Saamu 9 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 9:1-20

Saamu 9

Fún adarí orin. Ní ti ohun orin “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi.

1Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi;

Èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.

2Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ;

Èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.

3Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà;

Wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.

4Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú;

ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.

5Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run;

Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.

6Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá,

Ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu;

àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.

7Olúwa jẹ ọba títí láé;

ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.

89.8: Ap 17.31.Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo;

yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.

9Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára,

ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.

10Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ,

nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.

11Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni;

kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.

12Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí;

òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.

13Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi!

Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,

14Kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ

ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni

àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.

15Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́;

ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.

16A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀;

àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.

17Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú,

àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run.

18Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé,

ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.

19Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí;

Jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.

20Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa;

jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. Sela.

Nova Versão Internacional

Salmos 9:1-20

Salmo 99 Os salmos 9 e 10 talvez tenham sido originalmente um único poema, organizado em ordem alfabética, no hebraico. Na Septuaginta constituem um único salmo.

Para o mestre de música. De acordo com muth-laben9.0 Expressão de sentido desconhecido. Tradicionalmente: De acordo com a melodia A Morte para o Filho.. Salmo davídico.

1Senhor, quero dar-te graças de todo o coração

e falar de todas as tuas maravilhas.

2Em ti quero alegrar-me e exultar,

e cantar louvores ao teu nome, ó Altíssimo.

3Quando os meus inimigos contigo se defrontam,

tropeçam e são destruídos.

4Pois defendeste o meu direito e a minha causa;

em teu trono te assentaste,

julgando com justiça.

5Repreendeste as nações e destruíste os ímpios;

para todo o sempre apagaste o nome deles.

6O inimigo foi totalmente arrasado, para sempre;

desarraigaste as suas cidades;

já não há quem delas se lembre.

7O Senhor reina para sempre;

estabeleceu o seu trono para julgar.

8Ele mesmo julga o mundo com justiça;

governa os povos com retidão.

9O Senhor é refúgio para os oprimidos,

uma torre segura na hora da adversidade.

10Os que conhecem o teu nome confiam em ti,

pois tu, Senhor, jamais abandonas os que te buscam.

11Cantem louvores ao Senhor, que reina em Sião;

proclamem entre as nações os seus feitos.

12Aquele que pede contas do sangue derramado não esquece;

ele não ignora o clamor dos oprimidos.

13Misericórdia, Senhor!

Vê o sofrimento que me causam os que me odeiam.

Salva-me das portas da morte,

14para que, junto às portas da cidade9.14 Hebraico: filha. de Sião,

eu cante louvores a ti

e ali exulte em tua salvação.

15Caíram as nações na cova que abriram;

os seus pés ficaram presos no laço que esconderam.

16O Senhor é conhecido pela justiça que executa;

os ímpios caem em suas próprias armadilhas. Interlúdio9.16 Hebraico: Higaion.. Pausa

17Voltem os ímpios ao pó9.17 Hebraico: Sheol. Essa palavra também pode ser traduzida por sepultura, profundezas ou morte.,

todas as nações que se esquecem de Deus!

18Mas os pobres nunca serão esquecidos,

nem se frustrará a esperança dos necessitados.

19Levanta-te, Senhor!

Não permitas que o mortal triunfe!

Julgadas sejam as nações na tua presença.

20Infunde-lhes terror, Senhor;

saibam as nações que não passam de seres humanos. Pausa