历代志上 14 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

历代志上 14:1-17

大卫的宫殿和家人

1泰尔希兰差遣使者带着香柏木、木匠和石匠去为大卫建造宫殿。 2那时,大卫知道耶和华已立他做以色列的王,并因自己以色列子民的缘故而使他国家兴旺。

3大卫耶路撒冷又娶了多位妻子,生了许多儿女。 4他在耶路撒冷所生的孩子有沙姆亚朔罢拿单所罗门5益辖以利书亚以法列6挪迦尼斐雅非亚7以利沙玛比利雅大以利法列

打败非利士人

8非利士人听说大卫已被膏立为以色列王,就全军出动搜寻大卫大卫得知后,便出来迎敌。 9非利士人前来袭击利乏音谷。 10大卫就求问上帝说:“我可以去迎战非利士人吗?你会把他们交在我手里吗?”耶和华说:“去吧,我必把他们交在你手里。”

11于是,大卫前往巴力·毗拉心,击败了非利士人。他说:“上帝借我的手击溃敌人,如洪水冲垮堤岸。”所以,那地方叫巴力·毗拉心14:11 巴力·毗拉心”意思是“冲垮之主”。12非利士人在那里丢弃了他们的神像,大卫命人把它们烧掉。 13非利士人又来袭击那山谷, 14大卫又求问上帝,上帝对他说:“你不要正面出击,要绕到他们后面,从桑林对面攻打他们。 15当你听见桑树梢上响起脚步声时,就要进攻,因为那表示耶和华已在你前头去攻击非利士的军队了。” 16大卫遵命而行,打败非利士人,从基遍一直杀到基色17于是,大卫名扬列国,耶和华使列国都惧怕他。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Kronika 14:1-17

Ilé àti ìdílé Dafidi

114.1,2: 2Sa 5.11,12.Nísinsin yìí Hiramu àti ọba Tire rán oníṣẹ́ sí Dafidi, àti pẹ̀lú igi kedari pẹ̀lú àwọn ọ̀mọ̀lé àti gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ààfin fún un. 2Dafidi sì mọ Israẹli àti pé Olúwa ti fi òun ṣe ọba lórí Israẹli àti pé ìjọba rẹ̀ ga jùlọ nítorí ti àwọn ènìyàn rẹ̀.

314.3-7: 1Ki 3.5-8; 2Sa 5.14-16.Ní Jerusalẹmu Dafidi mú ọ̀pọ̀ ìyàwó ó sì di baba àwọn ọmọ ọkùnrin púpọ̀ àti ọmọbìnrin. 4Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ náà tí wọ́n bí fún un níbẹ̀: Ṣammua, Ṣobabu, Natani, Solomoni, 5Ibhari, Eliṣua, Elifeleti, 6Noga, Nefegi, Jafia, 7Eliṣama, Beeliada, àti Elifeleti.

Dafidi ṣẹ́gun àwọn ará Filistini

814.8-12: 2Sa 5.17-21.Nígbà tí àwọn ará Filistini gbọ́ pé a ti fi ààmì òróró yàn Dafidi ní ọba lórí gbogbo Israẹli, wọ́n sì lọ sókè pẹ̀lú ipá láti wá a rí, ṣùgbọ́n Dafidi gbọ́ nípa rẹ̀ ó sì jáde lọ láti pàdé wọn. 9Nísinsin yìí àwọn ará Filistini ti wá láti gbógun ti Àfonífojì Refaimu; 10Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run wí pé: “Kí èmi kí ó gòkè tọ àwọn ará Filistini lọ bí? Ìwọ ó ha fi wọ́n lé mi lọ́wọ́?”

Olúwa sì wí fún un pé, “Gòkè lọ èmi ó sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́.”

11Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gòkè lọ sí Baali-Perasimu, níbẹ̀ ó sì kọlù wọ́n. Ó sí wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí omi tí ya jáde, Ọlọ́run ti ya Dafidi lórí àwọn ọ̀tá mi pẹ̀lú ọwọ́ mi.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń pè ibẹ̀ ní Baali-Perasimu. 12Àwọn ará Filistini sì ti fi àwọn òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀. Dafidi sì pa á láṣẹ láti jó wọn nínú iná.

1314.13-16: 2Sa 5.22-25.Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn ará Filistini gbógun wọ́n sì fọ́nká àfonífojì, 14Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì tún béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, Ọlọ́run sì dalóhùn pé, Má ṣe gòkè tààrà, ṣùgbọ́n ẹ yí wọn ká kí ẹ sì mú wọn níwájú igi muliberi. 15Tí ó bá sì ṣe, tí ẹ̀yin bá ti gbọ́ ìró ẹsẹ̀ ní orí òkè igi muliberi, ẹ jáde fún ogun, nítorí èyí yóò fihàn pé Ọlọ́run ti jáde níwájú rẹ láti kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini. 16Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ṣe ohun tí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini láti gbogbo ọ̀nà Gibeoni lọ sí Geseri.

17Bẹ́ẹ̀ ni òkìkí Dafidi tàn ká gbogbo ilẹ̀ káàkiri, Olúwa sì mú kí gbogbo orílẹ̀-èdè bẹ̀rù rẹ̀.