ሚክያስ 5 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ሚክያስ 5:1-15

ከቤተ ልሔም ገዥ እንደሚመጣ የተሰጠ ተስፋ

1አንቺ የጭፍሮች ከተማ ሆይ፤

ጭፍሮችሽን አሰልፊ5፥1 ወይም አንቺ የተቀጠርሽ ከተማ ሆይ፤ ቅጥርሽን አጥብቂ

ከበባ ተደርጎብናልና።

የእስራኤልን ገዥ፣

ጕንጩን በበትር ይመቱታል።

2“አንቺ ግን፣ ቤተ ልሔም ኤፍራታ ሆይ፤

ከይሁዳ ነገዶች5፥2 ወይም ገዦች መካከል ትንሿ ብትሆኚም፣

አመጣጡ ከጥንት፣5፥2 ወይም ከቀድሞ ቀናት

ከቀድሞ ዘመን5፥2 ዕብራይስጡ አወጣጡ ይላል ወይም ከዘላለም የሆነ የሆነ፣

የእስራኤል ገዥ፣

ከአንቺ ይወጣልኛል።”

3ስለዚህ ወላዲቱ አምጣ እስክትገላገል ድረስ፣

እስራኤል ትተዋለች፤

የተቀሩት ወንድሞቹም፣

ተመልሰው ከእስራኤላውያን ጋር ይቀላቀላሉ።

4በእግዚአብሔር ኀይል፣

በአምላኩ በእግዚአብሔር ስም ታላቅነት፣

ጸንቶ ይቆማል፤ መንጋውንም ይጠብቃል።

በዚያን ጊዜ ኀያልነቱ እስከ ምድር ዳርቻ ስለሚደርስ፣

ተደላድለው ይኖራሉ።

5እርሱም ሰላማቸው ይሆናል።

ትድግናና ጥፋት

አሦራዊ ምድራችንን ሲወርር፣

ምሽጎቻችንንም ጥሶ ሲገባ፣

ሰባት እረኞችን፣

እንዲያውም ስምንት አለቆችን እናስነሣበታለን።

6የአሦርን ምድር በሰይፍ፣

የናምሩድን ምድር5፥6 ወይም ናምሩድን በመግቢያው በር በተመዘዘ ሰይፍ ይገዛሉ5፥6 ወይም ያፈርሳሉ

አሦራዊው ምድራችንን ሲወርር፣

ዳር ድንበራችንን ሲደፍር፣

እርሱ ነጻ ያወጣናል።

7የያዕቆብ ትሩፍ፣

በብዙ አሕዛብ መካከል

ከእግዚአብሔር ዘንድ እንደሚወርድ ጠል፣

በሣር ላይ እንደሚጥል ካፊያ፣

ሰውን እንደማይጠብቅ፣

የሰውንም ልጆች ተስፋ እንደማያደርግ ሰው ይሆናል።

8በዱር አራዊት መካከል እንዳለ አንበሳ፣

በእግሩ እየጨፈላለቀ እንደሚሄድ፣

የሰበረውን ማንም ሊነጥቀው እንደማይችል፣

በበግ መንጋ መካከል እንዳለ፣

እንደ ደቦል አንበሳ ሁሉ፣

የያዕቆብም ትሩፍ፣ በአሕዛብ ዘንድ፣ በብዙም ሕዝብ መካከል እንደዚሁ ይሆናል።

9እጅህ በጠላቶችህ ላይ በድል አድራጊነት ከፍ ከፍ ትላለች፤

ጠላቶችህም ሁሉ ይጠፋሉ።

10“በዚያን ጊዜ” ይላል እግዚአብሔር

“ፈረሶቻችሁን ከመካከላችሁ አጠፋለሁ፤

ሠረገሎቻችሁን እደመስሳለሁ።

11የምድራችሁን ከተሞች እደመስሳለሁ፤

ምሽጎቻችሁንም ሁሉ አፈርሳለሁ።

12ጥንቈላችሁን አጠፋለሁ፤

ከእንግዲህም አታሟርቱም።

13የተቀረጹ ምስሎቻችሁን፣

የማምለኪያ ዐምዶቻችሁንም ከመካከላችሁ አጠፋለሁ፤

ከእንግዲህ ለእጃችሁ ሥራ

አትሰግዱም።

14የአሼራ ምስልን ዐምድ5፥14 አሼራ የተባለችው አምላክ ትእምርት ነው። ከመካከላችሁ እነቅላለሁ፤

ከተሞቻችሁንም እደመስሳለሁ።

15ያልታዘዙኝን አሕዛብ፣

በቍጣና በመዓት እበቀላቸዋለሁ።”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 5:1-15

Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Olùgbàlà láti Bẹtilẹhẹmu

1Nísinsin yìí, kó àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ jọ,

ìwọ ìlú ti o ni ọmọ-ogun,

nítorí ó ti fi gbógun dó tì wá.

