ምሳሌ 6 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ምሳሌ 6:1-35

ከተላላነት መራቅ

1ልጄ ሆይ፤ ለጎረቤትህ ዋስ ብትሆን፣

ስለ ሌላውም ሰው እጅ መትተህ ቃል ብትገባ፣

2በተናገርኸው ነገር ብትጠመድ፣

ከአፍህ በወጣውም ቃል ብትያዝ፣

3ልጄ ሆይ፤ ራስህን ለማዳን ይህን አድርግ፤

በጎረቤትህ እጅ ስለ ወደቅህ፣

ሄደህ ራስህን አዋርድ፤

ጎረቤትህን አጥብቀህ ነዝንዘው።

4ዐይኖችህ እንቅልፍ አይያዛቸው፣

ሽፋሽፍቶችህም አያንጐላጁ።

5ከዐዳኝ እጅ እንዳመለጠች ሚዳቋ፣

ከአጥማጅ ወጥመድ እንዳፈተለከች ወፍ ራስህን አድን።

6አንተ ታካች፤ ወደ ጕንዳን ሂድ፤

ዘዴውን አስተውለህ ጠቢብ ሁን፤

7አዛዥ የለውም፤

አለቃም ሆነ ገዥ የለውም፤

8ሆኖም ግን በበጋ ምግቡን ያከማቻል፤

በመከርም ወቅት ቀለቡን ይሰበስባል።

9አንተ ታካች፤ እስከ መቼ ትተኛለህ?

ከእንቅልፍህስ መቼ ትነሣለህ?

10ጥቂት ማንቀላፋት፤ ጥቂት ማንጐላጀት፤

እጅን አጣጥፎ “እስቲ ጥቂት ልረፍ” ማለት፤

11ድኽነት እንደ ወንበዴ፣

ዕጦትም መሣሪያ እንደ ታጠቀ ሰው6፥11 ወይም እንደ ቦዘኔ ወይም ዕጦት እንደ ለማኝ ከተፍ ይልብሃል።

12ወሮበላና ጨካኝ፣

ነውረኛ አንደበቱን ይዞ የሚዞር፣

13በዐይኑ የሚጠቅስ፣

በእግሩ ምልክት የሚሰጥ፣

በጣቶቹ የሚጠቍም፣

14በልቡ ተንኰል ክፋትን የሚያውጠነጥን፣

ምንጊዜም ጠብ ይጭራል።

15ስለዚህ በቅጽበት መዓት ይወርድበታል፤

በድንገት ይጠፋል፤ መዳኛም የለውም።

16እግዚአብሔር የሚጠላቸው ስድስት ነገሮች አሉ፤

የሚጸየፋቸውም ሰባት ናቸው፤ እነርሱም፦

17ትዕቢተኛ ዐይን፣

ሐሰተኛ ምላስ፣

ንጹሕ ደም የሚያፈስሱ እጆች፣

18ክፋትን የሚያውጠነጥን ልብ፣

ወደ ክፋት የሚቻኰሉ እግሮች፣

19በውሸት ላይ ውሸት የሚጨምር ሐሰተኛ ምስክር፣

በወንድማማቾች መካከል ጠብን የሚጭር ሰው።

ከዝሙት መራቅ

20ልጄ ሆይ፤ የአባትህን ትእዛዝ አክብር፤

የእናትህንም ትምህርት አትተው።

21ምንጊዜም በልብህ አኑራቸው፤

በዐንገትህም ዙሪያ እሰራቸው።

22በምትሄድበት ሁሉ ይመሩሃል፤

በምትተኛበት ጊዜ ይጠብቁሃል፤

በምትነቃበት ጊዜም ያነጋግሩሃል።

23እነዚህ ትእዛዞች መብራት ናቸውና፤

ይህችም ትምህርት ብርሃን፣

የተግሣጽ ዕርምትም የሕይወት መንገድ ናት፤

24እርሷም ከምግባረ ብልሹ ሴት፣

ልዝብ አንደበት ካላት ዘልዛላ ሴት ትጠብቅሃለች።

25ውበቷን በልብህ አትመኝ፤

በዐይኗም አትጠመድ፤

26ጋለሞታ ሴት ቍራሽ እንጀራ ታሳጣሃለችና፤

አመንዝራዪቱም በሕይወትህ በራሱ ላይ ትሸምቃለች።

27ለመሆኑ ልብሱ ሳይቃጠል፣

በጕያው እሳት መያዝ የሚችል ሰው አለን?

28አንድ ሰው እግሮቹ ሳይቃጠሉ፣

በፍም ላይ መሄድ ይችላልን?

