箴言 3 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

箴言 3:1-35

信靠耶和华

1孩子啊,不要忘记我的训言,

要把我的诫命存在心里,

2因为这必使你延年益寿,

幸福平安。

3不要让慈爱和信实离开你,

要把他们系在你的颈项上,

刻在你的心坎上。

4这样,你必蒙上帝和世人的喜悦,

享有美誉。

5你要全心信靠耶和华,

不可倚靠自己的悟性。

6凡事都要寻求祂,

祂必指引你走正路。

7不要自以为有智慧,

要敬畏耶和华,远离恶事。

8这样可医治你的身体,

滋润你的筋骨。

9你要用自己的财富和一切初熟的物产来尊崇耶和华,

10祂必使你五谷满仓,

榨酒池溢出新酿。

11孩子啊,不可轻视耶和华的管教,

也不可厌烦祂的责备。

12因为耶和华责备祂所爱的人,

就像父亲责备他所疼爱的孩子。

13找到智慧、得到悟性的人有福了,

14因为智慧比银子更有价值,

比金子更有益处,

15比珠宝更珍贵;

你所喜爱的一切都难以相比。

16智慧的右手有长寿,

左手有富贵和尊荣。

17她的路上有福乐,

她的道上有平安。

18对持守智慧的人来说,

智慧是生命树,

紧握智慧的人必蒙祝福。

19耶和华以智慧奠立大地,

以悟性铺设诸天;

20祂的知识使深渊裂开,

使天上降下甘霖。

21孩子啊,你要守护智慧和明辨力,

别让她们离开你的视线。

22她们必给你带来生命,

作你颈项上华美的装饰。

23如此,你必步履稳健,不致失足;

24你必安然躺卧,睡得香甜。

25不要怕突来的灾祸,

不要怕恶人遭毁灭,

26因为耶和华是你的靠山,

祂使你的脚不陷入网罗。

27倘若有力量行善,

就当帮助有需要的人,不要推托。

28倘若可以帮忙,

就不可对有求于你的邻人说:

“回去吧,明天再来,我必给你!”

29邻舍在你附近安分居住,

不可谋害他。

30别人若没有害你,

不要无故与他相争。

31不要羡慕残暴之徒,

也不可步其后尘,

32因为耶和华憎恶邪僻之徒,

喜爱正直的人。

33耶和华咒诅恶人的家,

赐福义人的家。

34耶和华讥笑好讥诮的人,

恩待谦卑的人。

35智者得尊荣,

愚人受羞辱。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 3:1-35

Àwọn àǹfààní ọgbọ́n mìíràn

1Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi.

Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.

2Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà,

ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.

3Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé

so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ,

kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.

43.4: Ro 12.17.Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere

ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.

5Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ

má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ;

6Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ

òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.

73.7: Ro 12.16.Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ

bẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.

8Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ

àti okun fún àwọn egungun rẹ.

9Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa,

pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ

10Nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya

àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.

113.11,12: Hb 12.5,6.Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwa

má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,

12Nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí

bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.

13Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀,

ẹni tí ó tún ní òye sí i

14Nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ

ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.

15Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ;

kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.

16Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀;

ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.

17Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura,

òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.

18Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á;

àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.

19Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;

20Nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà,

àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.

21Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́,

má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.

22Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ,

àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.

23Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu,

ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀;

24Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù,

nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.

25Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì,

tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.

26Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ,

kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.

27Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ,

nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.

28Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé,

“Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,”

nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.

29Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ,

ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.

30Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí,

nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.

31Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan

tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.

32Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyídáyidà

ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.

33Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú,

ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.

343.34: (Gk): Jk 4.6; 1Pt 5.5.Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́,

ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.

35Ọlọ́gbọ́n jogún iyì,

ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.