መዝሙር 21 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

መዝሙር 21:1-13

መዝሙር 21

ምስጋና ስለ ንጉሡ

ለመዘምራን አለቃ፤ የዳዊት መዝሙር።

1እግዚአብሔር ሆይ፤ ንጉሥ በኀይልህ ደስ ይለዋል፤

በምትሰጠውም ድል እጅግ ሐሤት ያደርጋል።

2የልቡን መሻት ሰጠኸው፤

የከንፈሮቹንም ልመና አልከለከልኸውም። ሴላ

3መልካም በረከት ይዘህ በመንገዱ ላይ ጠብቀኸው፤

የንጹሕ ወርቅ ዘውድም በራሱ ላይ ደፋህለት።

4ሕይወትን ለመነህ፤

ረዥም ዘመናትንም እስከ ዘላለም ሰጠኸው።

5በአቀዳጀኸው ድል ክብሩ ታላቅ ሆነ፤

ክብርንና ሞገስን አጐናጸፍኸው።

6ዘላለማዊ በረከትን ሰጠኸው፤

ከአንተ ዘንድ በሚገኝ ፍሥሓም ደስ አሰኘኸው፤

7ንጉሡ በእግዚአብሔር ተማምኗልና፤

ከልዑልም ጽኑ ፍቅር የተነሣ፣

ከቆመበት አይናወጥም።

8እጅህ ጠላቶችህን ሁሉ ታገኛቸዋለች፤

ቀኝ እጅህም የሚጠሉህን ፈልጋ ትይዛለች።

9በምትገለጥበት ጊዜ፣

እሳት እንደሚንቀለቀልበት ምድጃ ታደርጋቸዋለህ፤

እግዚአብሔር በመዓቱ እንዳልነበሩ ያደርጋቸዋል፤

እሳቱም ሙጥጥ አድርጋ ትበላቸዋለች።

10ዘራቸውን ከምድር፣

ዘር ማንዘራቸውንም ከሰው ልጆች መካከል ታጠፋለህ።

11ክፋት ቢያስቡብህ፣

ተንኰል ቢወጥኑብህም አይሳካላቸውም፤

12በመጡበት ትመልሳቸዋለህና፤

ቀስትህንም በፊታቸው ላይ ታነጣጥራለህ።

13እግዚአብሔር ሆይ፤ በብርታትህ ከፍ ከፍ በል፤

ኀይልህን እናወድሳለን፤ እንዘምራለንም።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 21:1-13

Saamu 21

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.

1Háà! Olúwa, ọba yóò yọ̀ nínú agbára rẹ,

àti ní ìgbàlà rẹ, yóò ti yọ̀ pẹ́ tó!

2Nítorí pé ìwọ ti fi ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ fún un,

bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì dùn ún ní ìbéèrè ẹnu rẹ̀. Sela.

3Ìwọ ti fi àwọn ìbùkún oore kò ó ni ọ̀nà

ìwọ fi adé wúrà dé e ní orí.

4Ó béèrè fún ìyè, ìwọ sì fi fún un,

àní ọjọ́ gígùn títí ayérayé.

5Ògo rẹ̀ pọ̀ nípasẹ̀ ìṣẹ́gun tí o fi fún un;

ìwọ sì jẹ́ kí iyì ọláńlá rẹ̀ wà lára rẹ.

6Dájúdájú, ìwọ ti fi ìbùkún ayérayé fún un:

ìwọ sì mú inú rẹ̀ dùn pẹ̀lú ayọ̀ ojú u rẹ̀.

7Ọba ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa;

nípasẹ̀ ìfẹ́ Ọ̀gá-ògo tí kì í kùnà

kì yóò sípò padà.

8Ọwọ́ rẹ yóò wá gbogbo àwọn ọ̀tá a rẹ rí;

ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò wá àwọn tí o kórìíra rẹ rí.

9Nígbà tí ìwọ bá yọ

ìwọ yóò mú wọn dàbí iná ìléru.

Olúwa yóò gbé wọn mì nínú ìbínú rẹ̀,

àti pé iná rẹ̀ yóò jó wọn run.

10Ìwọ yóò pa ìrandíran wọn run kúrò lórí ilẹ̀,

àti irú-ọmọ wọn kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.

11Bí o tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n ro èrò ibi sí ọ

wọ́n sì ń pète ìwà ìkà, wọn kì yóò ṣe àṣeyọrí.

12Nítorí pé ìwọ yóò mú wọn yí ẹ̀yìn wọn padà

nígbà tí o bá pinnu láti ta wọ́n ní ọfà.

13Gbígbéga ni ọ́ Olúwa, nínú agbára rẹ;

a ó kọrin, a ó yín agbára a rẹ̀.