መዝሙር 22 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

መዝሙር 22:1-31

መዝሙር 22

የጻድቅ ሰው መከራና ተስፋ

ለመዘምራን አለቃ፤ “በንጋት አጋዘን” ዜማ የሚዜም፤ የዳዊት መዝሙር።

1አምላኬ፣ አምላኬ ለምን ተውኸኝ?

እኔን ከማዳን፣

ከመቃተቴም ቃል ለምን ራቅህ?

2አምላኬ ሆይ፤ በቀን ወደ አንተ ጮኻለሁ፤

አንተ ግን አልመለስህልኝም፤

በሌሊት እንኳ አላረፍሁም።

3አንተ ግን ቅዱሱ ነጋሢ፤22፥3 ወይም አንተ ግን ቅዱስ ነህ፤ በእስራኤል ምስጋና ላይ በዙፋን ተቀምጠሃል

የእስራኤልም ምስጋና ነህ።

4አባቶቻችን በአንተ ታመኑ፤

ተማመኑብህ፤ አንተም ታደግሃቸው።

5ወደ አንተ ጮኹ፤ ዳኑም፤

በአንተም ታመኑ፤ አላፈሩም።

6እኔ ግን ትል እንጂ ሰው አይደለሁም፤

ሰው ያላገጠብኝ፣ ሕዝብም የናቀኝ ነኝ።

7የሚያዩኝ ሁሉ ይሣለቁብኛል፤

ራሳቸውንም እየነቀነቁ እንዲህ እያሉ ይዘልፉኛል፤

8በእግዚአብሔር ተማምኗል፤

እንግዲህ እርሱ ያድነው፤

ደስ የተሰኘበትን፣

እስቲ ይታደገው።”

9አንተ ግን ከማሕፀን አወጣኸኝ፤

በእናቴም ጡት ሳለሁ፣ መታመኛ ሆንኸኝ።

10ከማሕፀን ስወጣም በአንተ ላይ ተጣልሁ፤

ከእናቴ ሆድ ጀምሮም አንተ አምላኬ ነህ።

11መከራ እየተቃረበ ነውና፣

የሚረዳኝም የለምና፣

ከእኔ አትራቅ።

12ብዙ ኰርማዎች ከበቡኝ፤

ኀይለኛ የባሳን በሬዎችም ዙሪያዬን ቆሙ።

13እንደሚነጥቅና እንደሚያገሣ አንበሳ፣

አፋቸውን ከፈቱብኝ።

14እንደ ውሃ ፈሰስሁ፤

ዐጥንቶቼም ሁሉ ከመጋጠሚያቸው ወለቁ፤

ልቤ እንደ ሰም ሆነ፤

በውስጤም ቀለጠ።

15ጕልበቴ እንደ ገል ደረቀ፤

ምላሴ ከላንቃዬ ጋር ተጣበቀ፤

ወደ ሞት ዐፈርም አወረድኸኝ።22፥15 ወይም …ዐፈር ውስጥ ተኛሁኝ

16ውሾች ከበቡኝ፤

የክፉዎች ሸንጎ በዙሪያዬ ተሰልፏል፤

እጆቼንና እግሮቼንም ቸነከሩኝ።22፥16 አንዳንድ የዕብራይስጥ የጥንት ቅጆች፣ ሰብዓ ሊቃናትና ሱርስት እንዲሁ ሲሆኑ፣ አብዛኛዎቹ የዕብራይስጥ የጥንት ቅጆች እንደ አንበሳ ይላሉ።