29ከሰው ሚስት ጋር የሚተኛም እንደዚሁ ነው፤

የሚደርስባትም ከቅጣት አያመልጥም።

30ሌባ በተራበ ጊዜ ራቡን ለማስታገሥ ቢሰርቅ፣

ሰዎች አይንቁትም።

31በቤቱ ያለውን ሀብት ሁሉ የሚጠይቀው ቢሆንም፣

ከተያዘ ሰባት ዕጥፍ መክፈል አለበት።

32የሚያመነዝር ሰው ግን ማመዛዘን ይጐድለዋል፤

እንዲህ የሚያደርግ ሁሉ ራሱን ያጠፋል።

33መደብደብና ውርደት ዕጣው ነው፤

ኀፍረቱም ከቶ አይወገድም፤

34ቅናት የባልን ቍጣ ይቀሰቅሳልና፤

በሚበቀልበትም ጊዜ ምሕረት አያደርግም።

35ምንም ዐይነት ካሳ አይቀበልም፤

የቱንም ያህል ብዙ ቢሆን መማለጃን እሺ አይልም።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 6:1-35

Ìkìlọ̀ láti ṣọ́ra fún ìwà òmùgọ̀

1Ọmọ mi, bí ìwọ bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ,

bí ìwọ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún àjèjì ènìyàn,

2bí a bá ti fi ọ̀rọ̀ tí ó sọ dẹkùn mú ọ,

tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ ti kó ọ sí pàkúté,

3Nígbà náà, ṣe èyí, ìwọ ọmọ mi, láti gba ara rẹ

níwọ̀n bí o ti kó ṣọ́wọ́ aládùúgbò rẹ:

lọ kí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀;

bẹ aládùúgbò rẹ dáradára

4Má ṣe jẹ́ kí oorun kí ó kùn ọ́,

tàbí kí o tilẹ̀ tòògbé rárá.

5Gba ara rẹ sílẹ̀, bí abo èsúró kúrò lọ́wọ́ ọdẹ,

bí ẹyẹ kúrò nínú okùn àwọn pẹyẹpẹyẹ.

6Tọ èèrà lọ, ìwọ ọ̀lẹ

kíyèsi ìṣe rẹ̀, kí o sì gbọ́n!

7Kò ní olùdarí,

kò sí alábojútó tàbí ọba,

8síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjò

yóò sì kó oúnjẹ rẹ̀ jọ ní àsìkò ìkórè.

9Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ?

Nígbà wo ni ìwọ yóò jí kúrò lójú oorun rẹ?

10Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,

ìkáwọ́gbera láti sinmi díẹ̀

11Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣà

àti àìní bí adigunjalè.

12Ènìyànkénìyàn àti ènìyàn búburú,

tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,

13tí ó ń ṣẹ́jú pàkòpàkò,

ó ń fi ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀rọ̀

ó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,

14tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀

ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.

15Nítorí náà ìdààmú yóò dé bá a ní ìṣẹ́jú akàn;

yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.

16Àwọn ohun mẹ́fà wà tí Olúwa kórìíra,

ohun méje ní ó jẹ́ ìríra sí i:

17Ojú ìgbéraga,

Ahọ́n tó ń parọ́

ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,

18ọkàn tí ń pète ohun búburú,

ẹsẹ̀ tí ó yára láti sáré sínú ìwà ìkà,

19Ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nu

àti ènìyàn tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrín àwọn ọmọ ìyá kan.

Ìkìlọ̀ nítorí àgbèrè

20Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́

má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.

21Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláé

so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ

22Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ;

nígbà tí ìwọ bá sùn, wọn yóò máa ṣe olùṣọ́ rẹ;

nígbà tí o bá jí, wọn yóò bá ọ sọ̀rọ̀.

23Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ fìtílà,

ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ìmọ́lẹ̀,

àti ìtọ́nisọ́nà ti ìbáwí

ni ọ̀nà sí ìyè.

24Yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin búburú,

kúrò lọ́wọ́ ẹnu dídùn obìnrin àjèjì.

25Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹ

tàbí kí o jẹ́ kí ó fi ojú rẹ̀ fà ọ́ mọ́ra.

26Nítorí pé nípasẹ̀ àgbèrè obìnrin ni ènìyàn fi ń di oníṣù-àkàrà kan,

ṣùgbọ́n àyà ènìyàn a máa wá ìyè rẹ̀ dáradára.

27Ǹjẹ́ ọkùnrin ha le è gbé iná lé orí itan

kí aṣọ rẹ̀ má sì jóná?

28Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná?

Kí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì má jóná?

29Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya;

kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láìjìyà.

30Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalè

nítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.

31Síbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méje

bí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.

32Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè kò nírònú;

ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ó ń pa ara rẹ̀ run ni

33Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀,

ẹ̀gàn rẹ̀ kì yóò sì kúrò láéláé.

34Nítorí owú yóò ru ìbínú ọkọ sókè,

kì yóò sì ṣàánú nígbà tí ó bá ń gbẹ̀san.

35Kò nígbà nǹkan kan bí ohun ìtánràn;

yóò kọ àbẹ̀tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó.