箴言 2 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

箴言 2:1-22

智慧的益處

1孩子啊,

你若接受我的教誨,

珍愛我的誡命,

2側耳聆聽智慧,

傾心渴慕悟性;

3你若呼求洞見,

竭力追求悟性,

4尋它如尋銀子,

找它如找寶藏,

5你就會懂得敬畏耶和華,

認識上帝。

6因為耶和華賜人智慧,

知識和悟性出自祂的口。

7祂使正直人充滿智慧,

是行為純全者的盾牌。

8祂看守正義之路,

護衛虔誠人的道。

9這樣,你就明白何為仁義、

公平和正直,

懂得一切美善之道。

10因為智慧必進入你心,

知識必令你的靈歡快。

11明辨力必護佑你,

悟性必看顧你。

12智慧必救你遠離惡道,

脫離言語荒謬的人。

13他們捨棄正道,走上黑路,

14以行惡為樂,喜愛惡人的邪僻;

15他們的道路歪邪,行徑扭曲。

16智慧要救你脫離淫婦,

脫離花言巧語的妓女。

17她撇棄了年輕時的丈夫,

忘了在上帝面前立的約。

18她的家通向死亡,

她的路直達陰間。

19到她那裡的人都有去無回,

找不到生命之道。

20所以你要行善人的路,

守義人的道。

21因為在地上,

正直人必安居,

純全無過的人必長存,

22惡人必遭滅絕,

奸徒必被剷除。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 2:1-22

Èrè ìwà rere tí ọgbọ́n ń mú wá

1Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi,

tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,

2tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n

tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,

3àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn,

tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye

4bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà

tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.

5Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa,

ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.

6Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n,

láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá

7Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo,

Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,

8ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́

Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.

9Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́,

àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.

10Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ

ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ

11Ìmòye yóò pa ọ mọ́

òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.

12Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú,

lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,

13ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin

láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,

14ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú,

tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,

15ọ̀nà ẹni tí ó wọ́

tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.

16Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin,

àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,

17ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀

tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.

18Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú

ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.

19Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà

bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.

20Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere

kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.

21Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà

àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.

22Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà

a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.