Salmernes Bog 3 – BPH & YCB

Bibelen på hverdagsdansk

Salmernes Bog 3:1-9

Tryghed hos Herren

1En sang af David, da han flygtede fra sin søn Absalom.

2Åh Herre, mine fjender er så mange,

de er alle imod mig, de gør mig bange.

3„Gud vil ikke redde ham!” siger de.

4Men Herren er mit skjold og min styrke,

han gav mig modet tilbage.

5Jeg råbte til ham om hjælp,

og han svarede mig fra sit hellige bjerg.

6Jeg lagde mig trygt til at sove,

for Herren skærmede mig med sin hånd.

7Jeg bliver ikke overmandet af frygt,

om så tusinder af fjender omringer mig.

8Men jeg råber til Herren:

„Grib ind, Herre! Red mig, Gud!”

Herren ydmyger alle mine fjender,

det er ham, der bryder de ondes magt.

9Han er den, som redder os.

Ja, velsign dit folk, Herre!

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 3:1-8

Saamu 3

Saamu ti Dafidi. Nígbà ti ó sá fún ọmọ rẹ̀ Absalomu.

1Olúwa, báwo ni àwọn ọ̀tá mi ṣe pọ̀ tó báyìí!

Báwo ni àwọn ti ó dìde sí mi ṣe pọ̀ tó!

2Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ń sọ ní ti tèmi, pé

“Ọlọ́run kò nígbà á là.” Sela.

3Ṣùgbọ́n ìwọ ni asà yí mi ká, Olúwa;

ìwọ fi ògo fún mi, ìwọ sì gbé orí mi sókè.

4Olúwa ni mo kígbe sókè sí,

ó sì dá mi lóhùn láti orí òkè mímọ́ rẹ̀ wá. Sela.

5Èmi dùbúlẹ̀, mo sì sùn;

mo sì tún padà jí, nítorí Olúwa ni ó ń gbé mi ró.

6Èmi kì yóò bẹ̀rù ẹgbẹgbẹ̀rún ènìyàn

tí wọ́n rọ̀gbà yí mi ká.

7Dìde, Olúwa!

Gbà mí, Ọlọ́run mi!

Lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní àgbọ̀n;

kí o sì ká eyín àwọn ènìyàn búburú.

8Láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìgbàlà ti wá.

Kí ìbùkún rẹ wà lórí àwọn ènìyàn rẹ. Sela.