箴言 4 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

箴言 4:1-27

父亲的教诲

1孩子们啊,

你们要听从父亲的教诲,

留心学习,以便领悟,

2因为我给你们的训诲是美好的,

不可背弃我的教导。

3我年幼时在父亲身边,

是母亲唯一的宠儿。

4父亲教导我说:

“要牢记我的话,

遵守我的诫命,就必存活。

5你要寻求智慧和悟性,

不要忘记或违背我的吩咐。

6不可离弃智慧,智慧必护佑你;

你要热爱智慧,智慧必看顾你。

7智慧至上,要寻求智慧,

要不惜一切,求得悟性。

8高举智慧,她必使你受尊崇;

拥抱智慧,她必使你得尊荣。

9她必为你戴上华冠,

加上荣冕。”

10孩子啊,你要听从我的教导,

就必延年益寿。

11我已经指示你走智慧之道,

引导你行正确的路。

12你行走,必不受妨碍;

你奔跑,绝不会跌倒。

13你要持守教诲,不要松懈;

要守护好,因为那是你的生命。

14不要涉足恶人的道,

不要行走坏人的路;

15要避开,不可踏足,

要绕道而行。

16因为他们不作恶就无法入睡,

不绊倒人就无法安眠;

17他们吃的是邪恶饼,

喝的是残暴酒。

18义人的道路好像黎明的曙光,

越照越亮,直到大放光明。

19恶人的道路一片幽暗,

他们不知被何物绊倒。

20孩子啊,你要聆听我的吩咐,

侧耳听我的训言;

21不要让它们离开你的视线,

要牢记在心。

22因为得到它们就得到生命,

全身也必康健。

23要一丝不苟地守护你的心,

因为生命之泉从心中涌出。

24不讲欺诈之言,

不说荒谬的话。

25眼睛要正视前方,

双目要向前直看。

26要铺平脚下的路,

使所行之道稳妥。

27不可偏右偏左,

要远离恶事。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 4:1-27

Ọgbọ́n ni o ga jùlọ

1Tẹ́tí, Ẹ̀yin ọmọ mi, sí ẹ̀kọ́ baba; fetísílẹ̀ kí o sì ní òye sí i

2Mo fún ọ ní ẹ̀kọ́ tí ó yè kooro

Nítorí náà má ṣe kọ ẹ̀kọ́ mi sílẹ̀

3Nígbà tí mo jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin ní ilé baba à mí,

mo jẹ́ èwe, tí mo sì jẹ́ ọ̀kan ṣoṣo lọ́wọ́ ìyá mi

4Ó kọ́ mi ó sì wí pé

“Jẹ́ kí àyà rẹ kí ó gba ọ̀rọ̀ mi dúró,

pa òfin mi mọ́, kí ìwọ kí ó sì yè.

5Gba ọgbọ́n, gba òye,

Má ṣe gbàgbé ọ̀rọ̀ mi tàbí kí o yẹsẹ̀ kúrò nínú rẹ̀

6Má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀, yóò sì dáàbò bò ọ́,

fẹ́ràn rẹ̀, yóò sì bojútó ọ.

7Ọgbọ́n ni ó ga jù; nítorí náà gba ọgbọ́n.

Bí ó tilẹ̀ ná gbogbo ohun tí o ní, gba òye

8Gbé e ga, yóò sì gbé ọ ga

dìrọ̀ mọ́ ọn, yóò sì bu iyì fún ọ.

9Yóò fi òdòdó ọ̀ṣọ́ ẹwà sí orí rẹ

yóò sì fi adé ẹlẹ́wà fún ọ.”

10Tẹ́tí, ọmọ mi, gba ohun tí mo sọ,

Ọjọ́ ayé è rẹ yóò sì gùn.

11Mo tọ́ ọ ṣọ́nà ní ọ̀nà ti ọgbọ́n

mo sì mú ọ lọ ní ọ̀nà ti tààrà.

12Nígbà tí o rìn, ìgbésẹ̀ rẹ kò ní ní ìdíwọ́

nígbà tí o bá sáré, ìwọ kì yóò kọsẹ̀.

13Di ẹ̀kọ́ mú, má ṣe jẹ́ kí ó lọ;

tọ́jú u rẹ̀ dáradára nítorí òun ni ìyè rẹ.

14Má ṣe gbé ẹsẹ̀ rẹ sí ojú ọnà àwọn ènìyàn búburú

tàbí kí o rìn ní ọ̀nà àwọn ẹni ibi.

15Yẹra fún un, má ṣe rìn níbẹ̀;

yàgò fún un kí o sì bá ọ̀nà tìrẹ lọ

16Nítorí wọn kò le sùn àyàfi tí wọ́n bá ṣe ibi,

wọn kò ní tòògbé àyàfi tí wọ́n bá gbé ẹlòmíràn ṣubú

17Wọ́n ń jẹ oúnjẹ ìwà búburú

wọ́n sì ń mu wáìnì ìwà ìkà.

18Ipa ọ̀nà olódodo dàbí àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn

tí ń tànmọ́lẹ̀ sí i títí ọjọ́ fi kanrí

19ṣùgbọ́n ọ̀nà ènìyàn búburú dàbí òkùnkùn biribiri;

wọn kò mọ ohun tí ó ń mú wọn kọsẹ̀.

20Ọmọ mi, tẹ́tí sí ohun tí mo sọ;

fetísílẹ̀ dáradára sí ọ̀rọ̀ mi

21Má ṣe jẹ́ kí wọ́n rá mọ́ ọ lójú

pa wọ́n mọ́ sínú ọkàn rẹ;

22Nítorí ìyè ni wọ́n jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó rí wọn

àti ìlera fún gbogbo ara ènìyàn

23Ju gbogbo nǹkan tókù lọ, pa ọkàn rẹ mọ́

Nítorí òun ni orísun ìyè,

24Mú àrékérekè kúrò ní ẹnu rẹ;

sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ìsọkúsọ jìnnà réré sí ẹnu rẹ.

25Jẹ́ kí ojú rẹ máa wo iwájú,

jẹ́ kí ìwo ojú rẹ máa wo ọ̀kánkán iwájú rẹ sá á.

264.26: (Gk): Hb 12.13.Kíyèsi ìrìn ẹsẹ̀ rẹ

sì rìn ní àwọn ọ̀nà tí ó dára nìkan

27Má ṣe yà sọ́tùn ún tàbí sósì;

pa ẹsẹ̀ rẹ mọ́ kúrò nínú ibi.