Saamu 55 – YCB & JCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 55:1-23

Saamu 55

Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi.

1Fi etí sí àdúrà mi, Ọlọ́run,

Má ṣe fi ojú pa ẹ̀bẹ̀ mi rẹ́:

2Gbọ́ mi kí o sì dá mi lóhùn.

Èrò mi ń dà mí láàmú, èmi sì ń pariwo.

3Sí ohùn àwọn ọ̀tá ni,

nítorí igbe àwọn ènìyàn búburú;

nítorí wọ́n mú ìjìyà wá sórí mi,

wọ́n sì kẹ́gàn mi nínú ìbínú wọn.

4Ọkàn mi wà nínú ìrora pẹ̀lú;

ẹ̀rù ikú kọjú ìjà sí mi.

5Ìbẹ̀rù àti ìwárìrì wa sí ara mi;

ìbẹ̀rù ti bò mí mọ́lẹ̀.

6Èmi sọ pé, “Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà!

Èmi ìbá fò lọ kí n sì sinmi.

7Èmi ìbá sálọ, jìnnà réré,

kí ń sì dúró sí aginjù;

8Èmi ìbá yára lọ́ si ibùgbé mi ní ibi ààbò,

jìnnà kúrò nínú ìjì àti ẹ̀fúùfù líle.”

9Da àwọn ẹni búburú láàmú, Olúwa, da ahọ́n wọn rú,

nítorí èmi rí ìwà agbára àti ìjà ní ìlú náà.

10Ọ̀sán àti òru ni wọ́n fi ń rìn gbogbo odi kiri;

ìwà ìkà àti èébú wà láàrín rẹ̀.

11Ìwà búburú ń bẹ ní àárín rẹ̀;

ẹ̀tàn àti èké kò kúrò ní ìgboro rẹ̀.

12Tí ọ̀tá bá tàbùkù mi,

èmi yóò fi ara mọ́ ọn;

tí ọ̀tá bá gbé ara rẹ̀ ga sí mi,

èmi ìbá sápamọ́ fún un.

13Ṣùgbọ́n tí ó bá ṣe ìwọ, ọkùnrin bí ẹgbẹ́ mi,

ẹlẹgbẹ́ mi, àti ọ̀rẹ́ tí ó súnmọ́ mi,

14pẹ̀lú ẹni tí èmi ti jẹ ìgbádùn adùn ìdàpọ̀,

bí a ṣe ń rìn pẹ̀lú àwùjọ ní ilé Ọlọ́run.

15Kí ikú kí ó dé bá wọn,

Kí wọn ó lọ láààyè sí isà òkú,

Jẹ́ kí wọn ó sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú ìpayà,

nítorí tí ìwà búburú ń bẹ ní ibùjókòó wọn, àti nínú wọn.

16Ṣùgbọ́n èmi pe Ọlọ́run;

Olúwa yóò sì gbà mí.

17Ní alẹ́, ní òwúrọ̀ àti ní ọ̀sán

èmi sọkún jáde nínú ìpọ́njú,

o sì gbọ́ ohùn mi.

18Ó rà mí padà láìléwu

kúrò nínú ogun tí ó dìde sí mi,

nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó dìde sí mi.

19Ọlọ́run yóò gbọ́, yóò sì pọ́n wọn lójú

àní, ẹni tí ó ti jókòó láti ìgbàanì—Sela.

Nítorí tí wọn kò ní àyípadà,

tí wọn kò sì bẹ̀rù Ọlọ́run.

20Ọ̀rẹ́ mi yìí ti dalẹ̀ èmi ọ̀rẹ́ rẹ̀;

ó ti ba májẹ̀mú rẹ̀ jẹ́.

21Ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ kúnná ju òrí-àmọ́,

ṣùgbọ́n ogun wà ni àyà rẹ̀;

ọ̀rọ̀ rẹ̀ fẹ́lẹ́ ju òróró lọ,

ṣùgbọ́n idà fífàyọ ní wọn.

2255.22: 1Pt 5.7.Gbé ẹrù rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ Olúwa

yóò sì mú ọ dúró;

òun kò ní jẹ́ kí olódodo ṣubú.

23Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni yóò mu àwọn ọ̀tá mi

wá sí ihò ìparun;

Àwọn ẹni tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ àti ẹni ẹ̀tàn,

kì yóò gbé ààbọ̀ ọjọ́ wọn.

Ṣùgbọ́n fún èmi, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ.

Japanese Contemporary Bible

詩篇 55:1-23

55

1ああ神よ、この祈りをお聞きください。

この切なる願いに、姿を隠さないでください。

2主よ、私に目を留めてください。

私は重荷につぶされそうで、

私の内からは、うめきと涙しか出て来ません。

3敵はわめき散らし、殺してやると脅してきます。

遠巻きにして、私を殺す策略を練っています。

その激しい怒りと憎しみが

私をのみ込もうとしています。

4私は身もだえして苦しみ、

恐怖の戦慄が全身を貫きます。

5私は身ぶるいし、おののいています。

6ああ、鳩のように翼があれば、遠くへ飛び去り、

身を横たえることもできますのに。

7はるかかなたの砂漠へ飛んで行き、

そこに潜んでいたいのです。

8この嵐を逃れて、隠れ場へ逃げ出したいのです。

9主よ、敵を仲間割れさせ、

自らの暴力によって自滅させてください。

10彼らは昼も夜も城壁の上を巡り、

侵入者を見張っていますが、

実際には問題は内部に巣くっているのです。

邪悪と不正が町にはびこっていますから。

11そこには殺人や盗みがあふれ、

市場ばかりか至る所で

詐欺がまかり通っています。

12私をののしるのは敵ではありません。

それなら我慢もできたでしょう。

身を避け、逃げることもできたでしょう。

13しかし、相手というのは、ほかならぬおまえ、

仲間であり友人であるおまえだった。

14われわれは兄弟同様の仲だったではないか。

祭りの日には連れ立って神の宮へ行き、

道々楽しく語り合った。

15彼らの人生の全盛期に死が取りついて、

彼らを倒しますように。

その家は罪に冒され、

心は底の底まで汚れきっていますから。

16しかし私は、主に願えば、

救っていただけるのです。

17朝、昼、晩と、私は神に祈り、大声で嘆願します。

すると、主はその願いを聞き入れてくださいます。

18多数を敵に回した不利な戦いであろうと、

主の救いは確実です。

19神を敬わず、その戒めを踏みにじった彼らには、

永遠の神が報復なさるのです。

20かつてあれほど親しかった友人が、

私を裏切りました。約束を破ったのです。

21口当たりのいいことばの裏には殺意が、

甘いことばの中には剣が隠されているのです。

22重荷を主にゆだねなさい。

主が背負ってくださいます。

信じて従う者が足をすべらせたり、倒れたりするのを、

主が黙って見ておられるはずがありません。

23神は敵を滅びの穴に投げ込まれます。

人殺しとうそつきの寿命は、半分に縮まることでしょう。

しかし、私は神の救いを信じ続けます。