彌迦書 5 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

彌迦書 5:1-15

耶和華的應許

1耶路撒冷的居民5·1 耶路撒冷的居民」希伯來文是「被圍攻的女子」。啊,

現在你們要調集軍隊!

敵人正四面圍攻我們,

要用杖擊打以色列首領的臉頰。

2以法他伯利恆啊,

你在猶大各城中毫不起眼,

但將有一位從你那裡出來,

為我統治以色列

祂的根源自亙古,來自太初。

3耶和華要將以色列人交給他們的敵人,

直到那臨盆的婦人生下兒子。

那時,祂流亡的弟兄將重返他們的以色列同胞那裡。

4祂要挺身而起,

倚靠耶和華的能力,

奉祂上帝耶和華的威名牧養祂的群羊。

他們將安然居住,

因為那時祂必受尊崇,直達地極。

5祂必給他們帶來平安!

亞述人侵略我們的國土、踐踏我們的宮殿時,

我們將選立七位牧者和八位首領抗擊他們。

6他們要用刀劍統治亞述,統治寧錄地區。

亞述人侵入我們國境、踐踏我們疆土時,

祂必拯救我們。

7雅各餘剩的子孫將在萬民中像從耶和華那裡降下的雨露,

又像灑在草上的甘霖。

他們不依靠人,

不冀望於世人。

8在各國各民中,

雅各餘剩的子孫猶如林間百獸中的獅子,

又像闖入羊群的猛獅,

將獵物撲倒撕碎,

無人能搭救。

9願你們伸手戰勝仇敵!

願你們的仇敵都被剷除!

10耶和華說:

「到那日,

我要消滅你們的戰馬,

毀壞你們的戰車。

11我要摧毀你們境內的城邑,

拆除你們所有的堡壘。

12我要除掉你們手中的巫術,

使你們那裡不再有占卜的。

13我要從你們中間除去雕刻的神像和神柱,

使你們不再跪拜自己所造的。

14我要從你們中間剷除亞舍拉神像,

毀滅你們的偶像。

15我要在烈怒中報應那些不聽從我的國家。」

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 5:1-15

Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Olùgbàlà láti Bẹtilẹhẹmu

1Nísinsin yìí, kó àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ jọ,

ìwọ ìlú ti o ni ọmọ-ogun,

nítorí ó ti fi gbógun dó tì wá.

Wọn yóò fi ọ̀pá lu àwọn alákòóso Israẹli ní ẹ̀rẹ̀kẹ́.

2“Ṣùgbọ́n ìwọ, Bẹtilẹhẹmu Efrata,

bí ìwọ ti jẹ́ kékeré láàrín àwọn ẹ̀yà Juda,

nínú rẹ ni ẹni tí yóò jẹ́ olórí ní Israẹli

yóò ti jáde tọ̀ mí wá,

ìjáde lọ rẹ̀ sì jẹ́ láti ìgbà àtijọ́,

láti ìgbà láéláé.”

3Nítorí náà Israẹli yóò di kíkọ̀sílẹ̀ pátápátá

títí di àkókò tí ẹni tí ń rọbí yóò fi bí,

àti àwọn ìyókù arákùnrin rẹ̀ yóò fi padà

láti darapọ̀ mọ́ àwọn Israẹli.

4Òun yóò sì dúró,

yóò sì máa ṣe olùṣọ́-àgùntàn àwọn agbo ẹran rẹ̀ ní agbára Olúwa,

ní ọláńlá orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.

Wọn yóò sì wà láìléwu,

nítorí nísinsin yìí ni títóbi rẹ

yóò sì dé òpin ayé.

Ìgbàlà àti ìparun

5Òun yóò sì jẹ́ àlàáfíà wọn.

Nígbà tí àwọn Asiria bá gbógun sí ilẹ̀ wa

tí wọ́n sì ń yan lórí odi alágbára wa,

nígbà náà ni a ó gbé olùṣọ́-àgùntàn méje dìde sí i,

àti olórí ènìyàn mẹ́jọ.

6Wọn yóò sì fi idà pa ilẹ̀ Asiria run,

àti ilẹ̀ Nimrodu pẹ̀lú idà tí a fà.

Òun yóò sì gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Asiria

nígbà tí wọn bá gbógun ti ilẹ̀ wa

tí wọ́n sì tún yan wọ ẹnu-bodè wa.

7Ìyókù Jakọbu yóò sì wà

láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn

bí ìrì láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa,

bí ọ̀wààrà òjò lórí koríko,

tí kò gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn

tàbí kò dúró de àwọn ọmọ ènìyàn.

8Ìyókù Jakọbu yóò sì wà láàrín àwọn aláìkọlà

ní àárín àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn,

bí i kìnnìún láàrín àwọn ẹranko inú igbó,

bí i ọmọ kìnnìún láàrín agbo àgùntàn,

èyí tí ó máa ń fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,

tí ó sì máa ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀,

tí kò sì ṣí ẹnìkan tí ó lè gbà á là.

9A ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀,

gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sì ni a ó parun.

10“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,

“Èmi yóò pa àwọn ẹṣin rẹ̀ run kúrò láàrín rẹ

èmi yóò sì pa àwọn kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ run.

11Èmi yóò sì pa ilẹ̀ ìlú ńlá rẹ̀ run,

èmi ó sì fa gbogbo ibi gíga rẹ̀ ya.

12Èmi yóò gé ìwà àjẹ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ̀,

ìwọ kì yóò sì ní aláfọ̀ṣẹ mọ́.

13Èmi yóò pa àwọn ère fínfín rẹ̀ run,

àti ọwọ́n rẹ̀ kúrò láàrín rẹ̀;

ìwọ kì yóò sì le è foríbalẹ̀

fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ mọ́.

14Èmi yóò fa ère Aṣerah tu kúrò láàrín rẹ̀,

èmi yóò sì pa ìlú ńlá rẹ̀ run.

15Èmi yóò gbẹ̀san ní ìbínú àti ìrunú

lórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò ti tẹríba fún mi.”