он ће упасти у земље и проћи кроз њих као поплава. 41Упашће и у Дивну земљу и многе ће земље пасти. Ипак, његовој руци умаћи ће Едом, Моав и већи део Амонаца. 42Он ће посегнути руком на земље; ни Египат му неће утећи. 43Он ће се домоћи власти над ризницима злата и сребра и над свим драгоценостима Египта. Следиће га Лувимани и Кушани. 44Међутим, узнемириће га вести са истока и са севера, па ће с великим гневом отићи да уништи и истреби многе. 45Затим ће разапети шаторе – царске одаје, између мора и горе Свете дивоте. А кад му дође крај, нико му неће помоћи.