Amosi 2 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Amosi 2:1-16

12.1-3: Isa 15–16; 25.10-12; Jr 48; El 25.8-11; Sf 2.8-11.Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu,

àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,

Nítorí ó ti sun ún, di eérú,

egungun ọba Edomu

2Èmi yóò rán iná sí orí Moabu

èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run.

Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo

pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè

3Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò

Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,”

ni Olúwa wí.

4Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda,

àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà

Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀

wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́

Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà

òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé

5Èmi yóò rán iná sí orí Juda

èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”

Ìdájọ́ tí yóò wá sórí Israẹli

6Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli

àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.

Wọ́n ta olódodo fún fàdákà

àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.

7Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀

bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀

tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára

Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà

Láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́

8Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ

Lórí aṣọ tí wọ́n ti jẹ́ ẹ̀jẹ́

ní ilé òrìṣà wọn

wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.

9“Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn

gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari.

Òun sì le koko bí igi óákù

mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá

àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.

10Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá,

mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún

láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.

11“Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín

àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri

èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?”

ni Olúwa wí.

12“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu

e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.

13“Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀

bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.

14Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ

alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀

jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là

15Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀

bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin

kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là

16Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ

yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,”

ni Olúwa wí.

La Bible du Semeur

Amos 2:1-16

Contre les Moabites

1L’Eternel dit ceci :

Moab2.1 Le territoire de Moab s’étendait à l’est de la mer Morte. a perpétré ╵de nombreux crimes ;

il a dépassé les limites. ╵Voilà pourquoi ╵je ne reviendrai pas ╵sur l’arrêt que j’ai pris,

car ce peuple a brûlé ╵les os du roi d’Edom, ╵pour les réduire en chaux.

2Je mettrai le feu à Moab

et il consumera ╵les palais de Qeriyoth2.2 Site inconnu (voir Jr 48.24). Autre traduction : de ses villes.,

et Moab périra ╵en plein tumulte

au bruit des cris de guerre, ╵au son du cor.

3Je ferai disparaître ╵son chef, et avec lui,

je vais exterminer ╵tous ses ministres,

l’Eternel le déclare.

Contre le royaume de Juda

4L’Eternel dit ceci :

Juda a perpétré ╵de nombreux crimes ;

il a dépassé les limites. ╵Voilà pourquoi ╵je ne reviendrai pas ╵sur l’arrêt que j’ai pris,

car ils ont méprisé ╵la Loi de l’Eternel

et n’ont pas obéi ╵à ses commandements.

Ils se sont égarés ╵en suivant les faux dieux

qu’autrefois leurs ancêtres ╵avaient déjà suivis.

5Je mettrai le feu à Juda

et il consumera ╵les palais de Jérusalem.

Contre Israël

6L’Eternel dit ceci :

Israël a commis ╵de nombreux crimes ;

il a dépassé les limites. ╵Voilà pourquoi ╵je ne reviendrai pas ╵sur l’arrêt que j’ai pris,

car pour un pot-de-vin ╵ils vendent l’innocent,

et l’indigent ╵pour une paire de sandales.

7Ils piétinent la tête ╵des démunis dans la poussière2.7 Ils piétinent la tête des démunis dans la poussière: c’est ainsi qu’ont compris les versions. Autre traduction : ils convoitent même jusqu’à la poussière du sol que les démunis se jettent sur la tête en signe de deuil.,

et ils faussent le droit des pauvres2.7 Autre traduction : ils détournent les humbles du droit chemin..

Le fils comme le père ╵vont vers la même fille2.7 Voir Lv 18.15 ; Dt 22.28-29.,

c’est ainsi qu’ils m’outragent, ╵moi qui suis saint.

8Près de chaque autel, ils s’étendent

sur des vêtements pris en gage2.8 Voir Ex 22.25-26 ; Dt 24.10-13.

et, dans le temple de leurs dieux, ╵ils vont boire

le vin ╵que l’on a perçu comme amende.

9Pourtant, moi j’ai détruit ╵devant eux les Amoréens2.9 Un terme qui englobe tous les anciens habitants de Canaan (voir v. 10 ; Gn 15.16 ; Dt 7.1).

qui sont aussi grands que des cèdres

et forts comme des chênes,

et j’ai détruit leurs fruits en haut

et en bas leurs racines.

10Pourtant, moi je vous ai fait ╵sortir d’Egypte

et je vous ai conduits ╵pendant quarante ans au désert

pour que vous possédiez ╵le pays des Amoréens.

11J’ai choisi certains de vos fils ╵pour être des prophètes

et certains de vos jeunes gens ╵pour m’être consacrés par vœu2.11 Voir Nb 6.1-21..

N’en est-il pas ainsi, ╵Israélites ?

l’Eternel le demande.

12Mais à ces hommes consacrés, ╵vous avez fait boire du vin

et aux prophètes, ╵vous avez ordonné :

« Ne prophétisez pas. »

13Je vais vous écraser sur place

comme écrase un chariot ╵chargé de gerbes.

14Alors les plus agiles mêmes ╵ne trouveront pas de refuge,

et les plus vigoureux ╵ne pourront rassembler leurs forces,

ni le guerrier ╵sauver sa vie.

15Celui qui manie l’arc ╵ne résistera pas.

L’homme le plus agile ╵ne s’échappera pas,

même le meilleur cavalier ╵ne pourra pas sauver sa vie.

16En ce jour-là, ╵le guerrier le plus valeureux

fuira, tout nu,

l’Eternel le déclare.