1Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù,
wúrà dídára di àìdán!
Òkúta ibi mímọ́ wá túká
sí oríta gbogbo òpópó.
2Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye,
tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe
wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán
iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!
3Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn
fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn,
ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn
bí ògòǹgò ní aginjù.
4Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́
lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn;
àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ
Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.
5Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára
di òtòṣì ní òpópó.
Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀
ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.
6Ìjìyà àwọn ènìyàn mi
tóbi ju ti Sodomu lọ,
tí a sí ní ipò ní òjijì
láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.
7Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì,
wọ́n sì funfun ju wàrà lọ
wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa,
ìrísí wọn dàbí safire.
8Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú;
wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó.
Ara wọn hun mọ́ egungun;
ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.
9Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn
ju àwọn tí ìyàn pa;
tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò
fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.
10Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú
ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ
tí ó di oúnjẹ fún wọn
nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.
11Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀;
ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde.
Ó da iná ní Sioni
tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.
12Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́,
tàbí àwọn ènìyàn ayé,
wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ
odi ìlú Jerusalẹmu.
13Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì
àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà,
tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo
sílẹ̀ láàrín rẹ̀.
14Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó
bí ọkùnrin tí ó fọ́jú.
Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n
tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.
15“Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!” ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn.
“Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!”
Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé,
“Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́.”
16Olúwa ti tú wọn ká fúnrarẹ̀;
kò sí bojútó wọn mọ́.
Kò sí ọ̀wọ̀ fún olórí àlùfáà mọ́,
àti àánú fún àwọn àgbàgbà.
17Síwájú sí i, ojú wa kùnà
fún wíwo ìrànlọ́wọ́ asán;
láti orí ìṣọ́ wa ni à ń wò
fún orílẹ̀-èdè tí kò le gbà wá là.
18Wọ́n ń ṣọ́ wa kiri,
àwa kò sì le rìn ní òpópó wa mọ́.
Òpin wa ti súnmọ́, ọjọ́ wa sì níye
nítorí òpin wa ti dé.
19Àwọn tí ń lé wa yára
ju idì ojú ọ̀run lọ;
wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkè
wọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní aginjù.
20Ẹni ààmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa,
ni wọ́n fi tàkúté wọn mú.
Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀
ni àwa yóò máa gbé láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
21Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Edomu,
ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Usi.
Ṣùgbọ́n, a ó gbé ago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú;
ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòhò.
22Ìwọ ọmọbìnrin Sioni, ìjìyà rẹ yóò dópin;
kò ní mú ìgbèkùn rẹ pẹ́ mọ́.
Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Edomu, yóò jẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ní yà
yóò sì fi àìṣedéédéé rẹ hàn kedere.
Quatrième élégie : la déchéance de Sion
Le peuple est brisé
1Comment4.1 Autre traduction : hélas ! ! L’or s’est terni !
L’or pur s’est altéré !
Les pierres saintes4.1 Selon certains, des pierres précieuses qui avaient fait partie du trésor du Temple. Pour d’autres, un symbole du peuple de Dieu (voir v. 2). ╵ont été dispersées
à tous les coins de rues !
2Comment se fait-il donc ╵que les précieux fils de Sion
estimés comme de l’or fin
soient maintenant considérés ╵comme des pots d’argile,
ouvrages d’un potier4.2 Voir Jr 18 et 19. ?
3Regardez les chacals : ╵voyez comment les mères
allaitent leurs petits ╵en tendant leur mamelle.
La communauté de mon peuple ╵est devenue aussi cruelle
que les autruches du désert4.3 Sur l’autruche cruelle, voir Jb 39.14-16..
4La langue du bébé
s’attache à son palais, ╵tellement il a soif.
Les tout petits enfants ╵réclament quelque nourriture
et nul ne leur en donne.
5Ceux qui, auparavant, ╵mangeaient des mets exquis,
expirent dans les rues,
et ceux qui ont été ╵élevés dans la pourpre
se couchent maintenant ╵sur un tas de fumier.
6La communauté de mon peuple ╵a commis un péché
plus grand que celui de Sodome4.6 Sur Sodome, voir Gn 19.24-25 et Jr 23.14 ; 49.18 ; 50.40.
qui a été anéantie ╵en un instant,
et sans qu’un homme ╵porte la main contre elle4.6 Autre traduction : sans que quelqu’un se donne la peine de la secourir..
