2 Tẹsalonika 3 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

2 Tẹsalonika 3:1-18

Ẹ̀bẹ̀ àdúrà

13.1: 1Tẹ 5.25; 1.8.Ní àkótán, ará, ẹ máa gbàdúrà fún wa, kí ọ̀rọ̀ Olúwa lè máa tàn káàkiri, kí ó sì jẹ́ èyí tí a bu ọlá fún, gẹ́gẹ́ bí ó ti rí ní ọ̀dọ̀ yín. 23.2: Ro 15.31.Kí ẹ sì máa gbàdúrà fún wa kí a lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn ìkà àti àwọn ènìyàn búburú, nítorí pé kì í ṣe gbogbo ènìyàn ló ní ìgbàgbọ́. 33.3: 1Kọ 1.9; 1Tẹ 5.24.Ṣùgbọ́n olódodo ni Olúwa, ẹni tí yóò fi ẹsẹ̀ yín múlẹ̀, tí yóò sì pa yín mọ́ kúrò nínú ibi. 4Àwa sì ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa ní ti ohun tí ẹ ń ṣe, àti pé àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a pàṣẹ fún un yín ni ẹ̀yin ń ṣe. 5Kí Olúwa máa tọ́ ọkàn yín ṣọ́nà sí ìfẹ́ Ọlọ́run àti sínú sùúrù Kristi.

Ìkìlọ̀ ní ṣíṣe ìmẹ́lẹ́

63.6: 1Kọ 5.4,5,11; 1Tẹ 5.14.Ní orúkọ Jesu Kristi Olúwa wa, àwa pàṣẹ fún un yín ará, pé kí ẹ yẹra fún gbogbo àwọn arákùnrin yín tí ń ṣe ìmẹ́lẹ́, tí kò sì gbé ní ìbámu pẹ̀lú ẹ̀kọ́ tí ẹ gbà ní ọ̀dọ̀ wa. 73.7: 1Tẹ 1.6,9.Nítorí ẹ̀yin náà mọ̀ bí ó ṣe yẹ kí ẹ máa fi ara wé wa. Àwa kì í ṣe ìmẹ́lẹ́ nígbà tí a wà ní ọ̀dọ̀ yín. 83.8: 1Tẹ 2.9; Ap 18.3; Ef 4.28.Bẹ́ẹ̀ ni àwa kò sì jẹ oúnjẹ ẹnikẹ́ni lọ́fẹ̀ẹ́. Ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀, àwa ń ṣiṣẹ́ tọ̀sán tòru kí a má ba à di àjàgà sí ẹnikẹ́ni nínú yín lọ́rùn. 93.9: 2Tẹ 3.7.Àwa ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, kì í ṣe nítorí pé àwa kò ní ẹ̀tọ́ láti béèrè fún un, ṣùgbọ́n àwa ń fi ara wa ṣe àpẹẹrẹ tí ẹ ó tẹ̀lé. 103.10: 1Tẹ 4.11.Nítorí nígbà tí àwa wà lọ́dọ̀ yín, a ṣe àwọn òfin wọ̀nyí fún un yín pé, “Bí ẹnikẹ́ni kò bá fẹ́ ṣiṣẹ́, kí ó má ṣe jẹun.”

113.11: 2Tẹ 3.6.A gbọ́ pé àwọn kan wà láàrín yín tí wọn jẹ́ ìmẹ́lẹ́. Wọ́n jẹ́ atọjúlékiri. 123.12: 1Tẹ 4.1,11.Ǹjẹ́ irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ ni àwa ń pàṣẹ fún, tí a sì ń rọ̀ nínú Jesu Kristi Olúwa pé kí wọn ó máa ṣiṣẹ́ fún oúnjẹ tí wọ́n ń jẹ. 133.13: Ga 6.9.Ṣùgbọ́n ní tiyín ará, ẹ má ṣe jẹ́ kí agara dá yín ní rere ṣíṣe.

