啟示錄 16 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

啟示錄 16:1-21

1我聽見殿中有宏亮的聲音對七位天使說:「去將那盛滿上帝烈怒的七個碗傾倒在地上。」

2第一位天使離去,將碗倒在了地上,那些有怪獸的印記、敬拜獸像的人身上長出奇痛無比的毒瘡。

3第二位天使將碗倒在了海洋裡,海水變得像死人的血,海中的活物都死光了。

4第三位天使將碗倒在了江河與水泉裡,水就變成了血。 5我聽見掌管各水源的天使說:

「昔在今在的聖者啊!

你是公義的,

因為你施行了審判。

6由於他們流了眾聖徒和先知們的血,

現在你使他們喝血,

這正是他們應得的報應。」

7我又聽見從祭壇發出的聲音說:

「是的,全能的主上帝,

你的判決真實公義。」

8第四位天使將碗倒在太陽上,太陽就變得炙熱如火,可以灼傷人。 9人們被炙熱灼傷,就褻瀆掌管這些災禍的上帝的名,他們毫無悔意,不肯歸榮耀給上帝。

10第五位天使將碗倒在那海中怪獸的座位上,牠的國便被黑暗籠罩,牠的國民痛苦難當,咬自己的舌頭。 11他們因為痛苦和毒瘡就褻瀆天上的上帝,不肯為自己的所作所為悔改。

12第六位天使將碗倒在幼發拉底大河上,河水立刻乾了,為東方各國的王預備了道路。 13我又看見三個像青蛙一樣的污鬼分別從巨龍、怪獸和假先知的口裡跳出來。 14其實牠們都是鬼魔的靈,能行奇蹟。牠們到普天下召集各王,預備在全能上帝的大日子來臨時聚集爭戰。

15「看啊!我要像賊一樣出其不意地來到。那警醒等候,看守自己衣裳,不致赤身行走蒙受羞辱的人有福了。」

16鬼魔把眾王召集到一個希伯來話叫哈米吉多頓的地方。

17第七位天使將碗倒在空中時,從殿裡的寶座上傳出響亮的聲音說:「成了!」 18隨後雷電交加,伴隨著巨響,還有空前劇烈的大地震。 19巴比倫大城裂作三段,其他各國的城邑也都倒塌了。上帝並沒有忘記巴比倫大城的罪惡,要把那杯盛滿祂烈怒的酒給她喝。 20海島都沉沒了,山嶺也都不見了, 21又有重達三十四公斤16·21 三十四公斤」希臘文是「一他連得」。的巨型冰雹從天而降,打在世人身上。世人無法忍受這極大的災禍,就褻瀆上帝。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ìfihàn 16:1-21

Àwọn ago ìbínú Ọlọ́run

116.1: Isa 66.6; Sm 69.24.Mo sì gbọ́ ohùn ńlá kan láti inú tẹmpili wá, ń wí fún àwọn angẹli, méje nì pé, “Ẹ lọ, ẹ sì tú ago ìbínú Ọlọ́run wọ̀n-ọn-nì sí orí ayé.”

216.2: Ek 9.10-11; De 28.35.Èkínní sì lọ, ó sì tú ago tirẹ̀ sí orílẹ̀ ayé: egbò kíkẹ̀ tí ó sì díbàjẹ́ sì dá àwọn ènìyàn tí ó ní ààmì ẹranko náà, àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ fún àwòrán rẹ̀.

316.3-4: Ek 7.17-21.Èkejì sì tú ago sínú Òkun; ó sì dàbí ẹ̀jẹ̀ òkú ènìyàn: gbogbo ọkàn alààyè sì kú nínú Òkun.

4Ẹ̀kẹta sì tú ago tirẹ̀ sínú odò, àti sí orísun àwọn omi; wọ́n sì di ẹ̀jẹ̀. 5Mo sì gbọ́ angẹli ti omi wí pé:

“Olódodo ni ìwọ Ẹni Mímọ́ ẹni tí ó ń bẹ,

tí ó sì ti wà,

nítorí tí ìwọ ṣe ìdájọ́ báyìí.

616.6: Sm 79.3.Nítorí tí wọ́n ti ta ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́ àti ti àwọn wòlíì sílẹ̀,

ìwọ sì fi ẹ̀jẹ̀ fún wọn mu; èyí yìí ní ó yẹ wọ́n.”

