Salmernes Bog 4 – BPH & YCB

Bibelen på hverdagsdansk

Salmernes Bog 4:1-9

At stole på Herren

1Til korlederen: Brug strengeinstrumenterne. En sang af David.

2Hør mig, Gud, når jeg råber om hjælp,

for du er en god Gud.

Du har hjulpet mig før,

når jeg var trængt op i en krog.

Vær nådig imod mig

og lyt til min bøn!

3I oprørske mennesker,

hvor længe vil I krænke min ære?

Hvor længe vil I stræbe efter falskhed

og foretrække løgn og bedrag?

4I må forstå, at Herren velsigner dem,

der trofast følger ham.

Han hører mit råb om hjælp,

han svarer, hver gang jeg kalder.

5Bliver I oprørte over noget, da synd ikke.

Tænk jer om, forhast jer ikke.

6Bring hellere ofre til Herrens ære

og sæt jeres lid til ham.

7Mange klager: „Hvorfor hjælper Gud os ikke?”

Herre, se i nåde til os.

8Mit hjerte glæder sig mere over dig

end over en rig høst af korn og vin.

9Jeg kan roligt lægge mig til at sove,

for du, Herre, beskytter mig.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 4:1-8

Saamu 4

Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu ti Dafidi.

1Dá mi lóhùn nígbà tí mo bá pè ọ́,

ìwọ Ọlọ́run òdodo mi,

Fún mi ní ìdáǹdè nínú ìpọ́njú mi;

ṣàánú fún mi, kí o sì gbọ́ àdúrà mi.

2Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, ẹ̀yin ọmọ ènìyàn, tí ẹ ó ṣe sọ ògo mi di ìtìjú?

Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, tí ẹ̀yin yóò ṣe fẹ́ràn ìtànjẹ àti tí ẹ̀yin yóò fi máa wá ọlọ́run èké?

3Ṣùgbọ́n kí ẹ mọ̀ pé, Olúwa ti ya ẹni olódodo sọ́tọ̀ fún ara rẹ̀;

Olúwa yóò gbọ́ nígbà tí mo bá pè é.

44.4: Ef 4.26.Ẹ bínú ẹ má ṣe ṣẹ̀;

Nígbà tí ẹ bá wà lórí ibùsùn yín,

ẹ bá ọkàn yín sọ̀rọ̀, kí ó sì dákẹ́ jẹ́.

5Ẹ rú ẹbọ òdodo

kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.

6Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ló ń béèrè pé, “Ta ni yóò ṣe rere fún wa?”

Olúwa, Jẹ́ kí ojú rẹ mọ́lẹ̀ sí wa lára,

7Ìwọ ti fi ayọ̀ púpọ̀ kún ọkàn mi

ju ìgbà tí hóró irúgbìn àti wáìnì tuntun wọ́n pọ̀ fún mi lọ.

8Èmi yóò dùbúlẹ̀, èmi ó sì sùn ní àlàáfíà,

nítorí ìwọ nìkan, Olúwa, ni o

mú mi gbé láìléwu.