Ọjọ́ iwájú Jerusalẹmu
1Ègbé ni fún ìlú aninilára,
ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
2Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni,
òun kò gba ìtọ́ni,
òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa,
bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
3Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù,
àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn,
wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
4Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga,
wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn.
Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́,
wọ́n sì rú òfin.
5Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo;
kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà.
Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀,
kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun,
síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
6“Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò,
ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́.
Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo
tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀.
Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí
ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù,
kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
7Èmi wí fún ìlú náà wí pé
‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi,
ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’
Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò
bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó.
Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara
láti ṣe ìbàjẹ́.
8Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí,
“títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin;
nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ
kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ
àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn,
àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi.
Nítorí, gbogbo ayé
ni a ó fi iná owú mi jẹ run.
9“Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́,
nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa,
láti fi ọkàn kan sìn ín.
10Láti òkè odò Etiopia,
àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká,
yóò mú ọrẹ wá fún mi.
11Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì
nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi,
nígbà náà ni èmi yóò mu
kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn.
Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́
ní òkè mímọ́ mi.
12Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù
àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀,
wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
13Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà
ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké,
bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní
ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀,
bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”
14Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni,
kígbe sókè, ìwọ Israẹli!
Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn,
ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
15Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì
kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn.
Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ,
Ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
16Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé,
“Má ṣe bẹ̀rù Sioni;
má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
17Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ,
Ó ní agbára láti gbà ọ là.
Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀;
Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀,
Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”
18“Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ,
àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀;
àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
19Ní àkókò náà
ni èmi yóò dojúkọ àwọn
tí ń ni yín lára,
èmi yóò gba àtiro là,
èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ,
èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní
gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
20Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ;
Nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé.
Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín
láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé,
nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín
padà bọ sípò ní ojú ara yín,”
ni Olúwa wí.
Tsogolo la Yerusalemu
1Tsoka kwa mzinda wa anthu opondereza,
owukira ndi odetsedwa!
2Sumvera aliyense,
sulandira chidzudzulo.
Sumadalira Yehova,
suyandikira pafupi ndi Mulungu wake.
3Akuluakulu ake ali ngati mikango yobuma,
olamulira ake ndi olusa ngati mimbulu ya nthawi ya madzulo,
zimene pofika mmawa sizisiya chilichonse.
4Aneneri ake ndi odzikuza;
anthu achinyengo.
Ansembe ake amadetsa malo opatulika
ndipo amaphwanya lamulo.
5Yehova amene ali pakati pawo ndi wolungama;
Iye salakwa.
Tsiku ndi tsiku amaweruza molungama,
ndipo tsiku lililonse salephera,
komabe ochita zoyipa sachita manyazi nʼkomwe.
6“Ndachotseratu mitundu ya anthu;
ndagwetsa malinga awo.
Ndipo sindinasiye ndi mmodzi yemwe mʼmisewu mwawo,
popanda aliyense wodutsa.
Mizinda yawo yawonongedwa;
palibe aliyense adzatsalemo.
7Ndinati,
‘Ndithudi, anthu a mu mzindawu adzandiopa
ndi kumvera kudzudzula kwanga!’
Ndipo sindidzawononga nyumba zawo,
kapena kuwalanganso.
Koma iwo anali okonzeka
kuchita mwachinyengo zinthu zonse zimene amachita.
8Choncho mundidikire,” akutero Yehova,
“chifukwa cha tsiku limene ndidzaperekera umboni.
Ndatsimikiza kusonkhanitsa pamodzi mitundu ya anthu,
kusonkhanitsa maufumu
ndi kutsanulira ukali wanga pa iwo;
mkwiyo wanga wonse woopsa.
Dziko lonse lidzatenthedwa
ndi moto wa mkwiyo wa nsanje yanga.
9“Pamenepo ndidzayeretsa milomo ya anthu a mitundu yonse
kuti anthu onsewo ayitane dzina la Yehova
ndi kumutumikira Iye pamodzi.
10Kuchokera kutsidya kwa mitsinje ya ku Kusi
anthu anga ondipembedza, omwazikana,
adzandibweretsera zopereka.
11Tsiku limenelo simudzachita manyazi
chifukwa cha zoyipa zonse munandichitira,
popeza ndidzachotsa onse mu mzinda uwu
amene amakondwera chifukwa cha kunyada kwawo.
Simudzakhalanso odzikuza
mʼphiri langa lopatulika.
12Koma ndidzasiya pakati panu
anthu ofatsa ndi odzichepetsa,
amene amadalira dzina la Yehova.
13Aisraeli otsala sadzachitanso zolakwika;
sadzayankhulanso zonama,
ngakhale chinyengo sichidzatuluka mʼkamwa mwawo.
Adzadya ndi kugona
ndipo palibe amene adzawachititse mantha.”
14Imba, iwe mwana wamkazi wa Ziyoni;
fuwula mokweza, iwe Israeli!
Sangalala ndi kukondwera ndi mtima wako wonse,
iwe mwana wamkazi wa Yerusalemu!
15Yehova wachotsa chilango chako,
wabweza mdani wako.
Yehova, Mfumu ya Israeli, ali pakati pako;
sudzaopanso chilichonse.
16Pa tsiku limenelo adzanena kwa Yerusalemu kuti,
“Usaope, iwe Ziyoni;
usafowoke.
17Yehova Mulungu wako ali pakati pako,
ali ndi mphamvu yopulumutsa.
Adzakondwera kwambiri mwa iwe,
adzakukhalitsa chete ndi chikondi chake,
adzayimba mokondwera chifukwa cha iwe.”
18“Ndidzakuchotserani zowawa
za pa zikondwerero zoyikika;
nʼzolemetsa ndi zochititsa manyazi.
19Taonani, nthawi imeneyo ndidzathana ndi
onse amene anakuponderezani;
ndidzapulumutsa olumala
ndi kusonkhanitsa amene anamwazika.
Ndidzawayamikira ndi kuwachitira ulemu
mʼdziko lililonse mmene anachititsidwa manyazi.
20Pa nthawi imeneyo ndidzakusonkhanitsani;
pa nthawi imeneyo ndidzakubweretsani ku mudzi kwanu.
Ndidzakuyamikirani ndi kukuchitirani ulemu
pakati pa mitundu ya anthu a dziko lapansi
pamene ndidzabwezeretsa mtendere wanu
inu mukuona,”
akutero Yehova.