14Bí ẹnikẹ́ni kò bá sì pa òfin wa nínú lẹ́tà yìí mọ́, ẹ ṣààmì sí ẹni náà. Ẹ má ṣe bá a kẹ́gbẹ́ kí ojú bà á le tì í. 15Síbẹ̀, ẹ má ṣe kà á sí ọ̀tá, ṣùgbọ́n ẹ máa kìlọ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí arákùnrin yín.

Ìkíni ìkẹyìn

163.16: Ru 2.4.Ǹjẹ́ kí Olúwa àlàáfíà, fúnrarẹ̀ máa fún yín ní àlàáfíà nígbà gbogbo. Kí Olúwa kí ó wà pẹ̀lú gbogbo yín.

173.17: 1Kọ 16.21.Èmi Paulu fi ọwọ́ ara mi kọ lẹ́tà ìkíni yìí, èyí ṣe ààmì ìdámọ̀ nínú gbogbo lẹ́tà. Bí mo ṣe máa ń kọ̀wé nìyìí.

183.18: Ro 16.20; 1Tẹ 5.28.Kí oore-ọ̀fẹ́ Jesu Kristi Olúwa wa wà pẹ̀lú yín.

Nouă Traducere În Limba Română

2 Tesaloniceni 3:1-18

Rugați‑vă pentru noi!

1În cele din urmă, fraților, rugați‑vă pentru noi, ca să se răspândească repede Cuvântul Domnului și să fie glorificat, așa cum este și între voi, 2și să fim scăpați de oamenii neascultători și răi, căci nu toți au credința. 3Însă Domnul este credincios; El vă va întări și vă va păzi de cel rău. 4Cu privire la voi, suntem încrezători în Domnul că faceți și veți continua să faceți lucrurile pe care le poruncim. 5Domnul să vă îndrepte inimile către dragostea lui Dumnezeu și răbdarea lui Cristos!

Împotriva leneviei

6Vă poruncim, fraților, în Numele Domnului nostru Isus Cristos, să vă îndepărtați de orice frate care umblă în neorânduială și nu după tradiția6 Din nou uzul termenului tradiție se face în conotație pozitivă, cu referire la comportamentul, practica și învățăturile sănătoase lăsate de apostoli. pe care ați6 Unele mss conțin: au primit‑o. primit‑o de la noi! 7Căci voi înșivă știți cum trebuie să urmați exemplul nostru, fiindcă n‑am trăit în neorânduială între voi, 8nici n‑am mâncat fără plată pâinea nimănui, ci cu osteneală și muncă grea am lucrat zi și noapte, ca să nu fim o povară pentru niciunul dintre voi. 9Și aceasta nu pentru că n‑am fi avut acest drept, ci ca să fim un exemplu pe care să‑l urmați. 10Căci, când eram cu voi, v‑am dat această poruncă: „Dacă cineva nu vrea să lucreze, nici să nu mănânce!“

11Auzim însă că unii dintre voi umblă în neorânduială, nelucrând nimic, ci amestecându‑se în treburile altora. 12Unor astfel de oameni le poruncim și îi îndemnăm, în Domnul Isus Cristos, să‑și mănânce pâinea, lucrând în liniște. 13Însă voi, fraților, să nu obosiți făcând binele!

14Și dacă cineva nu ascultă cuvântul nostru din această scrisoare, însemnați‑vi‑l și să nu vă amestecați cu el, ca să‑i fie rușine! 15Să nu‑l priviți ca pe un dușman, ci mustrați‑l ca pe un frate.

Cuvinte de încheiere

16Însuși Domnul păcii să vă dea întotdeauna pacea în orice fel. Domnul să fie cu voi toți!

17Salutul este scris cu mâna mea: Pavel. Acesta este semnul în fiecare scrisoare de‑a mea; așa scriu eu.

18Harul Domnului Isus Cristos să fie cu voi toți! Amin.