Wọn yóò fi ọ̀pá lu àwọn alákòóso Israẹli ní ẹ̀rẹ̀kẹ́.

2“Ṣùgbọ́n ìwọ, Bẹtilẹhẹmu Efrata,

bí ìwọ ti jẹ́ kékeré láàrín àwọn ẹ̀yà Juda,

nínú rẹ ni ẹni tí yóò jẹ́ olórí ní Israẹli

yóò ti jáde tọ̀ mí wá,

ìjáde lọ rẹ̀ sì jẹ́ láti ìgbà àtijọ́,

láti ìgbà láéláé.”

3Nítorí náà Israẹli yóò di kíkọ̀sílẹ̀ pátápátá

títí di àkókò tí ẹni tí ń rọbí yóò fi bí,

àti àwọn ìyókù arákùnrin rẹ̀ yóò fi padà

láti darapọ̀ mọ́ àwọn Israẹli.

4Òun yóò sì dúró,

yóò sì máa ṣe olùṣọ́-àgùntàn àwọn agbo ẹran rẹ̀ ní agbára Olúwa,

ní ọláńlá orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.

Wọn yóò sì wà láìléwu,

nítorí nísinsin yìí ni títóbi rẹ

yóò sì dé òpin ayé.

Ìgbàlà àti ìparun

5Òun yóò sì jẹ́ àlàáfíà wọn.

Nígbà tí àwọn Asiria bá gbógun sí ilẹ̀ wa

tí wọ́n sì ń yan lórí odi alágbára wa,

nígbà náà ni a ó gbé olùṣọ́-àgùntàn méje dìde sí i,

àti olórí ènìyàn mẹ́jọ.

6Wọn yóò sì fi idà pa ilẹ̀ Asiria run,

àti ilẹ̀ Nimrodu pẹ̀lú idà tí a fà.

Òun yóò sì gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Asiria

nígbà tí wọn bá gbógun ti ilẹ̀ wa

tí wọ́n sì tún yan wọ ẹnu-bodè wa.

7Ìyókù Jakọbu yóò sì wà

láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn

bí ìrì láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa,

bí ọ̀wààrà òjò lórí koríko,

tí kò gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn

tàbí kò dúró de àwọn ọmọ ènìyàn.

8Ìyókù Jakọbu yóò sì wà láàrín àwọn aláìkọlà

ní àárín àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn,

bí i kìnnìún láàrín àwọn ẹranko inú igbó,

bí i ọmọ kìnnìún láàrín agbo àgùntàn,

èyí tí ó máa ń fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,

tí ó sì máa ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀,

tí kò sì ṣí ẹnìkan tí ó lè gbà á là.

9A ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀,

gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sì ni a ó parun.

10“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,

“Èmi yóò pa àwọn ẹṣin rẹ̀ run kúrò láàrín rẹ

èmi yóò sì pa àwọn kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ run.

11Èmi yóò sì pa ilẹ̀ ìlú ńlá rẹ̀ run,

èmi ó sì fa gbogbo ibi gíga rẹ̀ ya.

12Èmi yóò gé ìwà àjẹ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ̀,

ìwọ kì yóò sì ní aláfọ̀ṣẹ mọ́.

13Èmi yóò pa àwọn ère fínfín rẹ̀ run,

àti ọwọ́n rẹ̀ kúrò láàrín rẹ̀;

ìwọ kì yóò sì le è foríbalẹ̀

fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ mọ́.

14Èmi yóò fa ère Aṣerah tu kúrò láàrín rẹ̀,

èmi yóò sì pa ìlú ńlá rẹ̀ run.

15Èmi yóò gbẹ̀san ní ìbínú àti ìrunú

lórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò ti tẹríba fún mi.”