17ዐጥንቶቼን ሁሉ አንድ በአንድ መቍጠር እችላለሁ፤

እነርሱም አፍጥጠው ይመለከቱኛል።

18ልብሶቼን ተከፋፈሉ፤

በእጀ ጠባቤም ላይ ዕጣ ተጣጣሉ።

19አንተ ግን፣ እግዚአብሔር ሆይ፤ ከእኔ አትራቅ፤

ዐጋዤ ሆይ፤ እኔን ለመርዳት ፍጠን።

20ነፍሴን ከሰይፍ ታደጋት፤

ውድ ሕይወቴንም ከውሾች ጡጫ አድናት።

21ከአንበሶች አፍ አድነኝ፤

ከአውራሪስ ቀንድም ታደገኝ።22፥21 ወይም ሰምተኸኛል

22ስምህን ለወንድሞቼ እነግራለሁ፤

በጉባኤም መካከል አመሰግንሃለሁ።

23እናንተ እግዚአብሔርን የምትፈሩ፤

አወድሱት፤

እናንተ የያቆብ ዘር ሁላችሁ፤ አክብሩት፤

የእስራኤልም ዘር ሁላችሁ፤ እርሱን ፍሩት።

24እርሱ የተጨነቀውን ሰው ጭንቀት፣

አልናቀም፤ ቸልም አላለምና፤

ፊቱንም ከእርሱ አልሰወረም፤

ነገር ግን ድረስልኝ ብሎ ሲጮኽ ሰማው።

25በታላቅ ጉባኤ የማቀርበው ምስጋናዬ ከአንተ የመጣ ነው፤

እርሱን በሚፈሩት22፥25 ዕብራይስጡ እኔ በሚፈሩኝ ይላል። ፊት ስእለቴን እፈጽማለሁ።

26ምስኪኖች በልተው ይጠግባሉ፤

እግዚአብሔርን የሚሹትም ያመሰግኑታል፤

ልባችሁም ለዘላለም ሕያው ይሁን!

27የምድር ዳርቻዎች ሁሉ ያስታውሳሉ፤

ወደ እግዚአብሔርም ይመለሳሉ፤

የሕዝቦች ነገዶች ሁሉ፣

በፊቱ ይሰግዳሉ።

28መንግሥት የእግዚአብሔር ናትና፤

ሕዝቦችንም የሚገዛ እርሱ ነው።

29የምድር ከበርቴዎች ይበላሉ፤

ይሰግዱለታልም፤

ነፍሱን በሕይወት ማቈየት የማይችለው፣ ወደ ዐፈር

ተመላሽ የሆነው ሁሉ በፊቱ ይንበረከካል።

30የኋለኛው ትውልድ ያገለግለዋል፤

ለመጪው ትውልድ ስለ ጌታ ይነገረዋል።

31ገና ላልተወለደ ሕዝብ፣

ጽድቁን ይነግራሉ፤

እርሱ ይህን አድርጓልና።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 22:1-31

Saamu 22

Fún adarí orin. Tí ohùn orin “àgbọ̀nrín òwúrọ̀.” Saamu ti Dafidi.

122.1: Mt 27.46; Mk 15.34.Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀?

Èéṣe tí o fi jìnnà láti gbà mí là,

àní sí igbe ìkérora mi?

2Ọlọ́run mi, ní ọ̀sán gangan ni mo kígbe, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi ní ohùn:

àti ní òru èmi kò dákẹ́.

3Ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹni mímọ́ ni ìwọ;

ẹni tí ó tẹ ìyìn Israẹli dó;

4Àwọn baba ńlá wa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ;

wọ́n ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ìwọ sì gbà wọ́n.

5Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà;

ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, a kò sì dójútì wọ́n.

6Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́, kì í sì í ṣe ènìyàn;

mo di ẹlẹ́gàn àwọn ènìyàn, ẹlẹ́yà àwọn ènìyàn

7Gbogbo àwọn tí ó rí mí fi mí ṣe ẹlẹ́yà;

wọ́n yọ ètè ẹ̀gàn wọn sí mi, wọ́n sì ń mi orí wọn pé.

8“Ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé Olúwa;

jẹ́ kí Olúwa gbà á là.

Jẹ́ kí ó gbà á là,

nítorí pé, ó ní ayọ̀ nínú rẹ̀.”

9Síbẹ̀ ìwọ ni ó ti mú mi wá láti inú;

ìwọ ni ó mú mi wà láìléwu, nígbà tí mo rọ̀ mọ́ ọmú ìyá mi.

