尼希米记 6 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

尼希米记 6:1-19

敌人阴谋阻挠重建

1参巴拉多比雅阿拉伯基善和我们其余的敌人听说我已修完城墙,没有留下任何缺口——那时我还没有为城门安上门扇—— 2参巴拉基善就派人告诉我说:“来,我们在阿挪平原的一个村庄见面吧。”其实他们想要害我。 3我派人回复他们说:“我正在做一件大工程,不能下去见你们。我怎能停止工作下去见你们呢?” 4他们四次派人来告诉我,每次我都这样拒绝了。 5参巴拉第五次派人送来一封未封口的信, 6上面写着:“各国都在谣传,基善也说,你和犹太人计划谋反,因而才修建城墙,据说你要做他们的王。 7你还派先知在耶路撒冷指着你预言说,‘犹大有王了。’如今王必听到这些传闻。所以你还是来与我们一同商议吧。” 8我就派人答复他说:“你所说的并非事实,是你心里捏造的。” 9因为他们想恐吓我们,以为我们会吓得手发软,无法完成工程。但上帝啊,求你使我的手有力量!

10我到米希达别的孙子、第来雅的儿子示玛雅的家中,那时他正闭门不出。他对我说:“我们在上帝的殿里会面,要关上殿门,因为他们要来杀你,要在夜间杀你。” 11但我回答说:“像我这样的人岂能逃跑?岂能进入殿里保命?我决不进去。” 12我察觉上帝并没有差派他,他是被多比雅参巴拉收买才说预言攻击我的。 13他们收买他是为了恐吓我,使我依从他去犯罪,好毁坏我的名声、羞辱我。 14我的上帝啊,求你按照他们的行为报应多比雅参巴拉、女先知挪亚底及其他恐吓我的先知。

工程竣工

15以禄月6:15 以禄月”即希伯来历的六月,阳历是八月中旬到九月中旬。二十五日城墙竣工,前后用了五十二天。 16我们的敌人和周围各国听说后,都感到惧怕和气馁,因为他们知道这工作是在上帝的帮助下完成的。 17在那些日子,多比雅犹大贵族之间多有书信来往。 18犹大有很多人与多比雅结盟,因为他是亚拉的儿子示迦尼的女婿,他儿子约哈难又娶了比利迦的儿子米书兰的女儿为妻。 19他们常告诉我有关多比雅的善行,并把我的话告诉他。多比雅不断写信恐吓我。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 6:1-19

Àwọn ọ̀tá kò dáwọ́ àtakò dúró

1Nígbà tí Sanballati, Tobiah Geṣemu ará Arabia àti àwọn ọ̀tá wa tókù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́kù nínú rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì ri àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà. 2Sanballati àti Geṣemu rán iṣẹ́ yìí sí mi pé: “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ono.”

Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbèrò láti ṣe mí ní ibi; 3Bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé; “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?” 4Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.

5Ní ìgbà karùn-ún, Sanballati rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú àpò ìwé wà ní ọwọ́ rẹ̀ 6tí a kọ sínú un rẹ̀ pé:

“A ròyìn rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè—Geṣemu sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé—ìwọ àti àwọn Júù ń gbèrò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbèrò láti di ọba wọn 7àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jerusalẹmu: ‘ọba kan wà ní Juda!’ Nísinsin yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”

8Mo dá èsì yìí padà sí i pé: “Kò sí ohun kan nínú irú ohun tí ìwọ sọ tí ó ṣẹlẹ̀; ìwọ kàn rò wọ́n ní orí ara rẹ ni.”

9Gbogbo wọn múra láti dẹ́rùbà wá, wọ́n ń rò ó wí pé, “Ọwọ́ wọn kò ní ran iṣẹ́ náà, àti wí pé wọn kò ní parí rẹ̀.”

Ṣùgbọ́n mo gbàdúrà pé, “Nísinsin yìí Ọlọ́run fi agbára fún ọwọ́ mi.”

10Ní ọjọ́ kan mo lọ sí ilé Ṣemaiah ọmọ Delaiah, ọmọ Mehetabeeli, ẹni tí a há mọ́ sínú ilé rẹ̀. Ó wí pé, “Jẹ́ kí a pàdé ní ilé Ọlọ́run nínú tẹmpili, kí o sì jẹ́ kí a pa àwọn ìlẹ̀kùn tẹmpili dé, nítorí àwọn ènìyàn ń bọ̀ láti pa ọ́, ní òru ni wọn yóò wá láti pa ọ́.”

11Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí irú ènìyàn bí èmi sálọ? Tàbí kí ènìyàn bí èmi sálọ sínú tẹmpili láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là? Èmi kò ní lọ!” 12Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán an, ṣùgbọ́n ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tobiah àti Sanballati ti bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀. 13Wọ́n bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rùbà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.

14A! Ọlọ́run mi, rántí Tobiah àti Sanballati, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Noadiah wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbèrò láti dẹ́rùbà mí. 15Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Eluli (oṣù kẹsànán), láàrín ọjọ́ méjìléláàdọ́ta.

Píparí odi

16Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.

17Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́lá Juda ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tobiah, èsì láti ọ̀dọ̀ Tobiah sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn. 18Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Juda ti mulẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekaniah ọmọ Arah (Sanballati fẹ́ ọmọ Ṣekaniah), ọmọ rẹ̀ Jehohanani sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Meṣullamu ọmọ Berekiah 19Síwájú sí í, wọ́n túbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún un. Tobiah sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rùbà mí.