Saamu 87 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 87:1-7

Saamu 87

Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Orin.

1Ó ti fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ sórí òkè mímọ́;

2Olúwa fẹ́ràn ẹnu-ọ̀nà Sioni

ju gbogbo ibùgbé Jakọbu lọ.

3Ohun ológo ni a sọ nípa rẹ̀,

ìlú Ọlọ́run;

4“Èmi ó dárúkọ Rahabu àti Babeli

láàrín àwọn tí ó jẹ́wọ́ mi:

Filistia pẹ̀lú, àti Tire, pẹ̀lú Kuṣi

yóò sọ pé, ‘Èyí ni a bí ní Sioni.’ ”

5Nítòótọ́, ti Sioni ni a ó sọ,

“Eléyìí àti eléyìí ni a bí nínú rẹ̀,

àti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ni yóò fìdí rẹ̀ múlẹ̀.”

6Olúwa yóò kọ nínú àkọsílẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀:

“Eléyìí ni a bí ní Sioni.”

7Àti àwọn olórin àti àwọn tí ń lu

ohun èlò orin yóò wí pé,

“Gbogbo orísun mi ń bẹ nínú rẹ.”

New International Reader’s Version

Psalm 87:1-7

Psalm 87

A psalm of the Sons of Korah. A song.

1The Lord has built his city

on the holy mountain.

2He loves the city of Zion

more than all the other places

where the people of Jacob live.

3City of God,

the Lord says glorious things about you.

4He says, “I will include Egypt and Babylon

in a list of nations who recognize me as king.

I will also include Philistia and Tyre, along with Cush.

I will say about them, ‘They were born in Zion.’ ”

5Certainly it will be said about Zion,

“This nation and that nation were born in it.

The Most High God himself will make it secure.”

6Here is what the Lord will write in his list of the nations.

“Each of them was born in Zion.”

7As they make music they will sing,

“Zion, all our blessings come from you.”