Sekariah 8 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sekariah 8:1-23

Ọlọ́run ṣe ìpinnu láti bùkún Jerusalẹmu

1Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun si tún tọ́ mí wá.

2Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Owú ńláńlá ni mo jẹ fún Sioni, pẹ̀lú ìbínú ńláńlá ni mo fi jowú fún un.”

3Báyìí ni Olúwa wí: “Mo yípadà sí Sioni èmi ó sì gbé àárín Jerusalẹmu: Nígbà náà ni a ó sì pé Jerusalẹmu ni ìlú ńlá òtítọ́; àti òkè ńlá Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni a ó pè ní òkè ńlá mímọ́.”

4Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Arúgbó ọkùnrin, àti arúgbó obìnrin, yóò gbé ìgboro Jerusalẹmu, àti olúkúlùkù pẹ̀lú ọ̀pá ni ọwọ́ rẹ̀ fún ogbó. 5Ìgboro ìlú yóò sì kún fún ọmọdékùnrin, àti ọmọdébìnrin, tí ń ṣiré ní ìta wọn.”

6Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Bí ó bá ṣe ìyanu ní ojú ìyókù àwọn ènìyàn yìí ni ọjọ́ wọ̀nyí, ǹjẹ́ ó ha lè jẹ́ ìyanu ni ojú mi bí?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

7Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Kíyèsi i, èmi ó gba àwọn ènìyàn mi kúrò ni ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti kúrò ni ilẹ̀ ìwọ̀-oòrùn. 8Èmi ó sì mú wọn padà wá, wọn ó sì máa gbé àárín Jerusalẹmu. Wọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi, èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ní òtítọ́, àti ní òdodo.”

9Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Jẹ́ kí ọwọ́ yín le ẹ̀yin ti ń gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní ọjọ́ wọ̀nyí ni ẹnu àwọn wòlíì tí ó wà ni ọjọ́ tí a fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun lélẹ̀, jẹ́ ki ọwọ́ rẹ̀ le kí a bá lè kọ́ tẹmpili. 10Nítorí pé, ṣáájú ọjọ́ wọ̀nyí, owó ọ̀yà ènìyàn kò tó nǹkan, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀yà ẹran pẹ̀lú, bẹ́ẹ̀ ni kò sí àlàáfíà fún ẹni ń jáde lọ, tàbí ẹni ti ń wọlé bọ, nítorí ìpọ́njú náà: nítorí mo dojú gbogbo ènìyàn, olúkúlùkù kọ aládùúgbò rẹ̀. 11Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí èmi kì yóò ṣè sí ìyókù àwọn ènìyàn yìí gẹ́gẹ́ bí tí ìgbà àtijọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

12“Nítorí irúgbìn yóò gbilẹ̀: àjàrà yóò ṣo èso rẹ̀, ilẹ̀ yóò sì hu ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan rẹ̀ jáde, àwọn ọ̀run yóò sì mu ìrì wọn wá; èmi ó sì mu kí èyí jẹ ogún ìní àwọn ìyókù ènìyàn yìí ni gbogbo nǹkan wọ̀nyí. 13Yóò sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí jẹ́ ègún láàrín àwọn kèfèrí, ẹ̀yin ilé Juda, àti ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó gbà yín sílẹ̀; ẹ̀yin o sì jẹ́ ìbùkún: ẹ má bẹ̀rù, ṣùgbọ́n jẹ́ ki ọwọ́ yín le.”

14Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Gẹ́gẹ́ bí mo ti rò láti ṣe yín níbi nígbà tí àwọn baba yín mú mi bínú,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, tí èmi kò sì ronúpìwàdà. 15“Bẹ́ẹ̀ ni èmi sì ti ro ọjọ́ wọ̀nyí láti ṣe rere fún Jerusalẹmu, àti fún ilé Juda: ẹ má bẹ̀rù. 168.16: Ef 4.25.Wọ̀nyí ni nǹkan tí ẹ̀yin ó ṣe: ki olúkúlùkù yín kí ó máa ba ọmọnìkejì rẹ̀ sọ òtítọ́; ṣe ìdájọ́ tòótọ́ àti àlàáfíà ní àwọn ibodè yín. 17Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ro ibi ni ọkàn rẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀; ẹ má fẹ́ ìbúra èké; nítorí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni mo kórìíra,” ni Olúwa wí.

18Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun sì tọ mi wá wí pé.

19Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwẹ̀ oṣù kẹrin, karùn-ún, keje, àti tí ẹ̀kẹwàá, yóò jẹ́ ayọ̀ àti dídùn inú, àti àpéjọ àríyá fún ilé Juda; nítorí náà, ẹ fẹ́ òtítọ́ àti àlàáfíà.”

20Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwọn ènìyàn yóò sá à tún wa, àti ẹni tí yóò gbe ìlú ńlá púpọ̀. 21Àwọn ẹni tí ń gbé ìlú ńlá kan yóò lọ sí òmíràn, wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a yára lọ gbàdúrà kí a sì wá ojúrere Olúwa, àti láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi pẹ̀lú yóò sì lọ.’ 22Nítòótọ́, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn àti àwọn alágbára orílẹ̀-èdè yóò wá láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní Jerusalẹmu; àti láti gbàdúrà, àti láti wá ojúrere Olúwa.”

23Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí ni ọkùnrin mẹ́wàá láti inú gbogbo èdè àti orílẹ̀-èdè yóò dìímú, àní yóò di etí aṣọ ẹni tí i ṣe Júù mú, wí pé, ‘Àwa yóò ba ọ lọ, nítorí àwa tí gbọ́ pé, Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.’ ”

New Serbian Translation

Књига пророка Захарије 8:1-23

Господ ће благословити Јерусалим

1Реч Господа над војскама је дошла и поручила:

2„Овако каже Господ над војскама: ’Стало ми је до Сиона, јако ми је стало! За њега ревнујем великом страшћу!’

3Овако каже Господ: ’Вратио сам се на Сион да пребивам усред Јерусалима. „Град истине“, зваће се Јерусалим, а и гора Господа над војскама „Света гора“.’

4Овако каже Господ над војскама: ’Стари људи и старе жене ће поново седети на трговима Јерусалима, времешни, свако са штапом у руци својој. 5Градске ће тргове испунити дечаци и девојчице. Играће се по улицама града.’

6Овако каже Господ над војскама: ’Ако би тих дана то претешко било у очима овог остатка, ових људи, хоће ли да буде претешко и у мојим очима? – говори Господ над војскама.’

7Овако каже Господ над војскама: ’Ево, спашћу свој народ из источне земље и из западне земље. 8Довешћу их да пребивају усред Јерусалима, па ће бити мој народ, а ја ћу бити њихов Бог у истини и у праведности.’

9Овако каже Господ над војскама: ’О, ви што слушате, нека вам руке буду јаке у времену овом због ових речи које вам говоре пророци – који су били на дан оснивања Дома Господа над војскама – да би се изградио Дом! 10Јер, пре тих дана није било наднице ни за људе ни за стоку. Ко год да је одлазио и долазио није имао мира од непријатеља, а ја сам завадио ближње међусобно. 11А ја сада нећу бити остатку народа овог какав сам био раније – говори Господ над војскама.

12Наиме, сејаће се у миру, лоза ће рађати родом својим, земља ће рађати плодовима и росиће небеса. Ја ћу дати остатку овог народа да наследи све ово. 13И као што сте били проклети међу народима, доме Јудин и доме Израиљев, тако ћу вас сада спасти да сте благослов. Не плашите се! Руке своје оснажите!’

14Јер овако каже Господ над војскама: ’Као што сам намеравао да вам наудим када су ме гневили ваши преци – каже Господ над војскама – и нисам се сажалио, 15тако сам окренуо своје намере у ово време, да Јерусалиму и дому Јудином учиним добро. Не плашите се! 16Ово су ствари које ћете да радите: говорите истину један другом. Ради мира истинито и праведно судите на својим вратима. 17Нека нико не смишља у срцу зло против ближњег свога. Не волите лажно заклињање. Све су то ствари које мрзим – говори Господ.’“

18Дошла ми је реч Господа над војскама:

19„Овако каже Господ над војскама: ’Постови четвртог, петог, седмог и десетог месеца за дом Јудин ће постати радост и милина, постаће радосни празници. Зато волите истину и мир.’

20Овако каже Господ над војскама: ’Поново ће доћи народи, становници градова многих. 21И становници ће ићи једни код других и говориће: хајде да одемо и вапимо пред лицем Господњим, да тражимо Господа над војскама. И ја ћу ићи! 22И доћи ће многи људи и народи моћни, да траже Господа над војскама у Јерусалиму, да вапе пред лицем Господњим.’

23Овако каже Господ над војскама: ’У то ће време по десеторо људи од сваког народног језика држати за скут једног Јеврејина и говориће: пустите нас да идемо с вама, јер смо чули да је са вама Бог!’“