Sekariah 10 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sekariah 10:1-12

Olúwa yóò gba Juda

1Ẹ béèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa;

Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná,

tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn,

fún olúkúlùkù koríko ní pápá.

2Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán,

àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké,

wọn sì tí rọ àlá èké;

wọ́n ń tu ni nínú lásán,

nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn,

a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́-àgùntàn kò sí.

3“Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran,

èmi o sì jẹ àwọn olórí ní yà

nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀,

ilé Juda wò,

yóò sì fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.

4Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá,

láti ọ̀dọ̀ rẹ ni èèkàn àgọ́ tí wá,

láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá,

láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.

5Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrin

alágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun,

nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn,

wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.

6“Èmi o sì mú ilé Juda ní agbára,

èmi o sì gba ilé Josẹfu là,

èmi ó sì tún mú wọn padà

nítorí mo tí ṣàánú fún wọn,

ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tì í ta wọ́n nù;

nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn,

èmi o sì gbọ́ tiwọn

7Efraimu yóò sì ṣe bí alágbára,

ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bi ẹni pé nípa ọtí wáìnì:

àní àwọn ọmọ wọn yóò rí í,

wọn o sì yọ̀, inú wọn ó sì dùn nínú Olúwa.

8Èmi ó kọ sí wọn, èmi ó sì ṣà wọ́n jọ;

nítorí èmi tí rà wọ́n padà;

wọn ó sì pọ̀ sí i gẹ́gẹ́ bí

wọ́n tí ń pọ̀ sí í rí.

9Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo tú wọn káàkiri orílẹ̀-èdè:

síbẹ̀ wọn ó sì rántí mi ni ilẹ̀ jíjìn;

wọn ó sì gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn,

wọn ó sì tún padà.

10Èmi ó sì tún mú wọn padà kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti

pẹ̀lú, èmi ó sì ṣà wọn jọ kúrò ni ilẹ̀ Asiria:

èmi ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ Gileadi àti Lebanoni; a

a kì yóò sì rí ààyè fún wọn bí ó ti yẹ.

11Wọn yóò sì la Òkun wàhálà já,

yóò sì bori rírú omi nínú Òkun,

gbogbo ibú odò ni yóò sì gbẹ,

a ó sì rẹ ìgbéraga Asiria sílẹ̀,

ọ̀pá aládé Ejibiti yóò sí lọ kúrò.

12Èmi ó sì mú wọn ní agbára nínú Olúwa;

wọn ó sì rìn sókè rìn sódò ni orúkọ rẹ̀,”

ni Olúwa wí.

Swedish Contemporary Bible

Sakarja 10:1-12

Herrens omsorg om sitt folk

1Be Herren om regn vid tiden för vårregnet.

Herren har gjort stormmolnen,

han ger regnskurar

och låter ge marken gröda åt alla.

2Men husgudarna talar svek,

spåmännen ser lögnaktiga syner,

berättar falska drömmar

och ger tom tröst.

Därför vandrar folket omkring, förtryckta,

för de har ingen herde.

3”Min vrede brinner mot herdarna,

och ledarna10:3 Ordagrant: bockarna. ska jag straffa.

Härskarornas Herre tar sig an

sin hjord, Juda folk,

och gör den till en stolt stridshäst åt sig.

4Från Juda ska hörnstenen komma,

därifrån ska tältpluggen komma,

därifrån bågen till striden,

och därifrån ska alla härskare komma.

5De ska bli som hjältar

som i striden trampar i smutsen på gatan.

De ska strida, för Herren är med dem,

och ryttarna med sina hästar ska komma på skam.

6Jag ska ge styrka åt Juda folk,

och Josefs folk ska jag rädda.

Jag ska låta dem återvända,

eftersom jag förbarmar mig över dem.

Det ska bli som om jag

aldrig hade förkastat dem,

för jag, Herren, deras Gud,

ska bönhöra dem.

7Efraims folk ska bli som hjältar.

De ska glädja sig som av vin.

Deras barn ska se det och vara glada.

De ska jubla i Herren.

8Jag ska vissla på dem

och samla dem,

för jag har friköpt dem.

De ska bli lika talrika som i gångna tider.

9Fastän jag skingrar dem bland folken

ska de ändå komma ihåg mig i fjärran länder.

De och deras barn ska få

leva och återvända.

10Jag ska föra dem tillbaka från Egypten

och samla dem från Assyrien.

Jag ska föra dem till Gilead och Libanon,

och där ska inte finnas utrymme nog för dem.

11De10:11 Egentligen han, vilket ev. skulle kunna syfta på Herren som drar fram över nödens hav och håller tillbaka dess vågor. ska gå genom nödens hav,

och havets vågor ska hållas tillbaka.

Alla Nilens djup ska torka ut,

Assyriens stolthet ska brytas ner

och Egypten förlora sin spira.

12Jag ska göra dem starka i Herren,

och i hans namn ska de vandra,10:12 Enligt bl.a. Septuaginta: …hans namn ska ge dem ära.

säger Herren.”