716.7: Sm 119.137.Mo sì gbọ́ ti pẹpẹ ń ké wí pé:

“Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa Ọlọ́run Olódùmarè,

òtítọ́ àti òdodo ní ìdájọ́ rẹ.”

8Ẹ̀kẹrin sì tú ago tirẹ̀ sórí oòrùn; a sì yọ̀ǹda fún un láti fi iná jó ènìyàn lára. 9A sì fi ooru ńlá jó àwọn ènìyàn lára, wọ́n sì sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Ọlọ́run, ẹni tí ó ní agbára lórí ìyọnu wọ̀nyí: wọn kò sì ronúpìwàdà láti fi ògo fún un.

1016.10: Ek 10.21.Ẹ̀karùnún sì tú ago tirẹ̀ sórí ìtẹ́ ẹranko náà; ilẹ̀ ọba rẹ̀ sì ṣókùnkùn; wọ́n sì ń gé ahọ́n wọn jẹ́ nítorí ìrora. 11Wọ́n sì sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run ọ̀run nítorí ìrora wọn àti nítorí egbò wọn, wọ́n kò sì ronúpìwàdà iṣẹ́ wọn.

1216.12: Isa 11.15-16.Ẹ̀kẹfà sì tu ìgò tirẹ̀ sórí odò ńlá Eufurate; omi rẹ̀ sì gbẹ, kí a lè pèsè ọ̀nà fún àwọn ọba láti ìlà-oòrùn wá. 1316.13: 1Ọb 22.21-23; Ek 8.3.Mo sì rí àwọn ẹ̀mí àìmọ́ mẹ́ta bí ọ̀pọ̀lọ́, wọ́n ti ẹnu dragoni náà àti ẹnu ẹranko náà àti ẹnu wòlíì èké náà jáde wá. 14Nítorí ẹ̀mí èṣù ni wọ́n, tí ń ṣe iṣẹ́ ìyanu, àwọn tí ń jáde lọ sọ́dọ̀ àwọn ọba gbogbo ilẹ̀ ayé, láti gbá wọn jọ sí ogun ọjọ́ ńlá Ọlọ́run Olódùmarè.

1516.15: 1Tẹ 5.2.“Kíyèsi i; ń bọ̀ bi olè, ìbùkún ni fún ẹni tí ń ṣọ́nà, tí ó sì ń pa aṣọ rẹ̀ mọ́, kí ó má bá a rìn ni ìhòhò, wọn a sì rí ìtìjú rẹ̀.”

1616.16: 2Ọb 9.27.Ó sì gbá wọn jọ́ sí ibìkan tí a ń pè ní Amagedoni ní èdè Heberu.

1716.17: Isa 66.6.Èkeje si tú ago tirẹ̀ sí ojú ọ̀run; ohùn ńlá kan sì ti inú tẹmpili jáde láti ibi ìtẹ́, wí pé, “Ó parí!” 1816.18: Ek 19.16; Da 12.1.Mọ̀nàmọ́ná sì kọ, a sì gbọ́ ohùn, àrá sì sán, ìṣẹ̀lẹ̀ ńlá sì ṣẹ̀, irú èyí tí kò ṣẹ̀ ri láti ìgbà tí ènìyàn ti wà lórí ilẹ̀, irú ìṣẹ̀lẹ̀ ńlá bẹ́ẹ̀, tí ó sì lágbára tó bẹ́ẹ̀. 19Ìlú ńlá náà sì pín sí ipa mẹ́ta, àwọn orílẹ̀-èdè sì ṣubú: Babeli ńlá sì wá sí ìrántí níwájú Ọlọ́run, láti fi ago ọtí wáìnì ti ìrunú ìbínú rẹ̀ fún un. 20Olúkúlùkù erékùṣù sì sálọ, a kò sì ri àwọn òkè ńlá mọ́. 2116.21: Ek 9.23.Yìnyín ńlá, tí ọ̀kọ̀ọ̀kan rẹ̀ tó tálẹ́ǹtì ní ìwọ̀n, sì bọ́ lù àwọn ènìyàn láti ọ̀run wà: Àwọn ènìyàn sì sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run nítorí ìyọnu yìnyín náà; nítorí tí ìyọnu rẹ̀ náà pọ̀ gidigidi.