7Les princes de Sion, ╵ils étaient plus purs que la neige
et plus blancs que du lait,
leurs corps étaient vermeils ╵bien plus que le corail,
leurs veines de saphir.
8Leur aspect est plus sombre, ╵à présent, que la suie,
nul ne les reconnaît ╵maintenant dans les rues.
La peau leur colle aux os,
elle est devenue sèche ╵comme du bois.
9Les victimes du glaive ╵sont plus heureuses
que les victimes ╵de la famine :
celles-ci dépérissent, ╵tenaillées par la faim,
car les produits des champs ╵leur font défaut.
10De tendres femmes, ╵de leurs mains ont fait cuire
la chair de leurs enfants
pour s’en nourrir,
à cause du désastre ╵qui a atteint ╵la communauté de mon peuple4.10 Voir 2 R 6.28-29..
Le juste jugement de Dieu
11L’Eternel a assouvi son courroux.
Oui, il a déversé ╵son ardente colère,
il a allumé un feu dans Sion
qui en a consumé les fondations.
12Aucun roi de la terre
ni aucun habitant du monde ╵n’a cru que l’adversaire,
que l’ennemi, ╵pourrait franchir
les portes de Jérusalem.
13Cela est arrivé ╵à cause des péchés ╵de ses prophètes
et des fautes des prêtres
qui répandaient au milieu d’elle
le sang des justes.
14Mais maintenant, ╵ils errent dans les rues ╵tout comme des aveugles,
ils sont souillés de sang
si bien que l’on ne peut
toucher leurs vêtements.
15« Allez-vous en, impurs, ╵voilà ce qu’on leur crie.
Hors d’ici, hors d’ici, ╵et ne nous touchez pas ! »
Et lorsqu’ils fuient ainsi ╵en errant çà et là, ╵les gens des autres peuples disent :
« Qu’ils ne restent pas en ce lieu4.15 Voir Lv 13.45. ! »
16L’Eternel en personne ╵les a disséminés,
il ne veut plus les voir.
On n’a pas respecté les prêtres
ni eu d’égards ╵pour les responsables du peuple4.16 Autre traduction : les vieillards..
L’heure de l’abandon
17Nos yeux se consument encore
dans l’attente d’une aide, ╵mais c’est en vain.
De nos postes de guet ╵nous attendions une nation
qui ne nous a pas secourus4.17 Probablement l’Egypte (voir Jr 29.16 ; 37.5-10)..
18Nos ennemis épient ╵la trace de nos pas,
et nous ne pouvons plus ╵circuler dans nos rues,
notre fin est prochaine, ╵nos jours sont à leur terme.
Oui, notre fin arrive.
19Ceux qui nous poursuivaient ╵ont été plus rapides
que l’aigle dans le ciel.
Ils nous ont pourchassés ╵avec acharnement ╵sur les montagnes,
ils se sont embusqués ╵contre nous au désert.
20Le roi qui de la part de l’Eternel ╵avait reçu l’onction4.20 Il s’agit de Sédécias (2 R 25.1-6 ; Jr 39.4-7 ; 52.6-11)., ╵et dont dépendait notre vie,
a été capturé ╵grâce à leurs pièges,
alors que nous disions :
« Nous vivrons sous sa protection ╵au milieu des nations. »
21Tu peux être ravie, ╵communauté d’Edom, ╵et exulter4.21 Lorsque Jérusalem est tombée, les Edomites ont participé à son pillage (Ez 25.12-14).,
toi qui habites ╵au pays d’Outs4.21 Outs: pays à l’est du Jourdain, peut-être Edom, au sud-est de la mer Morte (Gn 36.28 ; voir Jb 1.1 et note). :
à toi aussi, ╵on passera la coupe,
tu seras enivrée ╵et tu te mettras toute nue.
22Ton châtiment aura sa fin, ╵ô communauté de Sion,
Dieu ne te déportera plus.
Communauté d’Edom, ╵il te fera payer tes fautes,
et il fera paraître ╵tes péchés au grand jour.