對以色列和猶大的審判
1「祭司啊,要聽!
以色列家啊,要留心聽!
王室啊,要側耳聽!
這是對你們的審判,
因為你們像設在米斯巴的圈套,
鋪在他泊山的網羅。
2你們罪惡深重,
我要責罰你們。
3以法蓮做了妓女,我一清二楚;
以色列玷污了自己,也瞞不過我。」
4他們的惡行阻撓他們歸向自己的上帝,
邪淫之靈佔據了他們的心,
以致他們不認識耶和華。
5以色列被自己的傲慢指控,
以色列和以法蓮要跌倒在自己的罪中,
猶大也要一同跌倒。
6他們牽著牛羊去尋求耶和華,
卻尋不到,
因為祂已離他們而去。
7他們對耶和華不忠,
所生的是私生子,
他們和他們的田地必在朔日被吞噬。
8耶和華說:
「要在基比亞吹角,
在拉瑪鳴號,
在伯·亞文呐喊,
便雅憫啊,敵人就在你身後!
9以法蓮啊,你要在受懲罰的日子淪為廢墟!
我要在以色列各支派中宣告將來必要發生的事!
10猶大的首領如同擅移地界的人,
侵吞以色列的領土,
我要將烈怒如洪水般傾瀉在他們身上。
11以法蓮因甘願追隨偶像而受欺壓,
被審判壓碎。
12我要使以法蓮像蟲蛀的衣服,
使猶大家像朽爛的木頭。
13「以法蓮見自己患病,
猶大見自己有傷,
以法蓮便向強大的亞述王5·13 「強大的亞述王」或譯為「耶雷布王」,同10·6。求救。
亞述王卻不能醫病,也無法裹傷。
14我要像獅子一樣對待以法蓮,
如猛獅一樣對待猶大家,
將他們撕碎、拖走,
無人能營救他們。
15我要撇下他們,返回我的居所,
直到他們知罪來尋求我。
在苦難的日子裡,
他們必懇切地尋求我。」
Ìdájọ́ n bọ̀ lórí Israẹli àti Juda
1“Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yìn àlùfáà!
Ẹ fetísílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ Israẹli!
Ẹ gbọ́, ẹ̀yìn ilé ọba!
Ìdájọ́ yìí kàn yín:
Ẹ ti jẹ́ ẹ̀bìtì ní Mispa
àwọ̀n ti a nà sílẹ̀ lórí Tabori
2Àwọn ọlọ̀tẹ̀ ti gbilẹ̀ nínú ìpànìyàn
gbogbo wọn ni èmi ó bá wí,
3Mo mọ ohun gbogbo nípa Efraimu
Israẹli kò sì pamọ́ fún mi
Efraimu, ní báyìí ó ti ṣe àgbèrè
Israẹli sì ti díbàjẹ́.
4“Ìṣe wọn kò gbà wọ́n láààyè
láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wọn.
Ẹ̀mí àgbèrè wà ni ọkàn wọn,
wọn kò sì mọ Olúwa.
5Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí lé wọn;
Àwọn ọmọ Israẹli, àti Efraimu pàápàá kọsẹ̀ nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Juda náà sì kọsẹ̀ pẹ̀lú wọn.
6Nígbà tí wọ́n bá lọ pẹ̀lú agbo ẹran
àti ọ̀wọ́ ẹran wọn láti wá Olúwa,
wọn kò ní rí i,
ó ti yọ ara rẹ̀ kúrò láàrín wọn.
7Wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Olúwa
wọ́n sì bí àwọn àjèjì ọmọ.
Nísinsin yìí, ọdún oṣù tuntun wọn,
ni yóò pa wọn run pẹ̀lú ìpín wọn.
8“Fọn fèrè ní Gibeah,
kí ẹ sì fun ìpè ní Rama.
Ẹ pariwo ogun ní Beti-Afeni
máa wárìrì, ìwọ Benjamini.
9Efraimu yóò di ahoro
ní ọjọ́ ìbáwí
láàrín àwọn ẹ̀yà Israẹli
Mo sọ ohun tí ó dájú.
10Àwọn olórí Juda dàbí àwọn tí í
máa yí òkúta ààlà kúrò.
Èmi ó tú ìbínú gbígbóná mi lé
wọn lórí bí ìkún omi.
11A ni Efraimu lára,
A sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ìdájọ́
nítorí pé, ó pinnu láti tẹ̀lé òrìṣà
12Mo dàbí kòkòrò aṣọ sí Efraimu
Mo sì dàbí ìdin ara Juda.
13“Nígbà ti Efraimu ri àìsàn rẹ̀,
tí Juda sì rí ojú egbò rẹ̀
ni Efraimu bá tọ ará Asiria lọ,
ó sì ránṣẹ́ sí ọba ńlá náà fún ìrànlọ́wọ́
Ṣùgbọ́n kò le è wò ó sàn
bẹ́ẹ̀ ni kò le wo ojú egbò rẹ̀ jinná
14Nítorí pé, èmi ó dàbí kìnnìún sí Efraimu,
bí i kìnnìún ńlá sí ilé Juda.
Èmi ó fà wọ́n ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ èmi ó sì lọ;
Èmi ó gbé wọn lọ, láìsí ẹni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀.
15Nígbà náà ni èmi ó padà lọ sí ààyè mi
títí di ìgbà tí wọn ó fi gbà pé àwọn jẹ̀bi
wọn yóò sì wá ojú mi
nínú ìpọ́njú wọn, wọn ó fi ìtara wá mi.”