10Ìwọ ni a fi mí lé lọ́wọ́ láti inú ìyá mi wá,

nígbà tí ìyá mí sì ti bí mi, ìwọ ni Ọlọ́run mi.

11Má ṣe jìnnà sí mi,

nítorí pé ìyọnu súnmọ́ tòsí

kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò ṣe ìrànlọ́wọ́.

12Ọ̀pọ̀ akọ màlúù yí mi ká;

àwọn màlúù alágbára Baṣani rọ̀gbà yí mi ká.

13Wọ́n ya ẹnu wọn sì mi bí i kìnnìún tí ń dọdẹ kiri,

tí ń ké ramúramù.

14A dà mí jáde gẹ́gẹ́ bí omi,

gbogbo egungun mi ti yẹ̀ kúrò ní oríkèé rẹ̀.

Ọkàn mi sì dàbí i ìda;

tí ó yọ́ láàrín inú mi.

15Agbára mí ti gbẹ bí àpáàdì,

ahọ́n mí sì tilẹ̀ mọ́ párí ẹ̀rẹ̀kẹ́ ẹ mi;

ìwọ ti tẹ́ mi sínú eruku ikú.

16Àwọn ajá yí mi ká;

ìjọ àwọn ènìyàn ibi ti ká mi mọ́,

Wọ́n gún mi lọ́wọ́, wọ́n sì gún mi lẹ́sẹ̀

17Mo lè ka gbogbo àwọn egungun mi;

àwọn tìkára wọn ń wò, wọ́n dójú lé mi.

18Wọ́n pín aṣọ mi láàrín ara wọn

àní lórí aṣọ mi ni wọ́n ṣẹ́ gègé.

19Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, má ṣe jìnnà sí mi;

Háà! Olùrànlọ́wọ́ ọ̀ mi, yára wá fún àtìlẹ́yìn mi!

20Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ idà,

àní ẹ̀mí mi lọ́wọ́ agbára àwọn ajá.

21Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ kìnnìún;

Kí o sì gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ìwo àgbáǹréré.

22Èmi yóò kéde orúkọ rẹ láàrín arákùnrin àti arábìnrin mi;

nínú ìjọ ni èmi yóò máa yìn ọ́.

23Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ yìn ín!

Gbogbo ẹ̀yin ìran Jakọbu, ẹ fi ògo fún un!

Ẹ dìde fún un tẹ̀rù tẹ̀rù, ẹ̀yin irú-ọmọ Israẹli!

24Nítorí pé òun kò ṣátá, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíra

ìpọ́njú àwọn tí a ni lára;

kò sì fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún mi

ṣùgbọ́n ó gbọ́ nígbà tí mo ké pè é.

25Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìyìn mi yóò ti wá nínú àjọ ńlá;

ẹ̀jẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò san níwájú àwọn tí o bẹ̀rù rẹ̀

26tálákà yóò jẹ yóò sì yó;

àwọn tí n wá Olúwa yóò yin

jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ̀ wà láààyè títí ayérayé!

27Gbogbo òpin ayé ni yóò rántí

wọn yóò sì yípadà sí Olúwa,

àti gbogbo ìdílé orílẹ̀-èdè

ni wọn yóò jọ́sìn níwájú rẹ̀,

28Nítorí ìjọba ni ti Olúwa.

Òun ni ó ń pàṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè.

29Bẹ́ẹ̀ náà ni gbogbo àwọn olówó ayé wọn yóò ṣe àsè, wọn yóò sì sìn;

gbogbo àwọn tí ó wọ inú ilẹ̀ lọ yóò kúnlẹ̀ ní iwájú rẹ̀

àti ẹni tí kò lè pa ọkàn ara rẹ̀ mọ́ ni ààyè.

30Irú-ọmọ rẹ̀ yóò sìn ín;

a ó sọ fún àwọn ìran tí ń bọ̀ nípa Olúwa,

31Wọn yóò polongo òdodo rẹ̀

sí àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí,

wí pé, òun ni ó ṣe èyí.